< Daniel 1 >

1 In the thridde yeer of the rewme of Joachym, king of Juda, Nabugodonosor, the kyng of Babiloyne, cam to Jerusalem, and bisegide it.
Ní ọdún kẹta tí Jehoiakimu jẹ ọba Juda, Nebukadnessari ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kọlù ú pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
2 And the Lord bitook in his hond Joachym, the kyng of Juda, and he took a part of the vessels of the hous of God; and he bar out tho in to the lond of Sennaar, in to the hous of his god, and he took the vessels in to the hous of tresour of his god.
Olúwa sì fa Jehoiakimu ọba Juda lé e lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run. Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó lọ sí ilé òrìṣà ní Babeli, sí inú ilé ìṣúra òrìṣà rẹ̀.
3 And the kyng seide to Asphaneth, souereyn of his onest seruauntis and chast, that he schulde brynge yn of the sones of Israel, and of the kyngis seed, and the children of tirauntis, in whiche weren no wem,
Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Aṣipenasi, olórí àwọn ìwẹ̀fà ààfin rẹ̀ pé, kí ó mú nínú àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n wá láti ìdílé ọba àti lára àwọn tí ó wá láti ilé ọlá.
4 faire in schap, and lerned in al wisdom, war in kunnyng, and tauyt in chastisyng, and that myyten stonde in the paleis of the kyng, that he schulde teche hem the lettris and langage of Caldeis.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí kò ní àbùkù ara, tí wọ́n rẹwà, tí wọ́n sì fi ìfẹ́ sí ẹ̀kọ́ hàn, tí wọ́n sì ní ìmọ̀, tí òye tètè ń yé àti àwọn tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ṣiṣẹ́ ní ààfin ọba kí ó kọ́ wọ́n ní èdè àti onírúurú ẹ̀kọ́ ìwé ti àwọn Babeli.
5 And the king ordeynede to hem lijflode bi ech dai of hise meetis, and of the wyn wherof he drank; that thei nurschid bi thre yeer, schulden stonde aftirward bifor the siyt of the kyng.
Ọba pèsè oúnjẹ ojoojúmọ́ àti wáìnì láti orí tábìlì i rẹ̀ fún wọn, ó sì kọ́ wọn fún ọdún mẹ́ta. Lẹ́yìn náà ni wọn yóò bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiṣẹ́ fún ọba.
6 Therfor Danyel, Ananye, Myzael, and Azarie, of the sones of Juda, weren among hem.
Lára àwọn wọ̀nyí ni àwọn tó wá láti Juda: Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah.
7 And the souereyn of onest seruauntis and chast puttide to hem names; to Danyel he puttide Balthasar; to Ananye, Sidrach; to Mysael, Misach; and to Azarie, Abdenago.
Olórí àwọn ìwẹ̀fà fún wọn ní orúkọ tuntun: Ó fún Daniẹli ní Belteṣassari, ó fún Hananiah ní Ṣadraki, ó fún Miṣaeli ní Meṣaki àti Asariah ní Abednego.
8 Forsothe Danyel purposide in his herte, that he schulde not be defoulid of the boord of the kyng, nether of the wyn of his drink; and he preiede the souereyn of onest seruauntis and chast, that he schulde not be defoulid.
Ṣùgbọ́n Daniẹli pinnu ní ọkàn ara rẹ̀ pé òun kò ní ba ara òun jẹ́ pẹ̀lú oúnjẹ àti wáìnì ọba, nígbà náà ni ó gba ààyè lọ́wọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà wí pé òun kò fẹ́ ba ara òun jẹ́ ní ọ̀nà yìí.
9 Forsothe God yaf grace and merci to Daniel, in the siyt of the prince of onest seruauntis and chast.
Ọlọ́run mú kí Daniẹli rí ojúrere àti àánú gbà láti ọwọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà,
10 And the prince of onest seruauntis and chast seide to Daniel, Y drede my lord the king, that ordeinede to you mete and drynk; and if he seeth youre faces lennere than othere yonge wexynge men, youre eueneeldis, ye schulen condempne myn heed to the kyng.
ṣùgbọ́n olórí àwọn ìwẹ̀fà sọ fún Daniẹli pé, “Mo bẹ̀rù olúwa mi, ẹni tí o ti pèsè oúnjẹ àti ohun mímu rẹ. Báwo ni ìrísí rẹ yóò ṣe burú jù ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ẹlẹgbẹ́ ẹ̀ rẹ lọ? Nígbà náà ni èmi yóò fi orí mi wéwu lọ́dọ̀ ọba.”
11 And Danyel seide to Malazar, whom the prince of onest seruauntis and chast hadde ordeynede on Danyel, Ananye, Mysael, and Asarie,
Nígbà náà ni Daniẹli sọ fún olùṣọ́ tí olórí àwọn ìwẹ̀fà yàn lórí i Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah pé,
12 Y biseche, asaie thou vs thi seruauntis bi ten daies, and potagis be youun to vs to ete, and water to drynke; and biholde thou oure cheris,
“Jọ̀wọ́ dán àwa ìránṣẹ́ rẹ wò fún ọjọ́ mẹ́wàá. Má ṣe fún wa ní ohun kankan, àfi ewébẹ̀ láti jẹ àti omi láti mu.
13 and the cheris of children that eten the kyngis mete; and as thou seest, so do thou with thi seruauntis.
Nígbà náà ni kí o fi ìrísí i wa wé ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba, kí o sì ṣe àwa ìránṣẹ́ rẹ ní ìbámu pẹ̀lú u bí o bá ṣe rí i sí.”
14 And whanne he herde siche a word, he asaiede hem bi ten daies.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì gbà láti dán wọn wò fún ọjọ́ mẹ́wàá.
15 Forsothe after ten daies the cheris of hem apperiden betere and fattere, than alle the children that eeten the kyngis mete.
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹwàá ara wọn le, wọ́n sì sanra ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba lọ.
16 Certis Malazar took the metis, and the wyn of the drynk of hem, and yaf to hem potagis.
Bẹ́ẹ̀ ni olùṣọ́ mú oúnjẹ àdídùn àti wáìnì tí ó yẹ kí wọ́n mu kúrò, ó sì fún wọn ní ewébẹ̀ dípò rẹ̀.
17 Forsothe to these children God yaf kunnyng and lernyng in ech book, and in al wisdom; but to Daniel God yaf vndurstondyng of alle visiouns and dremys.
Ọlọ́run fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ní ìmọ̀ àti òye nínú gbogbo onírúurú ìwé àti ẹ̀kọ́ ọ wọn: Daniẹli sì ní òye ìran àti àlá ní oríṣìíríṣìí.
18 Therfor whanne the daies weren fillid, aftir whiche the kyng seide, that thei schulden be brouyt yn, the souereyn of onest seruauntis and chast brouyte in hem, in the siyt of Nabugodonosor.
Ní òpin ìgbà tí ọba dá, pé kí a mú wọn wá sínú ààfin, olórí àwọn ìwẹ̀fà mú wọn wá síwájú ọba Nebukadnessari.
19 And whanne the kyng hadde spoke to hem, siche weren not foundun of alle, as Daniel, Ananye, Misael, and Azarie; and thei stoden in the siyt of the king.
Ọba sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì rí i pé kò sí ẹni tí ó dàbí i Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah; nítorí náà wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣe iṣẹ́ ọba.
20 And ech word of wisdom and of vndurstondyng, which the king axide of hem, he foond in hem ten fold ouer alle false dyuynouris and astronomyens, that weren in al his rewme.
Nínú gbogbo ọ̀ràn ọgbọ́n àti òye tí ọba ń béèrè lọ́wọ́ wọn, ó rí i pé wọ́n sàn ní ìlọ́po mẹ́wàá ju gbogbo àwọn amòye àti ọlọ́gbọ́n tí ó wà ní gbogbo ìjọba rẹ̀.
21 Forsothe Danyel was til to the firste yeer of king Cyrus.
Daniẹli sì wà níbẹ̀ títí di ọdún kìn-ín-ní ọba Kirusi.

< Daniel 1 >