< Exodus 1 >

1 These ben the names of the sones of Israel, that entriden into Egipt with Jacob; alle entriden with her housis;
Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
2 Ruben, Symeon,
Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
3 Leuy, Judas, Isachar, Zabulon, and Benjamin,
Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
4 Dan, and Neptalim, Gad, and Aser.
Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
5 Therfor alle the soules of hem that yeden out of `the hipe of Jacob weren seuenti and fyue.
Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
6 Forsothe Joseph was in Egipt; and whanne he was deed, and alle hise brithren, and al his kynrede,
Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
7 the sones of Israel encreessiden, and weren multiplied as buriounnyng, and thei weren maad strong greetli, and filliden the lond.
ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
8 A newe kyng, that knewe not Joseph, roos in the meene tyme on Egipt, and seide to his puple, Lo!
Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
9 the puple of the sones of Israel is myche, and strongere than we;
Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
10 come ye, wiseli oppresse we it, lest perauenture it be multiplied; and lest, if batel risith ayens vs, it be addid to oure enemyes, and go out of the lond, whanne we ben ouercomun.
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
11 And so he made maistris of werkis souereyns to hem, that thei schulden turmente hem with chargis. And thei maden citees of tabernaclis to Farao, Fiton, and Ramesses.
Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
12 And bi hou myche thei oppressiden hem, bi so myche thei weren multiplied, and encreessiden more.
Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
13 And Egipcians hatiden the sones of Israel, and turmentiden, and scorneden hem;
Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
14 and brouyten her lijf to bitternesse bi hard werkis of cley and to tijl stoon, and bi al seruage, bi which thei weren oppressid in the werkis of erthe.
Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
15 Forsothe the kyng of Egipt seide to the mydwyues of Ebrews, of whiche oon was clepid Sefora, the tother Fua;
Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
16 and he commaundide to hem, Whanne ye schulen do the office of medewyues to Ebrew wymmen, and the tyme of childberyng schal come, if it is a knaue child, sle ye him; if it is a womman, kepe ye.
“Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
17 Forsothe the medewyues dredden God, and diden not bi the comaundement of the kyng of Egipt, but kepten knaue children.
Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
18 To whiche clepid to hym the kyng seide, What is this thing which ye wolden do, that ye wolden kepe the children?
Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
19 Whiche answeriden, Ebrew wymmen ben not as the wymmen of Egipt, for thei han kunnyng of the craft of medewijf, and childen bifore that we comen to hem.
Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
20 Therfor God dide wel to medewyues; and the puple encreesside, and was coumfortid greetli.
Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
21 And for the mydewyues dredden God, he bildide `housis to hem.
Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
22 Therfor Farao comaundide al his puple, and seide, What euer thing of male kynde is borun to Ebrewis, `caste ye into the flood; what euer thing of wymmen kynde, kepe ye.
Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”

< Exodus 1 >