< Genesis 39 >

1 Therfor Joseph was led in to Egipt, and Putifar, `chast and onest seruaunt of Farao, prince of the oost, a man of Egipt, bouyte hym of the hondis of Ismaelitis, of which he was brouyt.
Nígbà tí wọ́n mú Josẹfu dé Ejibiti, Potifari, ará Ejibiti tí i ṣe ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao. Òun ni olórí àwọn ọmọ-ogun Farao. Ó ra Josẹfu lọ́wọ́ àwọn ará Iṣmaeli tí wọ́n mú un lọ síbẹ̀.
2 And the Lord was with hym, and he was a man doynge with prosperite in alle thingis. And Joseph dwellide in `the hows of his lord,
Olúwa sì wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì bùkún un, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀gá rẹ̀ ará Ejibiti.
3 which knew best that the Lord was with Joseph, and that alle thingis whiche he dide, weren dressid of the Lord in `the hond of hym.
Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ rí i pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀, àti pé Olúwa jẹ́ kí ó máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́ rẹ̀ lé.
4 And Joseph foond grace bifor his lord, and `mynystride to hym, of whom Joseph was maad souereyn of alle thingis, and gouernede the hows bitaken to hym, and alle thingis that weren bitakun to hym.
Josẹfu sì rí ojúrere Potifari, ó sì di aṣojú rẹ̀, Potifari fi Josẹfu ṣe olórí ilé rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
5 And the Lord blesside the `hows of Egipcian for Joseph, and multipliede al his catel, as wel in howsis as in feeldis;
Láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu jẹ olórí ilé rẹ̀ àti ohun ìní rẹ̀ gbogbo, ni Ọlọ́run ti bẹ̀rẹ̀ sí ní bùkún àwọn ará Ejibiti nítorí Josẹfu. Ìbùkún Olúwa wà lórí gbogbo ohun tí Potifari ní, nílé àti lóko.
6 nether he knew ony other thing no but `breed which he eet. Forsothe Joseph was fair in face, and schapli in siyt.
Ó sì fi Josẹfu ṣe àkóso gbogbo ohun tí ó ní. Kò sì ṣe ìyọnu lórí ohunkóhun mọ àyàfi nípa oúnjẹ tí ó ń jẹ láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu ṣe àkóso ilé e rẹ̀. Josẹfu sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin ní ìdúró àti ìrísí rẹ̀,
7 And so aftir many daies the ladi castide hir iyen in to Joseph, and seide, Slepe thou with me;
lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, aya rẹ̀ ṣe àkíyèsí Josẹfu, ó sì wí fún un pé, “Wá bá mi lòpọ̀!”
8 which assentide not to the vnleueful werk, and seide to hir, Lo! while alle thingis ben bitakun to me, my lord woot not what he hath in his hows,
Ṣùgbọ́n Josẹfu kọ̀, ó sì wí fún aya ọ̀gá rẹ̀ pé, “Kíyèsi, Olúwa mi kò fi ohunkóhun dù mi nínú ilé yìí, gbogbo ohun ìní rẹ̀ ni ó fi lé mi lọ́wọ́.
9 nether ony thing is, which is not in my power, ether which `he hath not bitake to me, outakun thee, which art his wijf; how therfor may Y do this yuel, and do synne ayens my lord?
Kò sí ẹni tí ó jù mi lọ nínú ilé yìí, ọ̀gá mi kò fi ohunkóhun dù mi àyàfi ìwọ, tí í ṣe aya rẹ̀. Báwo ni mo ṣe lè ṣe ohun búburú yìí, kí ń sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run?”
10 Thei spaken siche wordis `bi alle daies, and the womman was diseseful to the yong waxynge man, and he forsook auoutrie.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ìgbà ni ó ń tẹnumọ́ èyí fún Josẹfu, Josẹfu kọ̀ láti bá a lòpọ̀. Ó tilẹ̀ kọ̀ láti máa dúró ni ibi tí ó bá wà.
11 Forsothe it bifelde in a dai, that Joseph entride in to the hows, and dide sum werk with out witnessis.
Ní ọjọ́ kan, Josẹfu lọ sínú ilé láti ṣe iṣẹ́, kò sì sí èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ ní tòsí.
12 And sche took `the hem of his clooth, and sche seide, Slepe thou with me; and he lefte the mentil in hir hoond, and he fledde, and yede out.
Ó sì di aṣọ Josẹfu mú, ó sì wí pé, “Wá bá mi lòpọ̀!” Ṣùgbọ́n Josẹfu fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí i lọ́wọ́, ó sì sá jáde.
13 And whanne the womman hadde seyn the clooth in hir hondis, and that sche was dispisid,
Nígbà tí ó rí i pé ó ti fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí òun lọ́wọ́, ó sì ti sá jáde,
14 sche clepide to hir the men of hir hows, and seide to hem, Lo! my lord hath brouyt in an Ebrew man, that he schulde scorn vs; he entride to me to do leccherie with me, and whanne Y criede, and he herde my vois,
ó pe àwọn ìránṣẹ́ ilé náà, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wò ó, ọkọ ọ̀ mi mú Heberu kan wọlé tọ̀ wá wá láti fi wá ṣe ẹlẹ́yà. Ó wọlé tọ̀ mí wá, láti bá mi lòpọ̀, ṣùgbọ́n mo kígbe.
15 he lefte the mentil which Y helde, and he fledde out.
Nígbà tí ó gbọ́ pé mo gbé ohùn mi sókè, tí mo sì kígbe, ó jọ̀wọ́ aṣọ rẹ̀ sọ́dọ̀ mi, ó sì sá, ó bọ́ sóde.”
16 Therfor in to the preuyng of trouthe, sche schewide the mantil, holdun to the hosebonde turnynge ayen hoom.
Ó sì fi aṣọ náà sọ́dọ̀ títí tí ọkọ rẹ̀ fi dé.
17 And she seide, The Ebrew seruaunt, whom thou brouytist, entride to me to scorne me; and whanne he siy me crye,
Ó rò fún un pé, “Ẹrú ará Heberu tí o rà wá ilé láti fi wá ṣẹlẹ́yà wá láti bá mi lòpọ̀.
18 he lefte the mentil which Y helde, and he fledde out.
Ṣùgbọ́n bí mo ti kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ó sì sá kúrò nínú ilé.”
19 And whanne these thingis weren herd, the lord bileuyde ouer myche to the wordis of the wijf, and was ful wrooth;
Nígbà tí Potifari gbọ́ ọ̀rọ̀ aya rẹ̀ pé báyìí ni ẹrú rẹ̀ ṣe sí aya rẹ̀, ó bínú gidigidi.
20 and he bitook Joseph in to prisoun, where the bounden men of the kyng weren kept, and he was closid there.
Ó sì ju Josẹfu sí ẹ̀wọ̀n, níbi tí a ń ju àwọn ẹlẹ́wọ̀n ọba sí. Ṣùgbọ́n, nígbà tí Josẹfu wà nínú ẹ̀wọ̀n níbẹ̀,
21 Forsothe the Lord was with Joseph, and hadde mercy on hym, and yaf grace to hym in the siyt of the prince of the prisoun,
Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì ṣàánú fún un, ó sì mú kí ó rí ojúrere àwọn alábojútó ọgbà ẹ̀wọ̀n.
22 which bitook in the hond of Joseph alle prisoneris that weren holdun in kepyng, and what euer thing was doon, it was vndur Joseph, nethir the prince knewe ony thing,
Nítorí náà, alábojútó ọgbà ẹlẹ́wọ̀n fi Josẹfu ṣe alákòóso ohun gbogbo tí ó wà nínú ẹ̀wọ̀n, àti ohun tí wọn ń ṣe níbẹ̀.
23 for alle thingis weren bitakun to Joseph; for the Lord was with hym, and dresside alle his werkis.
Wọ́dà náà kò sì mikàn nípa gbogbo ohun tí ó fi sí abẹ́ àkóso Josẹfu, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì ń jẹ́ kí ó ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé.

< Genesis 39 >