< Ezekiel 16 >

1 And the word of the Lord was maad to me,
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 and he seide, Sone of man, make thou knowun to Jerusalem her abhomynaciouns; and thou schalt seie,
“Ọmọ ènìyàn, mú kí Jerusalẹmu mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.
3 The Lord God seith these thingis. A! thou Jerusalem, thi rote and thi generacioun is of the lond of Canaan; thi fadir is Amorrei, and thi moder is Cetei.
Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Jerusalẹmu, ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kenaani; ará Amori ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hiti.
4 And whanne thou were borun, thi nawle was not kit awei in the dai of thi birthe, and thou were not waischun in watir in to helthe, nethir saltid with salt, nether wlappid in clothis.
Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fi omi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, a kò fi iyọ̀ pa ọ́ lára rárá, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi aṣọ wé ọ.
5 An iye sparide not on thee, that it hauynge merci on thee, dide to thee oon of these thingis; but thou were cast forth on the face of erthe, in the castynge out of thi soule, in the dai in which thou were borun.
Kò sí ẹni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ dé bi à ti ṣe nǹkan kan nínú ìwọ̀nyí fún ọ, ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.
6 Forsothe Y passide bi thee, and Y siy thee defoulid in thi blood; and Y seide to thee, whanne thou were in thi blood, Lyue thou; sotheli Y seide to thee in thi blood, Lyue thou.
“‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!” Nítòótọ́, nígbà tí ìwọ wà nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ pé, “Yè.”
7 Y yaf thee multiplied as the seed of a feeld, and thou were multiplied, and maad greet; and thou entridist, and camest fulli to wymmens ournyng; thi tetis wexiden greet, and thin heer wexide; and thou were nakid, and ful of schenschipe.
Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòhò láìfi nǹkan kan bora.
8 And Y passide bi thee, and Y siy thee, and lo! thi tyme, the tyme of louyeris; and Y spredde abrood my clothing on thee, and Y hilide thi schenschipe. And Y swoor to thee, and Y made a couenaunt with thee, seith the Lord God, and thou were maad a wijf to me.
“‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ̀ẹ́ rẹ ti tó, mo fi ìṣẹ́tí aṣọ mi bo ìhòhò rẹ. Mo búra fún ọ, èmi sì bá ọ dá májẹ̀mú ìwọ sì di tèmi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 And Y waischide thee in water, and Y clenside awei thi blood fro thee, and Y anoyntide thee with oile.
“‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò ní ara rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.
10 And Y clothide thee with clothis of dyuerse colours, and Y schodde thee in iacynct, and Y girde thee with biys;
Mo fi aṣọ oníṣẹ́-ọnà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun gbòò àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.
11 and Y clothide thee with sutil thingis, and Y ournede thee with ournement.
Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ ní ọwọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ ní ọrùn,
12 And Y yaf bies in thin hondis, and a wrethe aboute thi necke; and Y yaf a ryng on thi mouth, and cerclis to thin eeris, and a coroun of fairnesse in thin heed.
mo sì tún fi òrùka sí ọ ní imú, mo fi yẹtí sí ọ ní etí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ ní orí.
13 And thou were ourned with gold and siluer, and thou were clothid with biys and ray cloth with rounde ymagis, and many colours. Thou etist cleene flour of wheete, and hony, and oile, and thou were maad fair ful greetli; and thou encreessidist in to a rewme,
Báyìí ni mo ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà; tí aṣọ rẹ jẹ́ funfun gbòò, aṣọ olówó iyebíye àti aṣọ tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí. Ìyẹ̀fun kíkúnná, oyin àti òróró ni oúnjẹ rẹ. Ó di arẹwà títí ó fi dé ipò ayaba.
14 and thi name yede out in to hethene men for thi fairnesse; for thou were perfit in my fairnesse which Y hadde sett on thee, seith the Lord God.
Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀-èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ ní àṣepé, ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 And thou haddist trist in thi fairnesse, and didist fornicacioun in thi name; and thou settidist forth thi fornicacioun to ech that passide forth, that thou schuldist be maad his.
“‘Ṣùgbọ́n, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, ìwọ sì di alágbèrè nítorí òkìkí rẹ. Ìwọ sì fọ́n ojúrere rẹ káàkiri sí orí ẹni yówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.
16 And thou tokist of my clothis, and madist to thee hiy thingis set aboute on ech side; and thou didist fornycacioun on tho, as it was not don, nether schal be don.
Ìwọ mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi gíga òrìṣà tí ìwọ ti ń ṣe àgbèrè. Èyí kò yẹ kí ó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.
17 And thou tokist the vessels of thi fairnesse, of my gold and of my siluer, which Y yaf to thee; and thou madist to thee ymagis of men, and didist fornycacioun in tho.
Ìwọ tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.
18 And thou tokist thi clothis of many colours, and thou were clothid in tho; and thou settidist myn oile and myn encence in the siyt of tho.
Ìwọ sì wọ aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.
19 And thou settidist my breed, which Y yaf to thee, flour of wheete, and oile, and hony, bi whiche Y nurschide thee, in the siyt of tho, in to odour of swetnesse; and it was don, seith the Lord God.
Ìwọ tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ—ìyẹ̀fun dáradára, òróró àti oyin—fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.
20 And thou tokist thi sones and thi douytris, whiche thou gendridist to me, and offridist to tho, for to be deuourid. Whether thi fornicacioun is litil?
“‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rú ẹbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?
21 Thou offridist my sones, and yauest hem, and halewidist to tho.
Tí ìwọ ti pa àwọn ọmọ mí, ìwọ sì fà wọ́n fún ère gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun.
22 And aftir alle thin abhomynaciouns and fornicaciouns, thou bithouytist not on the daies of thi yong wexynge age, whanne thou were nakid, and ful of schenschipe, and were defoulid in thi blood.
Nínú gbogbo iṣẹ́ ìríra àti ìwà àgbèrè rẹ, ìwọ kò rántí ìgbà èwe rẹ, nígbà tí ìwọ wà ní ìhòhò, tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀.’
23 And after al thi malice, wo, wo bifelle to thee, seith the Lord God.
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Ègbé! Ègbé ni fún ọ. Lẹ́yìn gbogbo ìwà búburú rẹ,
24 And thou bildidist to thee a bordel hous, and madist to thee a place of hordom in alle stretis.
ìwọ kọ́lé amọ̀ fún ara rẹ, ìwọ sì kọ́ ojúbọ gíga sí gbogbo òpin ojú pópó.
25 At ech heed of the weie thou bildidist a signe of thin hordom, and madist thi fairnesse abhomynable; and thou departidist thi feet to ech man passynge forth, and multepliedist thi fornicaciouns.
Ní gbogbo ìkóríta ni ìwọ lọ kọ ojúbọ gíga sí, tí ìwọ sọ ẹwà rẹ di ìkórìíra, ìwọ sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ nípa fífi ara rẹ sílẹ̀ fún gbogbo ẹni tó ń kọjá lọ.
26 And thou didist fornicacioun with the sones of Egipt, thi neiyboris of grete fleischis, and thou multepliedist thi fornicacioun, to terre me to wraththe.
Ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Ejibiti tí í ṣe aládùúgbò rẹ láti mú mi bínú ìwọ sì ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀.
27 Lo! Y schal stretch forth myn hond on thee, and Y schal take awei thi iustifiyng; and Y schal yyue thee in to the soulis of hem that haten thee, of the douytris of Palestyns, that ben aschamed in thi weie ful of greet trespas.
Nítorí náà ni mo fi na ọwọ́ mi lé ọ lórí, mo sì ti bu oúnjẹ rẹ̀ kù; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to kórìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Filistini ti ìwàkiwà rẹ tì lójú.
28 And thou didist fornicacioun with the sones of Assiriens, for thou were not fillid yit; and after that thou didist fornicacioun, nether so thou were fillid.
Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ, ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara Asiria; ìwọ ti bá wọn ṣe àgbèrè, síbẹ̀síbẹ̀, kò sì lè tẹ́ ọ lọ́rùn.
29 And thou multipliedist thi fornycacioun in the lond of Canaan with Caldeis, and nether so thou were fillid.
Ìwọ si ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ láti ilẹ̀ Kenaani dé ilẹ̀ Kaldea; síbẹ̀ èyí kò sì tẹ́ ọ lọ́rùn níhìn-ín yìí.’
30 In what thing schal Y clense thin herte, seith the Lord God, whanne thou doist alle these werkis of a womman an hoore, and gredi axere?
“Olúwa Olódùmarè wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbèrè!
31 For thou madist thi bordel hous in `the heed of ech weie, and thou madist thin hiy place in ech street; and thou were not maad as an hoore ful of anoiyng,
Ni ti pé ìwọ kọ́ ilé gíga rẹ ni gbogbo ìkóríta, tí ìwọ sì ṣe gbogbo ibi gíga rẹ ni gbogbo ìta, ìwọ kò sì wa dàbí panṣágà obìnrin, ní ti pé ìwọ gan ọ̀yà.
32 encreessynge prijs, but as a womman auowtresse, that bryngith in aliens on hir hosebonde.
“‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!
33 Hiris ben youun to alle hooris, but thou hast youe hire to alle thi louyeris; and thou yauest to hem, that thei schulden entre to thee on ech side, to do fornycacioun with thee.
Àwọn ọkùnrin máa ń sanwó fún àwọn panṣágà ni ṣùgbọ́n ìwọ lo tún ń sanwó fun wọn, tí ó tún ń fún àwọn olólùfẹ́ rẹ lẹ́bùn àti owó ẹ̀yìn kí wọn bá à le máa wá ọ wá láti gbogbo agbègbè fún àgbèrè ṣíṣe.
34 And it was don in thee ayens the custom of wymmen in thi fornycaciouns, and fornicacioun schal not be after thee; for in that that thou yauest hiris, and tokist not hiris, the contrarie was don in thee.
Nínú àgbèrè rẹ ìwọ yàtọ̀ sí àwọn alágbèrè obìnrin yòókù; nínú àgbèrè rẹ tí ẹnìkan kò tẹ̀lé ọ láti ṣe àgbèrè; àti ní ti pé ìwọ ń tọrẹ tí a kò sì tọrẹ fún ọ, nítorí náà ìwọ yàtọ̀.
35 Therfor, thou hoore, here the word of the Lord.
“‘Nítorí náà, ìwọ alágbèrè, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
36 The Lord God seith these thingis, For thi riches is sched out, and thi schenschipe is schewid in thi fornicaciouns on thi louyeris, and on the idols of thin abhomynaciouns, in the blood of thi sones, whiche thou yauest to hem; lo!
Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, “Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ́ rẹ, àti nítorí gbogbo òrìṣà ìríra tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,
37 Y schal gadere to gidere alle thi louyeris, with whiche thou were meddlid, and alle men whiche thou louedist, with alle men whiche thou hatidist; and Y schal gadere hem on thee on ech side, and Y schal make nakid thi schenschipe bifore hem, and thei schulen se al thi filthe.
nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, àwọn ẹni ti ìwọ ti bá jayé àti gbogbo àwọn tí ìwọ ti fẹ́ àti àwọn tí ìwọ kórìíra. Èmi yóò sa gbogbo wọn káàkiri jọ, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòhò rẹ.
38 And Y schal deme thee bi the domes of auoutressis, and schedinge out blood;
Èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbéyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.
39 and Y schal yyue thee in to the blood of strong veniaunce, and of feruour. And Y schal yyue thee in to the hondis of hem, and thei schulen destrie thi bordel hous, and thei schulen destrie the place of thin hordom; and thei schulen make thee nakid of thi clothis, and thei schulen take awei the vessels of thi fairnesse, and thei schulen forsake thee nakid, and ful of schenschipe.
Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòhò àti ní àìwọṣọ.
40 And thei schulen bringe on thee a multitude, and thei schulen stoon thee with stoonys, and thei schulen sle thee with her swerdis.
Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, tiwọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.
41 And thei schulen brenne thin housis with fier, and thei schulen make domes in thee, bifor the iyen of ful many wymmen; and thou schalt ceese to do fornicacioun, and thou schalt no more yyue hiris.
Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.
42 And myn indignacioun schal reste in thee, and my feruent loue schal be takun awei fro thee; and Y schal reste, and Y schal no more be wrooth,
Nígbà náà ni ìbínú mi sí o yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ̀, èmi kò sì ní bínú mọ́.”
43 for thou haddist not mynde on the daies of thi yong wexynge age, and thou terridist me to ire in alle these thingis. Wherfor and Y yaf thi weies in thin heed, seith the Lord God, and Y dide not aftir thi grete trespassis, in alle these thin abhomynaciouns.
“‘Nítorí pé ìwọ kò rántí ọjọ́ èwe rẹ ṣùgbọ́n ìwọ ń rí mi fín pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ó dájú pé, Èmi yóò mú gbogbo ohun tí ìwọ ti ṣe wa sí orí rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí, ìwọ kì yóò sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ yìí ni orí gbogbo ohun ìríra rẹ mọ́?
44 Lo! ech man that seith a prouerbe comynli, schal take it in thee,
“‘Gbogbo àwọn to ń pòwe, ni yóò máa pòwe yìí mọ́ ọ pé: “Bí ìyá ṣe rí, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ rẹ̀ obìnrin.”
45 and schal seie, As the modir, so and the douytir of hir. Thou art the douyter of thi modir, that castide awey hir hosebonde and hir sones; and thou art the sister of thi sistris, that castiden a wei her hosebondis and her sones. Thi modir is Cetei, and thi fadir is Ammorrei;
Ìwọ ni ọmọ ìyá rẹ ti ó kọ ọkọ rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀; ìwọ ni arábìnrin àwọn arábìnrin rẹ tí ó kọ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn: ara Hiti ni ìyá rẹ, ara Amori sì ni baba rẹ.
46 and thi gretter sister is Samarie, sche and hir douytris, that dwellen at thi left side; but thi sistir lesse than thou, that dwellith at thi riyt side, is Sodom, and hir douytris.
Ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin ni Samaria, òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ n gbé ni apá àríwá rẹ, àti àbúrò rẹ obìnrin ní ń gbé ọwọ́ òsì rẹ̀, àti àbúrò rẹ obìnrin ti ń gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ obìnrin.
47 But thou yedist not in the weies of hem, nethir thou didist aftir the grete trespassis of hem; hast thou do almest a litil lesse cursidere dedis than thei, in alle thi weies?
Kì í sẹ pé ìwọ rìn ni ọ̀nà wọn nìkan, tàbí ṣe àfiwé ìwà ìríra wọn ṣùgbọ́n ní àárín àkókò kúkúrú díẹ̀, ìwọ bàjẹ́ jù wọ́n lọ
48 Y lyue, seith the Lord God, for Sodom, thi sister, did not, sche and hir douytris, as thou didist, and thi douytris.
Olúwa Olódùmarè wí pé, “Bí mo ṣe wà láààyè, Sodomu tí í ṣe ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ kò ṣe to ohun tí ìwọ àti ọmọbìnrin rẹ ṣe.”
49 Lo! this was the wickidnesse of Sodom, thi sister, pride, fulnesse of breed, and habundaunce, and idilnesse of hir, and of hir douytris; and thei puttiden not hond to a nedi man and pore.
“‘Wò ó, ẹ̀ṣẹ̀ tí Sodomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin ṣẹ̀ nìyìí. Òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ gbéraga, wọ́n jẹ́ alájẹjù àti aláìbìkítà; wọn kò ran tálákà àti aláìní lọ́wọ́.
50 And thei weren enhaunsid, and diden other abhominaciouns bifore me; and Y took hem awei, as thou hast seyn.
Nítorí náà, mo mu wọn kúrò níwájú mi lójú mi gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti rò ó, nítorí ìgbéraga àti àwọn ohun ìríra tí wọ́n ṣe.
51 And Samarie synnede not the half of thi synnes, but thou hast ouercome hem in thi grete trespassis; and thou hast iustified thi sistris in alle thin abhomynaciouns, whiche thou wrouytist.
Samaria kò ṣe ìdajì ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Ìwọ ṣe àwọn ohun ìríra ju tirẹ̀ lọ, ìwọ sì jẹ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo pẹ̀lú gbogbo ìwọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe.
52 Therfor and thou bere thi schenschipe, that hast ouercome thi sistris with thi synnes, and didist more cursidli than thei; for thei ben iustified of thee. Therfor and be thou schent, and bere thi schenschipe, which hast iustified thi sistris.
Gba ìtìjú rẹ, nítorí ìwọ ti jẹ́ kí arábìnrin rẹ gba ìdáláre. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti burú ju tí wọn lọ, wọn dàbí olódodo ju ìwọ lọ. Nítorí náà rú ìtìjú rẹ, kí o sì gba ẹ̀gàn rẹ pẹ̀lú nítorí ìwọ ti jẹ́ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo.
53 And Y schal conuerte and restore hem by the conuersioun of Sodom with hir douytris, and bi the conuersioun of Samarie and of hir douytris; and Y schal conuerte thi turnyng ayen in the myddis of hem,
“‘Bi o tilẹ̀ jẹ pe èmi yóò mú ìgbèkùn wọn padà, ìgbèkùn Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, pẹ̀lú Samaria àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, nígbà náà ni èmi yóò tún mú ìgbèkùn àwọn òǹdè rẹ wá láàrín wọn,
54 that thou bere thi schenschipe, and be aschamed in alle thingis whiche thou didist, coumfortynge hem.
kí ó bá à le rú ìtìjú rẹ, àti ẹ̀gàn gbogbo ohun tí ìwọ ṣe láti tù wọ́n nínú.
55 And thi sister Sodom and hir doytris schulen turne ayen to her eldnesse; and Samarie and hir douytris shulen turne ayen to her eeldnesse; and thou and thi douytris turne ayen to youre eldnesse.
Nígbà tí àwọn arábìnrin rẹ, Sodomu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ; Samaria àti àwọn ọmọbìnrin rẹ ba padà si ipò tí wọn wà tẹ́lẹ̀, ìgbà náà ni ìwọ náà yóò padà sí ipò àtijọ́ rẹ.
56 Forsothe Sodom, thi sister, was not herd in thi mouth, in the dai of thi pride,
Ìwọ ko tilẹ̀ ní dárúkọ arábìnrin rẹ Sodomu ni ọjọ́ ìgbéraga rẹ,
57 bifore that thi malice was schewid, as in this tyme, in to schenschipe of the douytris of Sirie, and of alle douytris in thi cumpas, of the douytris of Palestyn that ben aboute thee bi cumpas.
kó tó di pé àṣírí ìwà búburú rẹ tú síta, báyìí ìwọ di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Edomu, Siria àti gbogbo agbègbè rẹ, àti lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Filistini àti lọ́dọ̀ àwọn tó yí ọ ká, tiwọn si ń kẹ́gàn rẹ.
58 Thou hast bore thi greet trespas, and thi schenschipe, seith the Lord God.
Èmi yóò gba ẹ̀san ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti àwọn iṣẹ́ ìríra rẹ ní Olúwa wí.’
59 For the Lord God seith these thingis, And Y schal do to thee as thou dispisidist the ooth, that thou schuldist make voide the couenaunt;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Èmi yóò hùwà sí ọ gẹ́gẹ́ bi ó ṣe tọ́ sí ọ, nítorí ó ti kẹ́gàn ẹ̀jẹ́ nípa dídà májẹ̀mú.
60 and Y schal haue mynde on my couenaunt with thee in the daies of thi yongthe, and Y schal reise to thee a couenaunt euerlastynge.
Síbẹ̀ èmi yóò rántí májẹ̀mú tí mo bá ọ ṣe nígbà èwe rẹ, èmi yóò sì bá ọ dá májẹ̀mú láéláé.
61 And thou schalt haue mynde on thi weies, and schalt be aschamed, whanne thou schalt resseyue thi sistris grettere than thou, with thi lesse sistris; and Y schal yyue hem in to douytris to thee, but not of thi couenaunt.
Nígbà náà ni ìwọ yóò rántí àwọn ọ̀nà rẹ ojú yóò sì tì ọ́ nígbà tí mo bá gba àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ obìnrin padà. Fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọmọbìnrin, ṣùgbọ́n kì í ṣe lórí májẹ̀mú tí mo bá ọ dá.
62 And Y schal reise my couenaunt with thee, and thou schalt wite, that Y am the Lord, that thou haue mynde, and be aschamed;
Èmi yóò gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì mọ pé èmi ni Olúwa.
63 and that it be no more to thee to opene the mouth for thi schame, whanne Y schal be plesid to thee in alle thingis whiche thou didist, seith the Lord God.
Nígbà tí mo bá sì ti ṣe ètùtù fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tan, Èmi yóò sì rántí, ojú yóò tì ọ́, ìwọ kò sì ní le ya ẹnu rẹ mọ́ nítorí ìtìjú rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Ezekiel 16 >