< Daniel 9 >

1 In the firste yeer of Darius, the sone of Assuerus, of the seed of Medeis, that was emperour on the rewme of Caldeis,
Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ọmọ Ahaswerusi, ẹni tí a bí ní Media, òun ló jẹ ọba lórí ìjọba Babeli.
2 in the firste yeer of his rewme, Y, Danyel, vndurstood in bookis the noumbre of yeeris, of which noumbre the word of the Lord was maad to Jeremye, the profete, that seuenti yeer of desolacioun of Jerusalem schulde be fillid.
Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, èmi Daniẹli fi iyè sí i láti inú ìwé, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí wòlíì Jeremiah, wá pé, àádọ́rin ọdún ni Jerusalẹmu yóò fi wà ní ahoro.
3 And Y settide my face to my Lord God, to preie and to biseche in fastyngis, in sak, and aische.
Nígbà náà, ni mo yípadà sí Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ẹ́ pẹ̀lú àdúrà àti ẹ̀bẹ̀, pẹ̀lú àwẹ̀, aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
4 And Y preiede my Lord God, and Y knoulechide, and seide, Y biseche, thou Lord God, greet and ferdful, kepynge couenaunt and mercy to hem that louen thee, and kepen thi comaundementis.
Mo gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run mi, mo sì jẹ́wọ́ wí pé: “Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó ní ìfẹ́ rẹ̀ àti àwọn tí ó ń pa àwọn òfin rẹ̀ mọ́.
5 We han synned, we han do wickidnesse, we diden unfeithfuli, and yeden awei, and bowiden awei fro thi comaundementis and domes.
Àwa ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú. Àwa ti hu ìwà búburú, a sì ti ṣe ọ̀tẹ̀, a ti yí padà kúrò nínú àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà rẹ̀.
6 We obeieden not to thi seruauntis, profetis, that spaken in thi name to oure kyngis, to oure princes, and to oure fadris, and to al the puple of the lond.
Àwa kò fetí sí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ sí àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé àti àwọn baba wa, àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà.
7 Lord, riytfulnesse is to thee, forsothe schenschipe of face is to vs, as is to dai to a man of Juda, and to the dwelleris of Jerusalem, and to al Israel, to these men that ben niy, and to these men that ben afer in alle londis, to which thou castidist hem out for the wickidnessis of hem, in whiche, Lord, thei synneden ayens thee.
“Olúwa ìwọ ni olódodo, ṣùgbọ́n báyìí ìtìjú dé bá àwọn ènìyàn Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti gbogbo Israẹli ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti fọ́n wa ká sí nítorí àìṣòótọ́ ọ wa sí ọ.
8 Schame of face is to vs, to oure kyngis, to oure princes, and to oure fadris, that synneden;
Háà! Olúwa, àwa àti àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé, àti àwọn baba wa, ìtìjú dé bá wa nítorí àwa ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
9 but merci and benygnytee is to thee, oure Lord God. For we yeden awei fro thee,
Olúwa Ọlọ́run wa ní àánú, ó sì ń dáríjì, bí àwa tilẹ̀ ti ṣe ọ̀tẹ̀ sí i;
10 and herden not the vois of oure Lord God, that we schulden go in the lawe of hym, whiche he settide to vs bi hise seruauntis, profetis.
àwa kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, a kò sì pa àwọn òfin rẹ mọ́, èyí tí ó fún wa nípasẹ̀ àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
11 And al Israel braken thi lawe, and bowiden awei, that thei herden not thi vois; and cursyng, and wlatyng, which is writun in the book of Moises, the seruaunt of God, droppide on vs, for we synneden to hym.
Gbogbo Israẹli ti ṣẹ̀ sí òfin rẹ, wọ́n ti yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, wọ́n kọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ. “Nígbà náà ni ègún àti ìdájọ́ tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú ìbúra nínú òfin Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run dà sórí i wa, nítorí tí àwa ti sẹ̀ sí ọ.
12 And he ordeynede hise wordis, whiche he spak on vs, and on oure princes, that demyden vs, that thei schulden brynge in on vs greet yuel, what maner yuel was neuer vndur al heuene, bi that that is doon in Jerusalem,
Ìwọ ti mú ọ̀rọ̀ tí o sọ sí wa sẹ àti lórí àwọn alákòóso wa, nípa mímú kí ibi ńlá bá wa, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí lábẹ́ ọ̀run, bí ó ti ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu yìí.
13 as it is writun in the lawe of Moises. Al this yuel cam on vs, and, oure Lord God, we preieden not thi face, that we schulden turne ayen fro oure wickidnessis, and schulden thenke thi treuthe.
Bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Mose bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ibi yìí ti dé bá wa, síbẹ̀ a kò bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run wa, nípa yíyí padà kí a kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wa kí a sì mọ òtítọ́ rẹ.
14 And the Lord wakide on malice, and brouyt it on vs; oure Lord God is iust in alle his werkis whiche he made, for we herden not his vois.
Olúwa kò jáfara láti mú ibi náà wá sórí wa, nítorí olódodo ni Olúwa Ọlọ́run wa nínú u gbogbo ohun tí ó ń ṣe; síbẹ̀ àwa kò ṣe ìgbọ́ràn sí i.
15 And now, Lord God, that leddist thi puple out of the lond of Egipt in strong hond, and madist to thee a name bi this dai, we han synnede,
“Ní ìsinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, pẹ̀lú ọwọ́ agbára, tí ó fún ara rẹ̀ ní orúkọ tí ó wà títí di òní, a ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú.
16 we han do wickidnesse, Lord, ayens thi riytfulnesse. Y biseche, thi wraththe and thi stronge veniaunce be turned awey fro thi citee Jerusalem, and fro thi hooli hil; for whi for oure synnes, and for the wickidnessis of oure fadris, Jerusalem and thi puple ben in schenschipe, to alle men bi oure cumpas.
Olúwa, ní ìbámu pẹ̀lú ìwà òdodo rẹ, yí ìbínú àti ìrunú rẹ padà kúrò ní Jerusalẹmu ìlú u rẹ, òkè mímọ́ rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa ti mú Jerusalẹmu àti ènìyàn rẹ di ẹ̀gàn fún gbogbo àwọn tí ó yí wọn ká.
17 But now, oure God, here thou the preyer of thi seruaunt, and the bisechyngis of him, and schewe thi face on thi seyntuarie, which is forsakun.
“Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, nítorí i tìrẹ Olúwa, fi ojú àánú wo ibi mímọ́ rẹ tí ó ti dahoro.
18 My God, for thi silf boowe doun thin eere, and here; opene thin iyen, and se oure desolacioun, and the citee, on which thi name is clepid to help. For not in oure iustifiyngis we setten forth mekeli preiers bifor thi face, but in thi many merciful doyngis.
Tẹ́ etí rẹ sílẹ̀, Ọlọ́run, kí o gbọ́; ya ojú rẹ sílẹ̀, kí o sì wo ìdahoro ìlú tí a ń fi orúkọ rẹ pè. Àwa kò gbé ẹ̀bẹ̀ wa kalẹ̀ níwájú u rẹ nítorí pé a jẹ́ olódodo, bí kò ṣe nítorí àánú ńlá rẹ.
19 Lord, here thou; Lord, be thou plesid, perseyue thou, and do; my Lord God, tarie thou not, for thi silf, for thi name is clepid to help on the citee, and on thi puple.
Olúwa, fetísílẹ̀! Olúwa, dáríjì! Olúwa, gbọ́ kí o sì ṣe é! Nítorí i tìrẹ, Ọlọ́run mi, má ṣe pẹ́ títí, nítorí ìlú rẹ àti àwọn ènìyàn rẹ ń jẹ́ orúkọ mọ́ ọ lára.”
20 And whanne Y spak yit, and preiede, and knoulechide my synnes, and the synnes of my puple Israel, that Y schulde sette forth mekeli my preieris in the siyt of my God, for the hooli hil of my God,
Bí mo ṣe ń sọ̀rọ̀, tí mo sì ń gba àdúrà, tí mo ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi àti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn Israẹli ènìyàn mi, tí mo sì ń mú ẹ̀bẹ̀ mi tọ Olúwa Ọlọ́run mi nítorí òkè mímọ́ rẹ.
21 the while Y spak yit in my preyer, lo! the man Gabriel, whom Y hadde seyn in visioun at the bigynnyng, flei soone, and touchide me in the tyme of euentid sacrifice;
Bí mo ṣe ń gba àdúrà náà lọ́wọ́, Gabrieli ọkùnrin tí mo rí nínú ìran ìṣáájú, yára kánkán wá sí ọ̀dọ̀ mi ní àkókò ẹbọ àṣálẹ́.
22 and he tauyt me, and he spak to me, and seide, Danyel, now Y yede out, that Y schulde teche thee, and thou schuldist vndurstonde.
Ó jẹ́ kí ó yé mi, ó sì wí fún mi pé, “Daniẹli, mo wá láti jẹ́ kí o mọ̀ kí o sì ní òye.
23 Fro the bigynnyng of thi preieris a word yede out. Forsothe Y cam to schewe to thee, for thou art a man of desiris; therfor perseyue thou the word, and vndurstonde thou the visioun.
Bí o ṣe bẹ̀rẹ̀ sí nígbà àdúrà, a fún ọ ní ìdáhùn kan, èyí tí mo wá láti sọ fún ọ, nítorí ìwọ jẹ́ àyànfẹ́ gidigidi. Nítorí náà, gba ọ̀rọ̀ náà yẹ̀ wò kí ìran náà sì yé ọ:
24 Seuenti woukis of yeeris ben abreggid on thi puple, and on thin hooli citee, that trespassyng be endid, and synne take an ende, and that wickidnesse be doon awei, and euerlastynge riytfulnesse be brouyt, and that the visioun, and prophesie be fillid, and the hooli of seyntis be anoyntid.
“Àádọ́rin ọ̀sẹ̀ ni a pàṣẹ fún àwọn ènìyàn rẹ àti fún àwọn ìlú mímọ́ rẹ láti parí ìrékọjá, láti fi òpin sí ẹ̀ṣẹ̀, láti ṣe ètùtù sí ìwà búburú, láti mú òdodo títí ayé wá, láti ṣe èdìdì ìran àti wòlíì àti láti fi òróró yan Ibi Mímọ́ Jùlọ.
25 Therfor wite thou, and perseyue; fro the goyng out of the word, that Jerusalem be bildid eft, til to Crist, the duyk, schulen be seuene woukis of yeeris and two and sixti woukis of yeeris; and eft the street schal be bildid, and wallis, in the angwisch of tymes.
“Nítorí náà, mọ èyí pé, láti ìgbà tí a ti gbé ọ̀rọ̀ náà jáde wí pé kí a tún Jerusalẹmu ṣe, kí a sì tún kọ́, títí dé ìgbà ọmọ-aládé, ẹni òróró náà, alákòóso wa yóò fi dé, ó jẹ́ ọ̀sẹ̀ méje àti ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó sì tún ìgboro àti yàrá rẹ̀ mọ, ṣùgbọ́n ní àkókò wàhálà ni.
26 And after two and sixti woukis `of yeeris Crist schal be slayn. And it schal not be his puple, that schal denye hym. And the puple with the duyk to comynge schal distrie the citee, and the seyntuarie; and the ende therof schal be distriyng, and after the ende of batel schal be ordeynede desolacioun.
Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó ké Ẹni òróró náà kúrò, kò sì ní ní ohun kan. Àwọn ènìyàn ọmọ-aládé náà tí yóò wá ni yóò pa ìlú náà àti ibi mímọ́ run. Òpin yóò dé bí ìkún omi, ogun yóò máa jà títí dé òpin, a sì ti pàṣẹ ìdahoro.
27 Forsothe o wouk `of yeeris schal conferme the couenaunt to many men, and the offryng and sacrifice schal faile in the myddis of the wouke of yeeris; and abhomynacioun of desolacioun schal be in the temple, and the desolacioun schal contynue til to the parformyng and ende.
Yóò sì fi ìdí i májẹ̀mú kan múlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan. Ní àárín ọ̀sẹ̀ ni yóò mú òpin bá ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ. Àti lórí apá kan ni yóò dà ìríra tí ó mú ìdahoro wá, títí tí òpin tí a ti pàṣẹ lórí asọnidahoro yóò fi padà fi dé bá a.”

< Daniel 9 >