< 2 Kings 17 >
1 Yn the tweluethe yeer of Achaz, kyng of Juda, Osee, sone of Hela, regnyde in Samarie on Israel nyne yeer.
Ní ọdún kejìlá ọba Ahasi ará Juda, Hosea ọmọ Ela jẹ ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ fún ọdún mẹ́sàn-án.
2 And he dide yuel bifor the Lord, but not as the kyngis of Israel, that weren bifor hym.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i ti ọba Israẹli ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀.
3 Salmanasar, kyng of Assiriens, stiede ayens this Osee, and Osee was maad seruaunt to hym, and yildide tributis to hym.
Ṣalamaneseri ọba Asiria wá sókè láti mú Hosea, ẹni tí ó ti jẹ fún Ṣalamaneseri ó sì ti san owó òde fún un.
4 And whanne the kyng of Assiriens hadde perseyued, that Osee he enforside to be rebelle, and hadde sent messangeris to Sua, kyng of Egipt, that he schulde not yyue tributis to the kyng of Assiriens, as he was wont bi alle yeeris, `the kyng of Assiriens bisegide hym, and sente him boundun in to prisoun.
Ṣùgbọ́n ọba Asiria rí i wí pé Hosea jẹ́ ọlọ́tẹ̀, nítorí ó ti rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ ọba Ejibiti, kò sì san owó òde mọ́ fún ọba Asiria, gẹ́gẹ́ bí o ti máa ń ṣe ní ọdọọdún. Nígbà náà ọba Asiria fi agbára mú ún, ó sì fi sínú túbú.
5 And he yede thoruy al the lond, and he stiede to Samarie, and bisegide it bi thre yeer.
Ọba Asiria gòkè wá sí gbogbo ibi ilé náà, ó sì lọ sí Samaria, ó sì dúró tí ì fún ọdún mẹ́ta.
6 Forsothe in the nynthe yeer of Osee, the kyng of Assiriens took Samarie, and translatide Israel in to Assiriens; and he puttide hem in Hela, and in Thabor, bisidis the flood Gozam, in the citee of Medeis.
Ní ọdún kẹsànán ti Hosea, ọba Asiria mú Samaria ó sì kó Israẹli lọ sí Asiria. Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ ní Hala, ní Gosani ní etí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
7 Forsothe it was don, whanne the sones of Israel hadden synned bifor her Lord God, that ledde hem out of the lond of Egipt, fro the hond of Farao, kyng of Egipt, thei worschipeden alien goddis;
Gbogbo eléyìí ṣẹlẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde ní Ejibiti lábẹ́ agbára Farao ọba Ejibiti. Wọ́n sin ọlọ́run mìíràn,
8 and yeden bi the custom of hethene men, whiche the Lord hadde wastid in the siyt of the sones of Israel, and of the kyngis of Israel, for thei hadden do in lijk maner.
wọn si tẹ̀lé ìwà orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti gbá kúrò níwájú wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà ti ọba Israẹli tí ó ti paláṣẹ.
9 And the sones of Israel offendiden her Lord God bi wordis not riytful, and thei bildiden to hem silf hiy thingis in alle her citees, fro the tour of keperis `til to a strengthid citee.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe ohun ìríra sí Olúwa Ọlọ́run wọn kọ́ láti ilé ìṣọ́ sí ìlú tí a dáàbò bò, wọ́n kọ́ ilé gíga fún ara wọn ní gbogbo ìlú wọn.
10 And thei maden to hem ymagis, and wodis, in ech hiy hil, and vndur ech tree ful of bowis;
Wọ́n sì gbé àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀ sókè àti ère òrìṣà Aṣerah lórí gbogbo igi tútù.
11 and thei brenten there encence on the auteris bi the custom of hethene men, whiche the Lord hadde translatid fro the face of hem. And thei diden werste wordis, and thei wraththiden the Lord;
Ní gbogbo ibi gíga, wọ́n sun tùràrí gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú wọn. Wọ́n ṣe ohun búburú tí ó rú ìbínú Olúwa sókè.
12 and worschipiden vnclenesses, of whiche the Lord comaundide to hem, that thei schulden not do this word.
Wọ́n sìn òrìṣà, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí.”
13 And the Lord witnesside in Israel and in Juda, bi the hond of alle prophetis and seeris, and seide, Turne ye ayen fro youre werste weies, and kepe ye my comaundementis, and ceremonyes, bi al the lawe whiche Y comaundide to youre fadris, and as Y sente to you in the hond of my seruauntis prophetis.
Olúwa kìlọ̀ fún Israẹli àti Juda nípa gbogbo àwọn wòlíì wọn àti aríran: “Ẹ yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú yín. Kí ẹ ṣe òfin mi àti ìlànà mi, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin tí Èmi paláṣẹ fún àwọn baba yín láti tẹ̀lé àti èyí tí mo rán sí i yín nípa ìránṣẹ́ àwọn wòlíì mi.”
14 Whiche herden not, but maden hard her nol bi the nol of her fadris, that nolden obeie to her Lord God.
Ṣùgbọ́n wọn kò ní gbọ́, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọlọ́rùn líle gẹ́gẹ́ bí i ti baba wọn, ẹni tí kò gbà Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́.
15 And thei castiden, awei the lawful thingis of hym, and the couenaunt which he couenauntide with her fadris, and the witnessyngis bi whiche he witnesside to hem; and thei sueden vanytees, `that is, idols, and diden veynli; and sueden hethene men, that weren `bi the cumpas of hem; of whiche vanytees the Lord comaundide to hem, that thei schulden not do as also tho hethene men diden.
Wọ́n kọ̀ ìlànà rẹ̀ àti májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú baba wọn àti ìkìlọ̀ tí ó ti fi fún wọn. Wọ́n tẹ̀lé òrìṣà aláìníláárí, àwọn fún rara wọn sì jẹ́ aláìníláárí. Wọ́n tẹ̀lé orílẹ̀-èdè tí ó yí wọn ká bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti kìlọ̀ fún wọn pé, “Má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí wọn tí ń ṣe,” wọ́n sì ṣe ohun tí Olúwa ti kà léèwọ̀ fún wọn láti ṣe.
16 And thei forsoken alle the comaundementis of her Lord God, and thei maden to hem twei yotun calues, and wodis, and worschipiden al the knyythod of heuene; and thei seruyden Baal, and halewiden to hym her sones,
Wọ́n kọ̀ gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọ́n sì ṣe òrìṣà méjì fún ara wọn, wọ́n sì gbẹ́ ẹ ọ̀kan ní ère ẹgbọrọ màlúù, àti ọ̀kan ní ère òrìṣà Aṣerah. Wọ́n sì tẹrí wọn ba sí gbogbo ogun ọ̀run, wọ́n sì sin Baali.
17 and her douytris thoruy fier, and thei seruyden to fals dyuynyng, and to dyuynyng bi chiterynge of briddis; and thei yauen hem silf to do yuel bifor the Lord, and thei wraththiden hym.
Wọ́n sì fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn rú ẹbọ nínú iná. Wọ́n sì ń fọ àfọ̀ṣẹ, wọ́n sì ń ṣe àlúpàyídà wọ́n sì ta ara wọn láti ṣe ohun búburú níwájú Olúwa, wọ́n sì mú un bínú.
18 And the Lord was wrooth greetli to Israel; and he took awei hem fro his siyt, and noon lefte, no but the lynage of Juda oneli.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gidigidi pẹ̀lú Israẹli ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo ni ó kù,
19 But nether Juda hym silf kepte the heestis of `his Lord God, netheles he erride, and yede in the errour of Israel, whiche it wrouyte.
àti pẹ̀lú, Juda kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Israẹli tí wọ́n ṣe.
20 And the Lord castide awei al the seed of Israel, and turmentide hem, and bitook hem in the hond of rauynouris; til he castide awei hem fro his face,
Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli; ó sì jẹ wọ́n ní yà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè títí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.
21 fro that tyme in which Israel was departid fro the hous of Dauid, and maden to hem a kyng, Jeroboam, sone of Nabath. For Jeroboam departide Israel fro the Lord, and made hem to do a greet synne.
Nígbà tí ó ta Israẹli kúrò láti ìdílé Dafidi, wọ́n sì mú Jeroboamu ọmọ Nebati jẹ ọba wọn. Jeroboamu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli yípadà kúrò ní títẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́ṣẹ̀ ńlá.
22 And the sones of Israel yeden in alle the synnes of Jeroboam, whiche he hadde do; and thei departiden not fro tho synnes,
Àwọn ọmọ Israẹli forítì í nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn,
23 til the Lord dide awei Israel fro his face, as he spak in the hond of alle hise seruauntis prophetis; and Israel was translatid fro his lond in to Assiriens til in to this dai.
títí tí Olúwa fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ wòlíì. Bẹ́ẹ̀ ni a kó gbogbo ènìyàn Israẹli kúrò ní ilẹ̀ wọn lọ sí ìgbèkùn ni Asiria, títí di òní yìí.
24 Forsothe the kyng of Assiriens brouyte puple fro Babiloyne, and fro Cutha, and fro Hailath, and fro Emath, and fro Sepharuaym, and settide hem in the citees of Samarie for the sones of Israel; whiche hadden in possessioun Samarie, and dwelliden in the citees therof.
Ọba Asiria mú àwọn ènìyàn láti Babeli, Kuta, Afa, Hamati àti Sefarfaimi, wọ́n sì fi wọ́n sínú ìlú Samaria láti rọ́pò àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n sì ń gbé ní ìlú náà.
25 And whanne thei bigunnen to dwelle there, thei dredden not the Lord; and the Lord sente to hem liouns, that killiden hem.
Nígbà tí wọ́n gbé bẹ̀ ní àkọ́kọ́, wọn kò sì bẹ̀rù Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni ó rán kìnnìún sí àárín wọn. Wọ́n sì pa nínú wọn.
26 And it was teld to the kyng of Assiriens, and was seid, The folkis whiche thou translatidist, and madist to dwelle in the citees of Samarie, kunnen not the lawful thingis of God of the lond; and the Lord sente liouns in to hem, and lo! liouns sleen hem; for thei kunnen not the custom of God of the lond.
Wọ́n sì sọ fún ọba Asiria pé, “Àwọn ènìyàn tí ìwọ lé kúrò tí o sì fi sínú ìlú Samaria kò mọ ohun tí ọlọ́run ìlú náà béèrè. Ó sì ti rán kìnnìún sí àárín wọn, tí ó sì ń pa wọ́n run, nítorí ènìyàn wọn kò mọ ohun tí ó béèrè.”
27 Sotheli the kyng of Assiriens comaundide, and seide, Lede ye thidur oon of the preestis, whiche ye brouyten prisoneris fro thennus, that he go, and dwelle with hem, and teche hem the lawful thingis of God of the lond.
Nígbà náà ọba Asiria pàṣẹ yìí wí pé, “Mú ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó mú láti Samaria lọ padà gbé níbẹ̀ kí ó sì kọ́ àwọn ènìyàn ní, ohun tí ọlọ́run ilẹ̀ náà béèrè.”
28 Therfor whanne oon of these preestis had come, that weren led prisoneris fro Samarie, he dwellide in Bethel, and tauyte hem, how thei schulden worschipe the Lord.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó ti kúrò ní Samaria wá gbé ní Beteli ó sì kọ́ wọn bí a ti ń sin Olúwa.
29 And ech folk made his god, and thei settiden tho goddis in the hiy templis, whiche the men of Samarie hadden maad, folk and folk in her citees, in whiche thei dwelliden.
Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, olúkúlùkù orílẹ̀-èdè ṣe òrìṣà tirẹ̀ ní gbogbo ìlú níbi tí wọ́n gbé wà, wọ́n sì gbé wọn nínú ilé òrìṣà àti àwọn ènìyàn Samaria ó sì ṣe wọ́n sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì.
30 For men of Babiloyne maden Socoth Benoth; forsothe men of Cutha maden Vergel; and men of Emath maden Asyma;
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin láti Babeli ṣe àgọ́ àwọn wúńdíá, àwọn ènìyàn Kuti ṣe òrìṣà Nergali, àti àwọn ènìyàn Hamati ṣe ti Aṣima;
31 forsothe Eueis maden Nabaath and Tharcha; sotheli thei that weren of Sepharuaym brenten her sones in fier to Adramelech and Anamelech, goddis of Sepharuaym.
àti àwọn ará Afa ṣe Nibhasi àti Tartaki, àti àwọn ará Sefarfaimi sun àwọn ọmọ wọn níná gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Adrameleki àti Anameleki, àwọn òrìṣà Sefarfaimi.
32 And netheles thei worschipiden the Lord; forsothe of the laste men thei maden preestis of the hiye thingis, and settiden hem in hiye templis.
Wọ́n sin Olúwa, ṣùgbọ́n wọ́n sì tún yan gbogbo ẹgbẹ́ tí ènìyàn wọn láti ṣe iṣẹ́ oyè fún wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà ní ibi gíga.
33 And whanne thei worschipiden God, thei serueden also her goddis, bi the custom of hethene men, fro whiche thei weren translatid to Samarie;
Wọ́n sin Olúwa ṣùgbọ́n wọ́n sin òrìṣà wọn ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú àṣà orílẹ̀-èdè wọn láti ibi tí wọ́n ti gbé wọn wá.
34 `til in to present dai thei suen the eld custom; thei dredden not the Lord, nethir thei kepen hise cerymonyes, and domes, and lawe, and comaundement, which the Lord comaundide to the sones of Jacob, whom he nemyde Israel;
Láti ìgbà náà wá àwọn àlùfáà wọn ṣe bí ti àtẹ̀yìnwá. Wọn kò sin Olúwa tàbí kí wọ́n fi ara mọ́ ìlànà àti àṣẹ àti òfin tí Olúwa fi fún ìránṣẹ́ Jakọbu, tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
35 and he smoot a couenaunt with hem, and comaundide to hem, and seide, Nyle ye drede alien goddis, and onoure ye not outwardli hem, nethir worschipe ye inwardli hem, and make ye not sacrifice to hem;
Nígbà tí Olúwa ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ó pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe sin òrìṣà mìíràn tàbí tẹríba fún wọn, sìn wọ́n tàbí kí ẹ rú ẹbọ sí wọn.
36 but youre Lord God, that ledde you out of the lond of Egipt in greet strengthe, and in arm holdun forth, drede ye hym, and worschipe ye hym, and make ye sacrifice to hym.
Ṣùgbọ́n Olúwa, ẹni tí ó mú yín gòkè jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú agbára ńlá àti nínà apá, òun ni ẹni náà tí ó yẹ kí ẹ sìn. Òun ni ẹni tí ó yẹ kí ẹ tẹríba fún àti sí òun ni kí ẹ rú ẹbọ fún.
37 And kepe ye the cerymonyes, and domes, and the lawe, and comaundement, which he wroot to you, that ye do in alle daies; and drede ye not alien goddis.
Ó yẹ kí ẹ̀yin kí ó máa kíyèsi ara yín gidigidi láti pa ìlànà àti àṣẹ, àti òfin tí ó kọ fún un yín mọ́. Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn.
38 And nyle ye foryete the couenaunt, which he smoot with you, nether worschipe ye alien goddis;
Ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú tí mo ti ṣe pẹ̀lú yín mọ́ àti kí ẹ má sin ọlọ́run mìíràn.
39 but drede ye youre Lord God, and he schal delyuere you fro the hond of alle youre enemyes.
Kúkú sin Olúwa Ọlọ́run rẹ; Òun ni ẹni náà tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a yín.”
40 Forsothe thei herden not, but diden bi her formere custom.
Wọn kò ní gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni, wọ́n sì ń ṣe iṣẹ́ wọ́n ti àtijọ́.
41 Therfor these hethene men dredden sotheli God; but netheles thei serueden also her idols, for bothe her sones and the sones of sones doen so, til in to present dai, as her fadris diden.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn wọn sin Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà wọn. Títí di ọjọ́ òní ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn sì ń ṣe bí àwọn baba wọn ti ń ṣe.