< Ezra 5 >

1 Forsothe Aggei, the prophete, and Zacharie, the prophete, the sone of Ado, prophesieden, prophesiynge in the name of God of Israel, to the Jewis that weren in Juda and Jerusalem.
Nígbà náà wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, láti ìran Iddo, sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí àwọn ará Júù ní Juda àti Jerusalẹmu ní orúkọ Ọlọ́run Israẹli tí ẹ̀mí rẹ̀ ń bẹ lára wọn.
2 Thanne Zorobabel, the sone of Salatiel, and Josue, the sone of Josedech, risiden, and bigunnen to bilde the temple of God in Jerusalem; and with hem rysyden the prophetis of God, helpynge hem.
Nígbà náà Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua ọmọ Josadaki gbáradì fún iṣẹ́ àti tún ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu kọ́. Àwọn wòlíì Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú wọn, tí wọ́n ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
3 Forsothe in that tyme Tatannai, that was duyk biyende the flood, and Starbusannay, and the counselouris of hem, camen to hem, and seiden thus to hem, Who yaf counsel to you to bilde this hows, and to restore these wallis?
Ní àkókò náà Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹgbẹgbẹ́ wọn lọ sí ọ̀dọ̀ wọn. Wọ́n sì béèrè pé, “Ta ni ó fún un yín ní àṣẹ láti tún tẹmpili yìí kọ́ àti láti tún odi yìí mọ?”
4 To which thing we answeriden to hem, whiche weren the names of men, autours of that bildyng.
Wọ́n sì tún béèrè pé, “Kí ni orúkọ àwọn ọkùnrin tí ó ń kọ́ ilé yìí?”
5 Forsothe the iye of God of hem was maad on the elde men of Jewis, and thei myyten not forbede the Jewis; and it pleside that the thing schulde be teld to Darius, and thanne thei schulden make satisfaccioun ayens that accusyng.
Ṣùgbọ́n ojú Ọlọ́run wọn wà lára àwọn àgbàgbà Júù, wọn kò sì dá wọn dúró títí ìròyìn yóò fi dè ọ̀dọ̀ Dariusi kí wọ́n sì gba èsì tí àkọsílẹ̀ láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
6 This is the saumpler of the pistle, which Tathannai, duyk of the cuntrey biyende the flood, and Starbursannai, and hise counselouris, Arphasacei, that weren biyende the flood, senten to kyng Darius.
Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà tí Tatenai, olórí agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn. Àwọn olóyè ti agbègbè Eufurate, fi ránṣẹ́ sí ọba Dariusi.
7 The word which thei senten to hym was writun thus; Al pees be to the kyng Darius.
Ìròyìn tí wọ́n fi ránṣẹ́ sí i kà báyìí pé, Sí ọba Dariusi, Àlàáfíà fún un yín.
8 Be it knowun to the kyng, that we yeden to the prouince of Judee, to the hows of greet God, which is bildid with stoon vnpolischid, and trees ben set in the wallis, and thilke werk is bildid diligently, and encreessith in the hondis of hem.
Kí ọba kí ó mọ̀ pé a lọ sí ẹ̀kún Juda, sí tẹmpili Ọlọ́run tí ó tóbi. Àwọn ènìyàn náà ń kọ́ ọ pẹ̀lú àwọn òkúta ńlá ńlá àti pẹ̀lú fífi àwọn igi sí ara ògiri. Wọ́n ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àìsimi, ó sì ń ní ìtẹ̀síwájú kíákíá lábẹ́ ìṣàkóso wọn.
9 Therfor we axiden tho elde men, and thus we seiden to hem, Who yaf to you power to bilde this hows, and to restore these wallis?
A bi àwọn àgbàgbà, a sì fi ọ̀rọ̀ wá wọn lẹ́nu wò pé, “Ta ni ó fún un yín ní àṣẹ láti tún ilé Olúwa yìí kọ́ àti láti tún odi rẹ̀ mọ?”
10 But also we axiden of hem the names `of hem, that we schulden telle to thee; and we han write the names of men, whiche thei ben, that ben princes among hem.
A sì tún béèrè orúkọ wọn pẹ̀lú, kí a lè kọ àwọn orúkọ àwọn olórí wọn sílẹ̀ kí ẹ ba à le mọ ọ́n.
11 Sotheli thei answeriden bi sich word, and seiden, We ben the seruauntis of God of heuene and of erthe; and we bilden the temple that was bildid bifor these many yeeris, and `which temple the greet kyng of Israel `hadde bildid, and maad.
Èyí ni ìdáhùn tí wọ́n fún wa: “Àwa ni ìránṣẹ́ Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, àwa sì ń tún tẹmpili ilé Olúwa tí a ti kọ́ ní ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn kọ́, èyí tí ọba olókìkí kan ní Israẹli kọ́, tí ó sì parí i rẹ̀.
12 But aftir that oure fadris stiryden God of heuene and of erthe to wrathfulnesse, bothe he bitook hem in the hond of Nabugodonosor, Caldey, kyng of Babiloyne; and he distriede this hows, and translatide the puple therof in to Babiloyne.
Ṣùgbọ́n nítorí tí àwọn baba wa mú Ọlọ́run ọ̀run bínú, ó fi wọ́n lé Nebukadnessari ti Kaldea, ọba Babeli lọ́wọ́, ẹni tí ó run tẹmpili Olúwa yìí tí ó sì kó àwọn ènìyàn náà padà sí Babeli.
13 Forsothe in the firste yeer of Cirus, king of Babiloyne, Cirus, the king of Babiloyne, settide forth `a comaundement, that the hows of God schulde be bildid.
“Ṣùgbọ́n ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba Kirusi ọba Babeli, ọba Kirusi pàṣẹ pé kí a tún ilé Ọlọ́run yìí kọ́.
14 For whi kyng Cirus brouyte forth `fro the temple of Babiloyne also the goldun and siluerne vessels of Goddis temple, whiche Nabugodonosor hadde take fro the temple, that was in Jerusalem, and hadde bore tho awei in to the temple of Babiloyne; and tho vessels weren youun to Sasabazar bi name, whom `he made also prince. And Cirus seide to hym, Take these vessels,
Òun tilẹ̀ kò jáde láti inú tẹmpili ní Babeli fàdákà àti ohun èlò wúrà ilé Ọlọ́run, èyí tí Nebukadnessari kó láti inú tẹmpili ní Jerusalẹmu wá sí inú tẹmpili ní Babeli. Ọba Kirusi kó wọn fún ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Ṣeṣbassari, ẹni tí ó ti yàn gẹ́gẹ́ bí i baálẹ̀,
15 and go, and sette tho in the temple, which is in Jerusalem; and the hows of God be bildid in `his place.
ó sì sọ fún un pé, ‘Kó àwọn ohun èlò yìí kí o lọ, kí o sì kó wọn sí inú ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, kí ẹ sì tún ilé Ọlọ́run kọ́ sí ipò o rẹ̀.’
16 Therfor thanne thilke Sasabazar cam, and settide the foundementis of Goddis temple in Jerusalem; and fro that tyme `til to now it is bildid, and is not yit fillid.
“Nígbà náà ni Ṣeṣbassari náà wá, ó sí fi ìpìlẹ̀ ilé Ọlọ́run tí ó wá ní Jerusalẹmu lélẹ̀, láti ìgbà náà àní títí di ìsinsin yìí ni o ti n bẹ ní kíkọ́ ṣùgbọ́n, kò sí tí ì parí tán.”
17 Now therfor if it `semeth good to the king, rikene he in the biblet of the kyng, which is in Babiloyne, whether it be comaundid of kyng Cyrus, that Goddis hows schulde be bildid in Jerusalem; and sende he to vs the wille of the kyng `on this thing.
Nísinsin yìí tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn, ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí nínú ìwé ìrántí ní ilé ìṣúra ọba ní Babeli láti rí bí ọba Kirusi fi àṣẹ lélẹ̀ lóòótọ́ láti tún ilé Ọlọ́run yìí kọ́ ní Jerusalẹmu. Nígbà náà jẹ́ kí ọba kó fi ìpinnu rẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ yìí ránṣẹ́ sí wa.

< Ezra 5 >