< 2 Samuel 17 >

1 Therfor Achitofel seide to Absolon, Y schal chese twelue thousynde of men `to me, and Y schal rise, and pursue Dauid in this nyyt.
Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Èmi ó yan ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin èmi ó sì dìde, èmi ó sì lépa Dafidi lóru yìí.
2 And Y schal falle on hym, for he is wery, and with vnboundun hondis Y schal smyte hym. And whanne al the puple fleeth which is with hym, Y schal smyte the kyng `desolat, ether left aloone.
Èmi ó sì yọ sí i nígbà tí àárẹ̀ bá mú un tí ọwọ́ rẹ̀ sì ṣe aláìle, èmi ó sì dá a ní ìjì, gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ yóò sì sá, èmi ó sì kọlu ọba nìkan ṣoṣo.
3 And Y schal lede ayen al the puple, as o man is wont to turne ayen; for thou sekist o man, and al the puple schal be in pees.
Èmi ó sì mú gbogbo àwọn ènìyàn padà sọ́dọ̀ rẹ bi ìgbà tí ìyàwó bá padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ̀. Ọkàn ẹnìkan ṣoṣo tí ìwọ ń wá yìí ni ó túmọ̀ sí ìpadàbọ̀ gbogbo wọn; gbogbo àwọn ènìyàn yóò sì wà ní àlàáfíà.”
4 And the word of him plesyde Absolon, and alle the grete men in birthe of Israel.
Ọ̀rọ̀ náà sì tọ́ lójú Absalomu, àti lójú gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli.
5 Forsothe Absolon seide, Clepe ye also Chusy of Arath, and here we what also he seith.
Absalomu sì wí pé, “Ǹjẹ́ pe Huṣai ará Arki, àwa ó sì gbọ́ èyí tí ó wà lẹ́nu rẹ̀ pẹ̀lú.”
6 And whanne Chusi hadde come to Absolon, Absolon seide to hym. Achitofel spak siche a word; owen we do, ethir nay? what counsel yyuest thou?
Huṣai sì dé ọ̀dọ̀ Absalomu, Absalomu sì wí fún un pé, “Báyìí ni Ahitofeli wí, kí àwa ṣe bí ọ̀rọ̀ rẹ bí? Bí ko bá sì tọ́ bẹ́ẹ̀, ìwọ wí.”
7 And Chusi seide to Absolon, This is not good counsel, which Achitofel yaf in this tyme.
Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Ìmọ̀ tí Ahitofeli gbà yìí, kò dára nísinsin yìí.”
8 And eft Chusi seide, Thou knowist, that thi fadir, and the men that ben with him, ben moost stronge, and in bitter soule, as if a femal bere is fers in the forest, whanne the whelpis ben rauyschid; but also thi fader is a man werriour, and he schal not dwelle with the puple.
Huṣai sì wí pé, “Ìwọ mọ baba rẹ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé alágbára ni wọ́n, wọ́n sì wà ní kíkorò ọkàn bí àmọ̀tẹ́kùn tí a gbà ní ọmọ ni pápá, baba rẹ sì jẹ́ jagunjagun ọkùnrin kì yóò bá àwọn ènìyàn náà gbé pọ̀ lóru.
9 In hap now he is hid in the dichis, ethir in o place, in which he wole; and whanne ony man fallith in the bigynnyng, who euer schal here, he schal here, and schal seie, Wounde is maad in the puple that suede Absolon.
Kíyèsi i, ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ nísinsin yìí ni ihò kan, tàbí ní ibòmíràn: yóò sì ṣe, nígbà tí díẹ̀ nínú wọn bá kọ́ ṣubú, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ yóò sì wí pé, ‘Ìparun sì ń bẹ́ nínú àwọn ènìyàn tí ń tọ Absalomu lẹ́yìn.’
10 And ech strongeste man, whos herte is as `the herte of a lioun, schal be discoumfortid for drede; for al the puple of Israel knowith, that thi fadir is strong, and that alle men ben stronge, that ben with him.
Ẹni tí ó sì ṣe alágbára, tí ọkàn rẹ̀ sì dàbí ọkàn kìnnìún, yóò sì rẹ̀ ẹ́: nítorí gbogbo Israẹli ti mọ̀ pé alágbára ni baba rẹ, àti pé, àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ jẹ́ alágbára.
11 But this semeth to me to be riytful counsel; al Israel be gaderid to thee, fro Dan `til to Bersabee, vnnoumbrable as the soond of the see; and thou schalt be in the myddis of hem.
“Nítorí náà èmi dámọ̀ràn pé, kí gbogbo Israẹli wọ́jọ pọ̀ sọ́dọ̀ rẹ, láti Dani títí dé Beerṣeba, gẹ́gẹ́ bí iyanrìn létí òkun fún ọ̀pọ̀lọpọ̀; àti pé, kí ìwọ tìkára rẹ̀ ó lọ sí ogun náà.
12 And we schulen falle on hym, in what euer place he is foundun, and we schulen hile hym, as dew is wont to falle on the erthe; and we schulen not leeue of the men that ben with hym, `sotheli not oon.
Àwa ó sì yọ sí i níbikíbi tí àwa o gbé rí i, àwa ó sì yí i ká bí ìrì ti ń ṣẹ̀ sí ilẹ̀ àní, ọkàn kan kì yóò kù pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
13 `That if he entrith in to ony citee, al Israel schal cumpasse that citee with roopis, and we schulen drawe it in to the stronde, that no thing be foundun, sotheli not a litil stoon therof.
Bí o bá sì bọ́ sí ìlú kan, gbogbo Israẹli yóò mú okùn wá sí ìlú náà, àwa ó sì fà á lọ sí odò, títí a kì yóò fi rí òkúta kéékèèké kan níbẹ̀.”
14 And Absolon seide, and alle the men of Israel, The counsel of Chusi of Arath is betere than the counsel of Achitofel; sotheli the profitable counsel of Achitofel was destried bi Goddis wille, that the Lord schulde brynge in yuel on Absolon.
Absalomu àti gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wí pé, “Ìmọ̀ Huṣai ará Arki sàn ju ìmọ̀ Ahitofeli lọ! Nítorí Olúwa fẹ́ láti yí ìmọ̀ rere ti Ahitofeli po.” Nítorí kí Olúwa lè mú ibi wá sórí Absalomu.
15 And Chusi seide to Sadoch and to Abiathar, preestis, Achitofel yaf counsel to Absolon, and to the eldere men of Israel in this and this maner, and Y yaf sich and sich counsel.
Huṣai sì wí fún Sadoku àti fún Abiatari àwọn àlùfáà pé, “Báyìí ni Ahitofeli ti bá Absalomu àti àwọn àgbàgbà Israẹli dámọ̀ràn, báyìí lèmi sì bá a dámọ̀ràn.
16 Now therfor sende ye soone, and telle ye to Dauid, and seie ye, Dwelle thou not this nyyt in the feeldi places of deseert, but passe thou with out delay; lest perauenture the kyng be destried, and al the puple which is with hym.
Nítorí náà yára ránṣẹ́ nísinsin yìí kí o sì sọ fún Dafidi pé, ‘Má ṣe dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà lálẹ́ yìí, ṣùgbọ́n yára rékọjá kí a má bá a gbé ọba mì, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ.’”
17 Forsothe Jonathas and Achymaas stoden bisidis the welle of Rogel; an handmaide yede, and telde to hem, and thei yeden forth to telle the message to kyng Dauid; for thei myyten not be seyn, nether entre in to the citee.
Jonatani àti Ahimasi sì dúró ní En-Rogeli ọ̀dọ́mọdébìnrin kan sì lọ, ó sì sọ fún wọn, wọ́n sì lọ wọ́n sọ fún Dafidi ọba nítorí pé kí a má bá à rí wọn pé wọ́n wọ ìlú.
18 Forsothe a child siy hem, and he schewide to Absolon; sotheli thei entriden with swift goyng in to the hows of `sum man in Bahurym, that hadde a pit in his place, and thei yeden doun in to that pit.
Ṣùgbọ́n ọ̀dọ́mọdékùnrin kan rí wọn, ó sì wí fún Absalomu, ṣùgbọ́n àwọn méjèèjì sì yára lọ kúrò, wọ́n sì wá sí ilé ọkùnrin kan ní Bahurimu, ẹni tí ó ní kànga kan ní ọgbà rẹ̀, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ sí ibẹ̀.
19 Forsothe a womman took, and spred abrood an hilyng of the mouth of the pit as driynge `barli with the pile takun a wey, and so the thing was hid.
Obìnrin rẹ̀ sì mú nǹkan ó fi bo kànga náà, ó sì sá àgbàdo sórí rẹ̀, a kò sì mọ̀.
20 And whanne the seruauntis of Absolon hadde come in to the hows, thei seiden to the womman, Where is Achymaas and Jonathas? And the womman answeride to hem, Thei passiden hastily, whanne `watir was tastid a litil. And whanne thei that souyten hem hadden not founde, thei turneden ayen in to Jerusalem.
Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì tọ obìnrin náà wá sí ilé náà, wọ́n sì béèrè pé, “Níbo ni Ahimasi àti Jonatani gbé wà?” Obìnrin náà sì wí fún wọn pé, “Wọ́n ti gòkè rékọjá ìṣàn odò náà.” Wọ́n sì wá wọn kiri, wọn kò sì rí wọn, wọ́n sì yípadà sí Jerusalẹmu.
21 And whanne thei `that souyten hadden go, thei stieden fro the pit; and thei yeden, and telden to kyng Dauid, and seiden, Rise ye, passe ye soone the flood, for Achitofel yaf sich counsel ayens you.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti lọ tán, àwọn ọkùnrin náà sì jáde kúrò nínú kànga, wọ́n sì lọ wọ́n sì rò fún Dafidi ọba. Wọ́n sọ fún Dafidi pé, “Dìde kí o sì gòkè odò kánkán, nítorí pé báyìí ni Ahitofeli gbìmọ̀ sí ọ.”
22 Therfor Dauid roos, and al the puple that was with hym, and thei passiden Jordan, til it was cleer dai, bifor that the word was pupplischid; and sotheli not oon was left, that `passide not the flood.
Dafidi sì dìde, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì gòkè odò Jordani: kí ilẹ̀ tó mọ́, ènìyàn kò kù tí kò gòkè odò Jordani.
23 Forsothe Achitofel siy, that his counsel was not doon, and he sadlide his asse, and roos, and yede in to his hows, and in to his citee; and whanne his hows was disposid, he perischide bi hangyng, and he was biried in the sepulcre of his fadir.
Nígbà tí Ahitofeli sì rí i pé wọn kò fi ìmọ̀ tirẹ̀ ṣe, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ni gàárì, ó sì dìde, ó lọ ilé rẹ̀, ó sì palẹ̀ ilé rẹ̀ mọ̀, ó sì so, ó sì kú, a sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀. Absalomu gbógun ti Dafidi.
24 Sotheli Dauid cam in to the castels, and Absolon passide Jordan, he and alle the men of Israel with hym.
Dafidi sì wá sí Mahanaimu, Absalomu sì gòkè odò Jordani, òun àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli pẹ̀lú rẹ̀.
25 Forsothe Absolon ordeynede Amasan for Joab on the oost; forsothe Amasan was the sone of a man that was clepid Jethra of Jeyrael, which entride to Abigail, douyter of Naas, the sistir of Saruye, that was the modir of Joab.
Absalomu sì fi Amasa ṣe olórí ogun ní ipò Joabu: Amasa ẹni tí í ṣe ọmọ ẹnìkan, orúkọ ẹni tí a ń pè ní Itira, ará Israẹli, tí ó wọlé tọ Abigaili ọmọbìnrin Nahaṣi, arábìnrin Seruiah, ìyá Joabu.
26 And Israel settide tentis with Absolon in the lond of Galaad.
Israẹli àti Absalomu sì dó ní ilẹ̀ Gileadi.
27 And whanne Dauid hadde come in to castels, Sobi, the sone of Naas of Rabath, of the sones of Amon, and Machir, the sone of Amyel, of Lodobar, and Berzellai, of Galaad,
Nígbà tí Dafidi sì wá sí Mahanaimu, Ṣobi ọmọ Nahaṣi ti Rabba tí àwọn ọmọ Ammoni, àti Makiri ọmọ Ammieli ti Lo-Debari, àti Barsillai ará Gileadi ti Rogelimu.
28 of Rogelym, brouyten to hym beddyngis, and tapitis, and erthun vessels, wheete, and barli, and mele, and flour, and benys, and lente, and fried chichis, and hony,
Mú àwọn àkéte, àti àwọn àwo, àti ìkòkò amọ̀, àti alikama, àti ọkà barle, àti ìyẹ̀fun, àti àgbàdo díndín, àti ẹ̀wà, àti erèé, àti lẹntili.
29 and botere, and scheep, and fatte calues. And thei yauen to Dauid, and to the puple that weren with hym, to ete; for thei supposiden the puple to be maad feynt for hungur and thirst in deseert.
Àti oyin, àti òrí-àmọ́, àti àgùntàn, àti wàràǹkàṣì màlúù, wá fún Dafidi àti fún àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, láti jẹ: nítorí tí wọ́n wí pé, “Ebi ń pa àwọn ènìyàn, ó sì rẹ̀ wọ́n, òǹgbẹ sì ń gbẹ wọ́n ní aginjù.”

< 2 Samuel 17 >