< 2 Chronicles 16 >

1 Forsothe in the sixe and thrittithe yeer of his rewme Baasa, the kyng of Israel, stiede in to Juda, and cumpasside Rama with a wal, that no man of the rewme of Asa myyte go out ether entre sikirli.
Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
2 Sotheli Asa brouyte forth gold and siluer fro the tresours of the hows of the Lord, and fro the kyngis tresouris; and sente to Benadab, kyng of Sirie, that dwellide in Damask,
Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
3 and seide, Boond of pees is bitwixe me and thee, and my fadir and thi fadir hadden acordyng; wherfor Y sente to thee siluer and gold, that whanne thou hast broke the boond of pees, which thou hast with Baasa, king of Israel, thou make hym to go awei fro me.
“Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
4 And whanne this was foundun, Benadab sente princes of hise oostis to the citees of Israel, whiche smytiden Ahion, and Dan, and Abelmaym, and alle the wallid citees of Neptalym.
Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
5 And whanne Baasa hadde herd this, he ceesside to bilde Rama, and left his werk.
Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
6 Forsothe kyng Asa took al Juda, and thei token fro Rama the stonys and trees, whiche Baasa hadde maad redi to bildyng; and he bildide of tho Gabaa, and Maspha.
Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
7 In that tyme Anany, the profete, cam to Asa, kyng of Juda, and seide to hym, For thou haddist trist in the kyng of Sirie, and not in `thi Lord God, herfor the oost of `the kyng of Sirie aschapide fro thin hond.
Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
8 Whether `Ethiopiens and Libiens weren not many mo in charis, and knyytis, and ful greet multitude; whiche whanne thou haddist bileuyd to the Lord, he bitook in to thin hondis?
Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
9 For the iyen of the Lord biholden al the erthe, and yyuen strengthe to hem, that with perfit herte bileuen in to hym. Therfor thou hast do folili, and for this, yhe, in present tyme batels schulen rise ayens thee.
Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
10 And Asa was wrooth ayens the prophete, and comaundide hym to be sent in to stockis. Forsothe the Lord hadde indignacioun greetli on this thing, and killide ful many of the puple in that tyme.
Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
11 Sotheli the firste and the laste werkis of Asa ben writun in the book of kyngis of Juda and of Israel.
Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
12 Forsothe Asa was sijk ful gretli in the akynge of feet, in the nyne and thrittithe yeer of his rewme; and nether in his sikenesse he souyte the Lord, but tristide more in the craft of lechis.
Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
13 And Asa slepte with hise fadris, and he was deed in the oon and fourtithe yeer of his rewme.
Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
14 And thei birieden him in his sepulcre, which he hadde maad to hym silf in the cytee of Dauid; and thei puttiden hym on his bed ful of swete smellynge spices and oynementis of hooris, that weren `maad togidere bi the craft of oynement makeris, and thei brenten on hym with ful greet cost.
wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.

< 2 Chronicles 16 >