< Genesis 18 >

1 Forsothe in the valei of Mambre the Lord apperide to Abraham, sittynge in the dore of his tabernacle, in thilke heete of the dai.
Olúwa sì farahan Abrahamu nítòsí àwọn igi ńlá Mamre, bí ó ti jókòó ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀, nígbà tí ọjọ́-kanrí tí oòrùn sì mú.
2 And whanne he hadde reisid his iyen, thre men apperiden to hym, and stoden nyy hym. And whanne he hadde seyn hem, he ran fro the dore of his tabernacle in to the meting of hem, and he worschipide on erthe,
Abrahamu gbójú sókè, ó sì rí àwọn ọkùnrin mẹ́ta tí wọn dúró nítòsí rẹ̀. Nígbà tí ó rí wọn, ó sáré láti lọ pàdé wọn, ó sì tẹríba bí ó ti ń kí wọn.
3 and seide, Lord, if Y haue founde grace in thin iyen, passe thou not thi seruaunt,
Ó wí pé, “Bí mo bá rí ojúrere yín Olúwa mi, ẹ má ṣe lọ láì yà sọ́dọ̀ ìránṣẹ́ yín.
4 but I schal brynge a litil watir, and youre feet be waischid, and reste ye vndur the tre;
Ẹ jẹ́ kí a bu omi díẹ̀ wá kí ẹ̀yin kí ó wẹ ẹsẹ̀ yín, kí ẹ sì sinmi lábẹ́ igi níhìn-ín.
5 and Y schal sette a mussel of breed, and youre herte be coumfortid; aftirward ye schulen passe; for herfor ye bowiden to youre seruaunt. Whiche seiden, Do thou as thou hast spoke.
Ẹ jẹ́ kí n wá oúnjẹ wá fún un yín, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ, kí ara sì tù yín, kí ẹ si tẹ̀síwájú ní ọ̀nà yín, nígbà tí ẹ ti yà ní ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ yín.” Wọn sì wí pé “Ó dára.”
6 Abraham hastide in to the tabernacle, to Sare, and seide to hir, Hast thou, meddle thou thre half buschelis of clene flour; and make thou looues bakun vndur aischis.
Abrahamu sì yára tọ Sara aya rẹ̀ lọ nínú àgọ́, ó wí pé, “Tètè mú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun dáradára mẹ́ta kí o sì pò ó pọ̀, kí o sì ṣe oúnjẹ.”
7 Forsothe he ran to the droue of beestis, and took therof a calf moost tendre and best, and yaf to a child, which hastide, and sethede the calfe;
Abrahamu sì tún sáré lọ sí ibi agbo ẹran, ó sì mú ọmọ màlúù kan fún ìránṣẹ́ rẹ̀, ìránṣẹ́ náà sì tètè ṣè é.
8 and he took botere, and mylk, and the calf which he hadde sode, and settide bifore hem; forsothe Abraham stood bisidis hem vndur the tre.
Ó sì mú wàrà àti mílíìkì àti màlúù tí ó ti pèsè, ó sì gbé síwájú wọn. Ó sì dúró nítòsí wọn lábẹ́ igi bí wọn ti ń jẹ ẹ́.
9 And whanne thei hadden ete, thei seiden to hym, Where is Sare thi wijf? He answerde, Lo! sche is in the tabernacle.
Wọn béèrè pé, “Sara aya rẹ ń kọ́?” Ó dáhùn pé, “Ó wà nínú àgọ́.”
10 To whom the Lord seide, Y schal turne ayen, and Y schal come to thee in this tyme, if Y lyue; and Sare, thi wijf, schal haue a sone. Whanne this was herd, Sare leiyede bihynde the dore of the tabernacle.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún un pé, “Èmi yóò sì tún padà tọ̀ ọ́ wá nítòótọ́ ní ìwòyí àmọ́dún; Sara aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.” Sara sì ń dẹtí gbọ́ láti ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tí ó wà lẹ́yìn ọkùnrin náà.
11 Forsothe bothe weren olde, and of greet age, and wommans termes ceessiden to be maad to Sare.
Abrahamu àti Sara sì ti di arúgbó, Sara sì ti kọjá àsìkò ìbímọ.
12 And she leiyede, seiynge pryueli, after that Y wexede eld, and my lord is eld, schal Y yyue diligence to lust?
Nítorí náà, Sara rẹ́rìn-ín nínú ara rẹ̀ bí ó ti ń rò ó lọ́kàn rẹ̀ pé, “Lẹ́yìn ìgbà tí mo ti di arúgbó tán tí olúwa mi pẹ̀lú sì ti gbó jọ̀kújọ̀kú, èmi yóò ha tún lè bímọ?”
13 Forsothe the Lord seide to Abraham, Whi leiyeth Sare, thi wijf, seiynge, whether Y an eld womman schal bere child verili?
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abrahamu pé, “Kín ló dé tí Sara fi rẹ́rìn-ín tí ó sì wí pé, ‘Èmi yóò ha bímọ nítòótọ́, nígbà tí mo di ẹni ogbó tán?’
14 whether ony thing is hard to God? Bi the biheeste Y schal turne ayen to thee in this same tyme, if Y lyue; and Sara schal haue a sone.
Ǹjẹ́ ohunkóhun wà tí ó ṣòro jù fún Olúwa? Èmi ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìwòyí àmọ́dún, Sara yóò sì bí ọmọkùnrin.”
15 Sare was aferd for drede, and denyede, seiynge, Y leiyede not. Forsothe the Lord seide, It is not so, but thou leiyedist.
Ẹ̀rù sì ba Sara, ó sì sẹ́ pé òun kò rẹ́rìn-ín. Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Dájúdájú ìwọ rẹ́rìn-ín.”
16 Therfor whanne the men hadden risen fro thennus, thei dressiden the iyen ayens Sodom; and Abraham yede to gidre, ledynge hem forth.
Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, wọn kọjú sí ọ̀nà Sodomu, Abrahamu sì sìn wọ́n dé ọ̀nà.
17 And the Lord seide, Wher Y mowe hele fro Abraham what thingis Y schal do,
Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ǹjẹ́ èmi yóò ha pa ohun tí mo fẹ́ ṣe mọ́ fún Abrahamu bí?
18 sithen he schal be in to a greet folk and moost strong, and alle naciouns of erthe schulen be blessid in hym?
Dájúdájú Abrahamu yóò sá à di orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára, àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni a ó bùkún fún nípasẹ̀ rẹ̀.
19 For Y woot that Abraham schal comaunde hise children, and his hows after hym, that thei kepe the weie of the Lord, and that thei do riytfulnesse and dom, that the Lord bringe for Abraham alle thingis whiche he spak to Abraham.
Nítorí tí èmi ti yàn án láti kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ará ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, láti máa pa ọ̀nà Olúwa mọ nípa ṣíṣe olóòtítọ́ àti olódodo: kí Olúwa le è mú ìlérí rẹ̀ fún Abrahamu ṣẹ.”
20 And so the Lord seide, The cry of men of Sodom and of men of Gomorre is multiplied, and her synne is agreggid greetli; Y schal come doun,
Olúwa sì wí pé, igbe Sodomu àti Gomorra pọ̀ púpọ̀ àti pé ẹ̀ṣẹ̀ wọn burú jọjọ.
21 and schal se whether thei han fillid in werk the cry that cam to me, that Y wite whether it is not so.
“Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ síbẹ̀ láti ṣe ìwádìí igbe tí ó dé sí etí ìgbọ́ mi nípa wọn, kí èmi sì mọ òtítọ́ tí ó wà níbẹ̀.”
22 And thei turneden han fro thennus, and yeden to Sodom. Abraham sotheli stood yit bifore the Lord,
Àwọn ọkùnrin náà yí padà, wọ́n sì ń lọ sí ìhà Sodomu. Ṣùgbọ́n Abrahamu dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
23 and neiyede, and seide, Whether thou schalt leese a iust man with the wickid man?
Nígbà náà ni Abrahamu súnmọ́ ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì wí pé, “Ìwọ yóò ha pa olódodo ènìyàn àti ènìyàn búburú run papọ̀ bí?”
24 if fifti iust men ben in the citee, schulen thei perische togidere, and schalt thou not spare that place for fifti iust men, if thei ben ther ynne?
“Bí ó bá ṣe pé ìwọ rí àádọ́ta olódodo nínú ìlú náà, ìwọ yóò ha run ún, ìwọ kì yóò ha dá ìlú náà sí nítorí àwọn àádọ́ta olódodo tí ó wà nínú rẹ̀ náà?
25 Fer be it fro thee that thou do this thing, and sle a iust man with a wickid man, and that a iust man be maad as a wickid man; this is not thin that demest al erthe; thou schalt not make this doom.
Kò jẹ́ rí bẹ́ẹ̀! Dájúdájú ìwọ kì yóò ṣe ohun tí ó jọ bẹ́ẹ̀, láti pa olódodo pẹ̀lú àwọn ènìyàn rere àti àwọn ènìyàn búburú. Dájúdájú, ìwọ kì yóò ṣe èyí tí ó tọ́ bi?”
26 And the Lord seide to him, If Y schal fynde in Sodom fifti iust men in the myddis of the citee, Y schal foryyue to al the place for hem.
Olúwa wí pé, “Bí mo bá rí àádọ́ta olódodo ní ìlú Sodomu, èmi yóò dá ìlú náà sí nítorí tiwọn.”
27 Abraham answerde and seide, For Y bigan onys, Y schal speke to my Lord, sithen Y am dust and aische;
Abrahamu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Wò ó nísinsin yìí, níwọ̀n bí èmi ti ní ìgboyà láti bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa, èmi ẹni tí í ṣe erùpẹ̀ àti eérú,
28 what if lesse than fifti iust men bi fyue ben, schalt thou do a wey al the cite for fyue and fourti? And the Lord seide, Y schal not do a wei, if I schal fynde fyue and fourti there.
bí ó bá ṣe pe olódodo márùndínláàádọ́ta ni ó wà nínú ìlú, ìwọ yóò ha pa ìlú náà run nítorí ènìyàn márùn-ún bí?” Olúwa dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo márùndínláàádọ́ta nínú rẹ̀.”
29 And eft Abraham seide to hym, But if fourti ben there, what schalt thou do? The Lord seide, Y schal not smyte for fourti.
Òun sì tún wí lẹ́ẹ̀kan si pé, “Bí ó bá ṣe pé ogójì ni ń kọ́?” Olúwa sì tún wí pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo ogójì nínú rẹ̀.”
30 Abraham seide, Lord, Y biseche, take thou not to indignacioun, if Y speke; what if thretti be foundun there? The Lord answerde, Y schal not do, if Y schal fynde thretti there.
Abrahamu sì tún bẹ Olúwa pé, “Kí Olúwa má ṣe bínú, ṣùgbọ́n èmi yóò sọ̀rọ̀. Bí ó bá ṣe pé ọgbọ̀n ni a rí níbẹ̀ ń kọ́?” Olúwa dáhùn pé, “Bí mó bá rí ọgbọ̀n, èmi kì yóò pa ìlú run.”
31 Abraham seide, For Y bigan onys, Y schal speke to my Lord; what if twenti be foundun there? The Lord seide, Y schal not sle for twenti.
Abrahamu wí pé, “Níwọ́n bí mo ti ní ìgboyà láti bá Olúwa sọ̀rọ̀ báyìí, jẹ́ kí n tẹ̀síwájú. Bí o bá ṣe pé olódodo ogún péré ni ó wà nínú ìlú náà ń kọ́?” Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa á run nítorí ogún ènìyàn náà.”
32 Abraham seide, Lord, Y biseche, be thou not wrooth, if Y speke yit onys; what if ten be founden there? The Lord seide, Y schal not do a wey for ten.
Abrahamu sì wí pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú Olúwa. Jẹ́ kí ń béèrè lẹ́ẹ̀kan si. Bí ó bá ṣe pé ènìyàn mẹ́wàá ni ó jẹ́ olódodo ń kọ́?” Olúwa wí pé, “Nítorí ènìyàn mẹ́wàá náà, èmi kì yóò pa á run.”
33 The Lord yede forth, after that he ceesside to speke to Abraham, and Abraham turnede ayen in to his place.
Olúwa sì bá tirẹ̀ lọ, nígbà tí ó bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Abrahamu sì padà sílé.

< Genesis 18 >