< Exodus 6 >

1 And the Lord seide to Moises, Now thou schalt se, what thingis Y schal do to Farao; for bi strong hond he schal delyuere hem, and in myyti hond he schal caste hem out of his lond.
Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
2 And the Lord spak to Moises,
Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
3 and seide, Y am the Lord, that apperide to Abraham, and to Isaac, and to Jacob in Almyyti God; and Y schewide not to hem my greet name Adonai;
Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
4 and Y made couenaunt with hem, that Y schulde yyue to hem the lond of Canaan, the lond of her pilgrymage, in which thei weren comelyngis.
Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
5 Y herde the weilyng of the sones of Israel, in which the Egipcians oppresseden hem, and Y hadde mynde of my couenaunt.
Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
6 Therfor seie thou to the sones of Israel, Y am the Lord, that schal lede out you of the prisoun of Egipcians; and Y schal delyuere fro seruage; and Y schal ayen bie in `an hiy arm, and in grete domes;
“Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
7 and Y schal take you to me in to a puple, and Y schal be youre God; and ye schulen wite, for Y am youre Lord God, `which haue led you out of the prisoun of Egipcians,
Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
8 and haue led you in to the lond, on which Y reiside myn hond, that Y schulde yyue it to Abraham, and to Ysaac, and to Jacob; and Y schal yyue to you that lond to be weldid; I the Lord.
Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
9 Therfor Moises telde alle thingis to the sones of Irael, whiche assentide not to hym for the angwisch of spirit, and for the hardest werk.
Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
10 And the Lord spak to Moises,
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
11 and seide, Entre thou, and speke to Farao, kyng of Egipt, that he delyuere the children of Israel fro his lond.
“Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
12 Moises answeride bifore the Lord, Lo! the children of Israel here not me, and hou schal Farao here, moost sithen Y am vncircumcidid in lippis?
Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
13 And the Lord spak to Moises and to Aaron, and yaf comaundementis to the sones of Israel, and to Farao, kyng of Egipt, that thei schulden lede out the sones of Israel fro the lond of Egipt.
Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
14 These ben the princis of housis bi her meynees. The sones of Ruben, the firste gendrid of Israel, Enoch, and Fallu, Esrom, and Charmy; these ben the kynredis of Ruben.
Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
15 The sones of Symeon, Jamuel, and Jamyn, and Aod, and Jachym, and Soer, and Saul, the sone of a womman of Canaan; these ben the kynretis of Symeon.
Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
16 And these ben the names of the sones of Leuy by her kynredis, Gerson, and Caath, and Merary. Forsothe the yeeris of lijf of Leuy weren an hundrid and seuene and thretti.
Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
17 The sones of Gerson, Lobny and Semei, bi her kynredis.
Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
18 The sones of Caath, Amram, and Isuar, and Hebron, and Oziel; and the yeeris of lijf of Caath weren an hundrid and thre and thretti.
Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
19 The sones of Merari weren Mooli and Musi. These weren the kynredis of Leuy bi her meynees.
Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
20 Forsothe Amram took a wijf, Jocabed, douytir of his fadris brother, and sche childide to hym Aaron, and Moises, and Marie; and the yeeris of lijf of Amram weren an hundred and seuene and thretti.
Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
21 Also the sones of Isuar weren Chore, and Nafeg, and Zechry.
Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
22 Also the sones of Oziel weren Misael, and Elisaphan, and Sechery.
Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
23 Sotheli Aaron took a wijf, Elizabeth, the douytir of Amynadab, the sistir of Naason, and sche childide to hym Nadab, and Abyu, and Eleazar, and Ythamar.
Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
24 Also the sones of Chore weren Aser, and Elcana, and Abiasab; thes weren the kinredis of Chore.
Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
25 And sotheli Eleazar, sone of Aaron, took a wijf of the douytris of Phatiel, and sche childide Fynees to hym. These ben the princis of the meynees of Leuy bi her kynredis.
Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
26 This is Aaron and Moises, to whiche the Lord comaundide, that thei schulden lede out of the lond of Egipt the sones of Israel by her cumpanyes;
Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
27 these it ben, that speken to Pharao king of Egipt, that thei lede the sones of Israel out of Egipt;
Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
28 this is Moises and Aaron, in the dai in which the Lord spak to Moises in the lond of Egipt.
Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
29 And the Lord spak to Moises, and seide, Y am the Lord; spek thou to Farao, kyng of Egipt, alle thingis whiche Y speke to thee.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
30 And Moises seide bifore the Lord, Lo! Y am vncircumcidid in lippis; hou schal Farao here me?
Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”

< Exodus 6 >