< Amos 4 >

1 Ye fatte kien, that ben in the hil of Samarie, here this word; whiche maken fals caleng to nedi men, and breken pore men; which seien to youre lordis, Bringe ye, and we schulen drynke.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria, ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára, tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
2 The Lord God swoor in his hooli, for lo! daies schulen come on you; and thei schulen reise you in schaftis, and youre remenauntis in buylynge pottis.
Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra: “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́ nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ, ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
3 And ye schulen go out bi the openyngis, oon ayens another, and ye schulen be cast forth in to Armon, seith the Lord.
Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ gba àárín odi yíya a ó sì lé e yín sí Harmoni,” ni Olúwa wí.
4 Come ye to Bethel, and do ye wickidli; to Galgala, and multiplie ye trespassyng; and offre ye eerli youre sacrifices, in thre daies youre tithis.
“Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀; ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i. Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá, ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
5 And sacrifice ye heriyng of breed maad sour, and clepe ye wilful offryngis, and telle ye; for ye, sones of Israel, wolden so, seith the Lord God.
Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
6 Wherfor and Y yaf to you astonying of teeth in alle youre citees, and nedinesse of looues in alle youre places; and ye turneden not ayen to me, seith the Lord.
“Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín, àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín, síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
7 Also Y forbeed reyn fro you, whanne thre monethis weren yit `to comyng, til to ripe corn; and Y reynede on o citee, and on another citee Y reynede not; o part was bireyned, and the part driede vp on which Y reynede not.
“Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta. Mo rán òjò sí ibùgbé kan ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn. Oko kan ní òjò; àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
8 And tweyne and thre citees camen to o citee, to drynke watir, and tho weren not fillid; and ye camen not ayen to me, seith the Lord.
Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
9 Y smoot you with brennynge wynd, and with rust, the multitude of youre orcherdis, and of youre vyneris; and a wort worm eet youre olyue places, and youre fige places; and ye camen not ayen to me, seith the Lord.
“Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n. Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
10 Y sente in to you deth in the weie of Egipt, Y smoot with swerd youre yonge men, `til to the caitifte of youre horsis, and Y made the stynk of youre oostis to stie in to youre nose thirlis; and ye camen not ayen to me, seith the Lord.
“Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín bí mo ti ṣe sí Ejibiti. Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín. Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn. Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
11 Y distriede you, as God distriede Sodom and Gomorre, and ye ben maad as a brond rauyschid of brennyng; and ye turneden not ayen to me, seith the Lord.
“Mo ti bì ṣubú nínú yín, bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
12 Wherfor, thou Israel, Y schal do these thingis to thee; but aftir that Y schal do to thee these thingis, Israel, be maad redi in to ayen comyng of thi God.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli, àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín, ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”
13 For lo! he fourmeth hillis, and makith wynd, and tellith to man his speche; and he makith a `morew myist, and goith on hiy thingis of erthe; the Lord God of oostis is the name of hym.
Ẹni tí ó dá àwọn òkè tí ó dá afẹ́fẹ́ tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn, ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn tí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

< Amos 4 >