< 2 Chronicles 5 >

1 Therfor Salomon brouyte in alle thingis, siluer and gold, whiche Dauid, his fadir, hadde avowid; and he puttide alle vesselis in the tresouris of the hows of the Lord.
Nígbà tí gbogbo iṣẹ́ tí Solomoni ti ṣe fún tẹmpili Olúwa ti parí, ó kó gbogbo àwọn nǹkan tí Dafidi baba rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀: wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò ọ̀ṣọ́, ó sì fi wọ́n sínú ìṣúra ilé Ọlọ́run.
2 After whiche thingis he gaderide togidere alle the grettere men in birthe of Israel, and alle the princes of lynagis, and the heedis of meynees, of the sones of Israel, in to Jerusalem, that thei schulden brynge the arke of boond of pees of the Lord fro the citee of Dauid, which is Syon.
Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli jọ sí Jerusalẹmu, gbogbo àwọn olórí ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan àti àwọn olóyè àwọn ìdílé Israẹli, kí wọn kí ó gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá láti Sioni ìlú Dafidi.
3 Therfor alle men of Israel camen to the kyng, in the solempne dai of the seuenthe monethe.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli péjọ sí ọ̀dọ̀ ọba ní àkókò àjọ àgọ́.
4 And whanne alle the eldre men of Israel `weren comen, the dekenes baren the arke,
Gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli sì wá, àwọn ọmọ Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
5 and brouyten it in, and al the aray of the tabernacle. Forsothe the preestis with the dekenes baren the vessels of seyntuarie, that weren in the tabernacle.
Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí náà gòkè àti àgọ́ ìpàdé àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ni ó mú wọn gòkè wá.
6 Sotheli kyng Salomon, and alle the cumpenyes of Israel, and alle that weren gaderid to gidere, offriden bifor the arke wetheris and oxis with outen ony noumbre; for the multitude of slayn sacrifices was `so greet.
Nígbà náà ni ọba Solomoni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, wà níwájú àpótí ẹ̀rí náà wọ́n sì fi àgùntàn àti màlúù tí a kò le è kà tán rú ẹbọ, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è mọ iye wọn tán nítorí bí wọ́n ti pọ̀ tó.
7 And preestis brouyten the arke of boond of pees of the Lord in to his place, that is, to Goddis answeryng place of the temple, in to the hooli of hooli thingis, vndur the wyngis of cherubyns;
Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
8 so that cherubyns spredden forth her wyngis ouer the place, in which the arke was put, and hiliden thilke arke with hise barris.
Àwọn Kérúbù na ìyẹ́ wọn bo ibi àpótí ẹ̀rí náà àti àwọn ọ̀pá tí ó gbé e ró.
9 Sotheli the heedis, by which the arke was borun, weren opyn bifor Goddis answeryng place, for tho heedis weren a litil lengere; but if a man hadde be a litil with out forth, he myyt not se tho barris. Therfor the arke was there til in to present dai;
Àwọn ọ̀pá rẹ̀ náà gùn tó bẹ́ẹ̀ tí a fi rí orí àwọn ọ̀pá náà láti ibi àpótí ẹ̀rí náà níwájú Ibi Mímọ́ náà, ṣùgbọ́n a kò rí wọn lóde. Níbẹ̀ ni ó sì wà títí di òní yìí.
10 and noon other thing was in the arke, no but twei tablis, whiche Moyses hadde put in Oreb, whanne the Lord yaf the lawe to the sones of Israel goynge out of Egipt.
Kò sí ohun kan nínú àpótí ẹ̀rí náà bí kò ṣe wàláà méjì tí Mose fi sínú rẹ̀ ní Horebu, ní ìgbà tí Olúwa fi bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti.
11 Forsothe the prestis yeden out of the seyntuarie, for alle preestis, that myyten be foundun there, weren halewid, and the whiles, and the ordre of seruyces among hem was not departid yit in that tyme;
Lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà jáde wá láti Ibi Mímọ́. Gbogbo àwọn àlùfáà tí ó wà níbẹ̀ ni ó ya ara wọn sí mímọ́ láìbìkítà fún ìpín wọn.
12 bothe dekenes and syngeris, that is, bothe thei that weren vndur Asaph, and thei that weren vndur Eman, and thei that weren vndur Idithum, her sones and britheren, clothid with white lynun clothis, sownyden with cymbalis and sautrees and harpis, and stoden at the west coost of the auter, and with hem weren sixe score preestis trumpynge.
Gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ akọrin: Asafu, Hemani, Jedutuni àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ẹbí wọn, wọ́n dúró ní igun ìlà-oòrùn pẹpẹ náà wọ́n wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ tuntun wọ́n ń lo kimbali, dùùrù àti ohun èlò orin olókùn. Ìwọ̀n ọgọ́fà àwọn àlùfáà tí wọ́n ń fun ìpè ni wọ́n tẹ̀lé wọn.
13 Therfor whanne alle sungen togidur both with trumpis, and vois, and cymbalis, and orguns, and of dyuerse kynde of musikis, and reisiden the vois an hiy, the sown was herd fer, so that whanne thei hadden bigunne to preyse the Lord, and to seie, Knouleche ye to the Lord, for he is good, for his mercy is in to the world, `ether, with outen ende; the hows of God was fillid with a cloude,
Àwọn afùnpè àti àwọn akọrin pa ohùn wọn pọ̀ sí ọ̀kan ṣoṣo, láti fi ìyìn àti ọpẹ́ fun Olúwa. Wọ́n fi ìpè, kimbali àti àwọn ohun èlò orin mìíràn mọ́ ọn, wọ́n gbé ohùn wọn sókè láti fi yin Olúwa, wọ́n ń kọrin pé, “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ wà títí láéláé.” Nígbà náà ni ìkùùkuu ojú ọ̀run kún inú tẹmpili Olúwa,
14 and the preestis miyten not stonde and serue for the derknesse; for the glorie of the Lord hadde fillid the hows of the Lord.
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn àlùfáà kò le è ṣiṣẹ́ ìsìn wọn nítorí ìkùùkuu náà, nítorí ògo Olúwa kún inú tẹmpili Ọlọ́run.

< 2 Chronicles 5 >