< Genesis 11 >

1 Forsothe the lond was of o langage, and of the same speche.
Lẹ́yìn náà, gbogbo àgbáyé sì ń sọ èdè kan ṣoṣo.
2 And whanne thei yeden forth fro the eest, thei fonden a feeld in the lond of Sennaar, and dwelliden ther ynne.
Bí àwọn ènìyàn ṣe ń tẹ̀síwájú lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n rí pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan ní ilẹ̀ Ṣinari, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
3 And oon seide to his neiybore, Come ye, and make we tiel stonys, and bake we tho with fier; and thei hadden tiel for stonus, and pitche for morter;
Wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a mọ bíríkì kí a sì sún wọ́n jìnà.” Bíríkì ni wọ́n ń lò ní ipò òkúta, àti ọ̀dà ilẹ̀ tí wọn ń lò láti mú wọn papọ̀ dípò ẹfun (òkúta láìmù tí wọ́n fi ń ṣe símẹ́ńtì àti omi).
4 and seiden, Come ye, and make we to vs a citee and tour, whos hiynesse stretche `til to heuene; and make we solempne oure name bifor that we be departid in to alle londis.
Nígbà náà ni wọ́n wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tẹ ìlú kan dó fún ara wa, kí a sì kọ́ ilé ìṣọ́ kan tí yóò kan ọ̀run, kí a ba à lè ní orúkọ, kí a má sì tú káàkiri sórí gbogbo ilẹ̀ ayé.”
5 Forsothe the Lord cam down to se the citee and tour, which the sones of Adam bildiden.
Ṣùgbọ́n, Olúwa sọ̀kalẹ̀ láti wo ìlú àti ilé ìṣọ́ tí àwọn ènìyàn náà ń kọ́.
6 And he seide, Lo! the puple is oon, and o langage is to alle, and thei han bigunne to make this, nethir thei schulen ceesse of her thouytis, til thei fillen tho in werk; therfor come ye, go we doun,
Olúwa wí pé, “Bí àwọn ènìyàn bá ń jẹ́ ọ̀kan àti èdè kan tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ yìí, kò sí ohun tí wọ́n gbèrò tí wọn kò ní le ṣe yọrí.
7 and scheende we there the tunge of hem, that ech man here not the voys of his neiybore.
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ lọ, kí a da èdè wọn rú kí èdè wọn má ba à yé ara wọn mọ́.”
8 And so the Lord departide hem fro that place in to alle londis; and thei cessiden to bielde a cytee.
Olúwa sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó.
9 And therfor the name therof was clepid Babel, for the langage of al erthe was confoundide there; and fro thennus the Lord scaterede hem on the face of alle cuntrees.
Ìdí èyí ni a fi pè é ní Babeli nítorí ní ibẹ̀ ni Olúwa ti da èdè gbogbo ayé rú. Olúwa tí sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.
10 These ben the generaciouns of Sem. Sem was of an hundrid yeer whanne he gendride Arfaxath, twey yeer aftir the greet flood.
Wọ̀nyí ni ìran Ṣemu. Ọdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣemu pé ọgọ́rùn-ún ọdún ni ó bí Arfakṣadi.
11 And Sem lyuede aftir that he gendride Arfaxath fyue hundrid yeer, and gendride sones and douytris.
Lẹ́yìn tí ó bí Arfakṣadi, Ṣemu tún wà láààyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
12 Forsothe Arfaxath lyuede fyue and thretti yeer, and gendride Sale;
Nígbà tí Arfakṣadi pé ọdún márùndínlógójì ni ó bí Ṣela.
13 and Arfaxath lyuede aftir that he gendride Sale thre hundride and thre yeer, and gendride sones and douytris.
Arfakṣadi sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Ṣela, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.
14 Also Sale lyuede thretti yeer, and gendride Heber;
Nígbà tí Ṣela pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Eberi.
15 and Sale lyuede after that he gendride Heber foure hundrid and thre yeer, and gendride sones and douytris.
Ṣela sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Eberi tán, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
16 Sotheli Heber lyuede foure and thretti yeer, and gendride Falech;
Eberi sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, ó sì bí Pelegi.
17 and Heber lyuede aftir that he gendride Falech foure hundrid and thretti yeer, and gendride sones and douytris.
Eberi sì wà láààyè fún irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n lẹ́yìn tí ó bí Pelegi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
18 Also Falech lyuede thretti yeer, and gendride Reu;
Nígbà tí Pelegi pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Reu.
19 and Falech lyuede aftir that he gendride Reu two hundrid and nyne yeer, and gendride sones and douytris.
Pelegi sì tún wà láààyè fún igba ọdún ó lé mẹ́sàn-án lẹ́yìn tí ó bí Reu, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
20 And Reu lyuede two and thretti yeer, and gendride Saruch;
Nígbà tí Reu pé ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ni ó bí Serugu.
21 and Reu lyuede aftir that he gendride Saruch two hundrid and seuene yeer, and gendride sones and douytris.
Reu tún wà láààyè lẹ́yìn tí ó bí Serugu fún igba ọdún ó lé méje, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn.
22 Sotheli Saruch lyuede thretti yeer, and gendride Nachor;
Nígbà tí Serugu pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Nahori.
23 and Saruch lyuede aftir that he gendride Nacor two hundrid yeer, and gendride sones and douytris.
Serugu sì wà láààyè fún igba ọdún lẹ́yìn tí ó bí Nahori, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
24 Forsothe Nachor lyuede nyne and twenti yeer, and gendride Thare;
Nígbà tí Nahori pé ọmọ ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n, ó bí Tẹra.
25 and Nachor lyuede after that he gendride Thare an hundrid and nynetene yeer, and gendride sones and douytris.
Nahori sì wà láààyè fún ọdún mọ́kàn dín lọ́gọ́fà lẹ́yìn ìbí Tẹra, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
26 And Thare lyuede seuenti yeer, and gendride Abram, and Nachor, and Aran.
Lẹ́yìn tí Tẹra pé ọmọ àádọ́rin ọdún ó bí Abramu, Nahori àti Harani.
27 Sotheli these ben the generaciouns of Thare. Thare gendride Abram, Nachor, and Aran. Forsothe Aran gendride Loth;
Wọ̀nyí ni ìran Tẹra. Tẹra ni baba Abramu, Nahori àti Harani. Harani sì bí Lọti.
28 and Aran diede bifore Thare, his fadir, in the lond of his natiuite, in Vr of Caldeis.
Harani sì kú ṣáájú Tẹra baba rẹ̀ ní ilẹ̀ ìbí rẹ̀ ní Uri ti ilẹ̀ Kaldea.
29 Forsothe Abram and Nachor weddiden wyues; the name of the wijf of Abram was Saray, and the name of the wiif of Nachor was Melcha, the douyter of Aran, fadir of Melcha and fadir of Jescha.
Abramu àti Nahori sì gbéyàwó. Orúkọ aya Abramu ni Sarai, nígbà tí aya Nahori ń jẹ́ Milka, tí ṣe ọmọ Harani. Harani ni ó bí Milka àti Iska.
30 Sotheli Saray was bareyn, and hadde no children.
Sarai sì yàgàn, kò sì bímọ.
31 And so Thare took Abram, his sone, and Loth, the sone of Aran his sone, and Saray, his douyter in lawe, the wijf of Abram, his sone, and ledde hem out of Vr of Caldeis, that thei schulen go in to the lond of Chanaan; and thei camen `til to Aran, and dwelliden there.
Tẹra sì mú ọmọ rẹ̀ Abramu àti Lọti ọmọ Harani, ọmọ ọmọ rẹ̀, ó sì mú Sarai tí i ṣe aya ọmọ rẹ̀. Abramu pẹ̀lú gbogbo wọn sì jáde kúrò ní Uri ti Kaldea láti lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn dé Harani wọ́n tẹ̀dó síbẹ̀.
32 And the daies of Thare weren maad two hundrid yeer and fyue, and he was deed in Aran.
Nígbà tí Tẹra pé ọmọ igba ọdún ó lé márùn-ún ni ó kú ní Harani.

< Genesis 11 >