< 2 Samuel 5 >

1 And alle the lynagis of Israel camen to Dauid, in Ebron, and seiden, Lo! we ben thi boon and thi fleisch.
Gbogbo ẹ̀yà Israẹli sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa ń í ṣe.
2 But also yistirdai and the thridde day ago, whanne Saul was kyng on vs, thou leddist out, and leddist ayen Israel; forsothe the Lord seide to thee, Thou schalt fede my puple Israel, and thou schalt be duyk on Israel.
Àti nígbà àtijọ́, nígbà tí Saulu fi jẹ ọba lórí wa, ìwọ ni ẹni tí ó máa ń kó Israẹli jáde, ìwọ sì ni ó máa ń mú wọn bọ̀ wá ilé: Olúwa sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò ṣe olùṣọ́ Israẹli àwọn ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún Israẹli.’”
3 Also and the eldere men of Israel camen to the kyng, in Ebron; and kyng Dauid smoot with hem boond of pees in Ebron, bifor the Lord; and thei anoyntiden Dauid in to kyng on Israel.
Gbogbo àgbàgbà Israẹli sì tọ ọba wá ní Hebroni, Dafidi ọba sì bá wọn ṣe àdéhùn kan ní Hebroni, níwájú Olúwa: wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba Israẹli.
4 Dauid was a sone of thretti yeer, whanne he bigan to regne, and he regnyde fourti yeer in Ebron;
Dafidi sì jẹ́ ẹni ọgbọ̀n ọdún nígbà tí ó jẹ ọba; ó sì jẹ ọba ní ogójì ọdún.
5 he regnede on Juda seuene yeer and sixe monethis; forsothe in Jerusalem he regnede thretti and thre yeer, on al Israel and Juda.
Ó jẹ ọba ní Hebroni ní ọdún méje àti oṣù mẹ́fà lórí Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lórí gbogbo Israẹli àti Juda.
6 And the kyng yede, and alle men that weren with hym, in to Jerusalem, to Jebusey, dweller of the lond. And it was seide of hem to Dauid, Thou schalt not entre hidur, no but thou do awei blynde men and lame, seiynge, Dauid schal not entre hydur.
Àti ọba àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ àwọn ará Jebusi, àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà; àwọn tí ó sì ti wí fún Dafidi pé, “Bí kò ṣe pé ìwọ bá mú àwọn afọ́jú àti àwọn arọ kúrò, ìwọ kì yóò wọ ìhín wá.” Wọ́n sì wí pé, “Dafidi kì yóò lè wá síyìn-ín.”
7 Forsothe Dauid took the tour of Syon; this is the citee of Dauid.
Ṣùgbọ́n Dafidi fi agbára gba ìlú odi Sioni: èyí náà ni í ṣe ìlú Dafidi.
8 For Dauid hadde `sette forth meede in that dai to hym, that hadde smyte Jebusei, and hadde touchid the goteris of roouys, and hadde take awey lame men and blynde, hatynge the lijf of Dauid. Therfor it is seid in prouerbe, A blynde man and lame schulen not entre in to the temple.
Dafidi sọ lọ́jọ́ náà pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọlu àwọn ará Jebusi, jẹ́ kí ó gba ojú àgbàrá, kí o sí kọlu àwọn arọ, àti àwọn afọ́jú tí ọkàn Dafidi kórìíra.” Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí pé, “Afọ́jú àti arọ wà níbẹ̀, kì yóò lè wọlé.”
9 Forsothe Dauid dwellide in the tour, and clepide it the citee of Dauid; and he bildide bi cumpas fro Mello, and with ynne.
Dafidi sì jókòó ní ilé àwọn ọmọ-ogun tí ó ní odi, a sì ń pè é ní ìlú Dafidi. Dafidi mọ ògiri yí i ká láti Millo wá, ó sì kọ́ ilé nínú rẹ̀.
10 And he entride profitynge and encreessynge; and the Lord God of oostis was with hym.
Dafidi sì ń pọ̀ sí i, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
11 Also Hyram, kyng of Tire, sent messangeris to Dauid, and cedre trees, and crafti men of trees, and crafti men of stoonus to wallis; and thei bildiden the hows of Dauid.
Hiramu ọba Tire sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, àti igi kedari, àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àti àwọn tí ń gbẹ́ òkúta, wọ́n kọ́ ilé kan fún Dafidi.
12 And Dauid knew, that the Lord hadde confermed hym kyng on Israel, and that he hadde enhaunsid his rewme on his puple Israel.
Dafidi sì kíyèsi i pé, Olúwa ti fi ìdí òun múlẹ̀ láti jẹ ọba lórí Israẹli, àti pé, ó gbé ìjọba rẹ̀ ga nítorí Israẹli àwọn ènìyàn rẹ̀.
13 Therfor Dauid took yit concubyns, and wyues of Jerusalem, after that he cam fro Ebron; and also othere sones and douytris weren borun to Dauid.
Dafidi sì tún mú àwọn àlè àti aya sí i láti Jerusalẹmu wá, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti Hebroni bọ̀, wọ́n sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin fún Dafidi.
14 And these ben the names of hem that weren borun to hym in Jerusalem; Samua, and Sobab, and Nathan,
Èyí sì ni orúkọ àwọn tí a bí fún un ní Jerusalẹmu; Ṣammua, Ṣobabu, Natani àti Solomoni.
15 and Salomon, and Jobaar, and Helisua,
Àti Ibhari, àti Eliṣua, àti Nefegi, àti Jafia.
16 and Repheg, and Japhia, and Helysama, and Holida, and Heliphelech.
Àti Eliṣama, àti Eliada, àti Elifeleti.
17 Therfor Filisteis herden, that thei hadden anoyntid Dauid kyng on Israel, and alle Filisteis stieden to seke Dauid. And whanne Dauid hadde herd this, he yede doun into a strong hold.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Filistini gbọ́ pé, wọ́n ti fi Dafidi jẹ ọba lórí Israẹli, gbogbo àwọn Filistini sì gòkè wá láti wá Dafidi; Dafidi sì gbọ́, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìlú olódi.
18 Forsothe Filisteis camen, and weren spred abrood in the valei of Raphaym.
Àwọn Filistini sì wá, wọ́n sì tẹ ara wọn ní àfonífojì Refaimu.
19 And Dauid counseilide the Lord, and seide, Whether Y schal stie to Filisties, and whether thou schalt yyue hem in myn hond? And the Lord seide to Dauid, Stie thou, for Y schal bitake, and Y schal yyue Filisteis in thin hond.
Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Kí èmi ó gòkè tọ àwọn Filistini bí? Ìwọ ó fi wọ́n lé mi lọ́wọ́ bí?” Olúwa sì wí fún Dafidi pé, “Gòkè lọ, nítorí pé dájúdájú èmi ó fi àwọn Filistini lé ọ lọ́wọ́.”
20 Therfor Dauid cam in to Baal Farasym, and smoot hem there, and seide, The Lord departide myn enemyes bifor me, as watris ben departid. Therfor the name of that place was clepid Baal Farasym.
Dafidi sì dé Baali-Perasimu, Dafidi sì pa wọ́n níbẹ̀, ó sì wí pé, “Olúwa ti ya lu àwọn ọ̀tá mi níwájú mi, gẹ́gẹ́ bí omi ti ń ya.” Nítorí náà ni òun ṣe pe orúkọ ibẹ̀ náà ni Baali-Perasimu.
21 And thei leften there her sculptils, whiche Dauid took, and hise men.
Wọ́n sì fi òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì kó wọn.
22 And Filisteis addiden yit, that thei schulden stie, and thei weren spred abrood in the valey of Raphaym.
Àwọn Filistini sì tún gòkè wá, wọ́n sì tan ara wọn kalẹ̀ ní àfonífojì Refaimu.
23 Sotheli Dauid councelide the Lord, and seide, Whether Y schal stie agens Filisties, and whether thou schalt bitake hem in to myn hondis? Which answeride, Thou schalt not stie ayens hem, but cumpasse thou bihynde her bak, and thou schalt come to hem on the contrarie side of the pere trees.
Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òun sì wí pé, “Má ṣe gòkè lọ; ṣùgbọ́n bù wọ́n lẹ́yìn, kí o sì kọlù wọ́n níwájú àwọn igi Baka.
24 And whanne thou schalt here the sown of cry goynge in the cop of `pere trees, thanne thou schalt biginne batel; for thanne the Lord schal go out befor thi face, that he smyte the castels of Filisteis.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá gbọ́ ìró ẹsẹ̀ lórí àwọn igi Baka náà, nígbà náà ni ìwọ yóò sì yára, nítorí pé nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ níwájú rẹ láti kọlù ogun àwọn Filistini.”
25 Therfor Dauid dide as the Lord comaundide to hym; and he smoot Filisteys fro Gabaa til `the while thei camen to Jezer.
Dafidi sì ṣe bẹ́ẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un; ó sì kọlu àwọn Filistini láti Geba títí dé Geseri.

< 2 Samuel 5 >