< 1 Samuel 10 >

1 Forsothe Samuel took `a vessel of oyle, and schedde out on the heed of Saul, and kisside hym, and seide, Lo! the Lord hath anoyntid thee in to prince on hys eritage; and thou schalt delyuere his puple fro the hond of his enemyes, that ben `in his cumpas. And this a tokene to thee, that the Lord hath anoyntid thee in to prince;
Samuẹli sì mú ìgò kékeré tí òróró wà nínú rẹ̀, ó sì dà á sí orí Saulu. Ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu, wí pé, “Olúwa kò ha tí fi òróró yàn ọ ní olórí lórí ohun ìní rẹ̀?
2 whanne thou schalt go fro me to day, thou schalt fynde twei men bisidis `the sepulcre of Rachel, in `the endis of Beniamyn, in myddai, clensynge grete dichis; and thei schulen seie to thee, The femel assis ben foundun, whiche thou yedist to seke; and while the assis ben lefte, thi fadir is bisy for you, and seith, What schal Y do of my sone?
Bí ìwọ bá kúrò lọ́dọ̀ mi lónìí, ìwọ yóò bá ọkùnrin méjì pàdé lẹ́bàá ibojì Rakeli ní Selsa, ní agbègbè Benjamini. Wọ́n yóò sọ fún ọ pé, ‘Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ìwọ jáde lọ láti wá ní wọn tí rí. Nísinsin yìí, baba à rẹ tí dákẹ́ kò ronú nípa wọn mọ́, ó sì ń dààmú nípa à rẹ. Ó ń béèrè, “Kí ni èmi yóò ṣe nípa ọmọ mi?”’
3 And whanne thou hast go fro thennus, and hast passid ferthere, and hast come to the ook of Tabor, thre men, stiynge to God in to Bethel, schulen fynde thee there, o man berynge thre kydis, and another man berynge thre kakis of breed, and an other man berynge a galoun of wyn.
“Nígbà náà, ìwọ yóò lọ láti ibẹ̀ títí yóò fi dé ibi igi ńlá Tabori. Ọkùnrin mẹ́ta tí wọ́n ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní Beteli yóò pàdé rẹ níbẹ̀. Ọ̀kan yóò mú ọmọ ewúrẹ́ mẹ́ta lọ́wọ́, èkejì, ìṣù àkàrà mẹ́ta àti ẹ̀kẹta yóò mú ìgò wáìnì.
4 And whanne thei han gret thee, thei schulen yyue to thee twei loues, and thou schalt take of `the hond of hem.
Wọ́n yóò kí ọ, wọn yóò sì fún ọ ní ìṣù àkàrà méjì, tí ìwọ yóò gbà lọ́wọ́ wọn.
5 After these thingis thou schalt come in to the `hil of the Lord, where is the stondyng, that is, forselet, of Filisteis; and whanne thou schalt entre in to the citee, there thou schalt haue metynge thee the flok of prophetis comynge doun fro the hiy place, and a sautree, and tympane, and pipe, and harpe bifor hem, and hem prophesiynge.
“Lẹ́yìn náà, ìwọ yóò lọ sí òkè Ọlọ́run, níbi tí ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini wà. Bí ìwọ ti ń súnmọ́ ìlú náà, ìwọ yóò bá àwọn wòlíì tí ó tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ bọ̀ láti ibi gíga, pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn, tambori àti fèrè àti haapu níwájú wọn, wọn yóò sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀.
6 And the Spirit of the Lord schal skippe in to thee, and thou schalt prophecie with hem, and thou schalt be chaungid in to another man.
Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé ọ, ìwọ yóò sì sọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú wọn, ìwọ yóò sì di ẹni ọ̀tọ̀.
7 Therfor whanne alle thesse signes bifallen to thee, do thou, what euer thingis thin hond fyndith, `that is, dispose thee to regne comelili and myytily, for the Lord is with thee.
Bí ìwọ bá ti rí àmì wọ̀nyí, ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà láti ṣe, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.
8 And thou schalt go doun bifor me in to Galgala; for Y schal come doun to thee, that thou offre an offryng, and offre pesible sacrifices; bi seuene daies thou schalt abide, til I come to thee, and shewe to thee what thou schal do.
“Lọ ṣáájú mi sí Gilgali. Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá láti rú ẹbọ sísun àti láti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ dúró fún ọjọ́ méje títí èmi yóò fi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti sọ fún ọ ohun tí ó yẹ tí ìwọ yóò ṣe.”
9 Therfor whanne Saul hadde turnede awei his schuldre to go fro Samuel, God chaungide another herte to Saul, and alle these signes camen in that dai.
Bí Saulu ti yípadà láti fi Samuẹli sílẹ̀, Ọlọ́run yí ọkàn Saulu padà àti pé gbogbo àmì wọ̀nyí sì wá sí ìmúṣẹ ní ọjọ́ náà.
10 And thei camen to the forseid hil, and lo! a cumpeny of prophetis metynge hym; and the Spirit of the Lord `scippide on hym, and he propheciede in the myddis of hem.
Nígbà tí wọ́n dé òkè Gibeah náà, àwọn wòlíì tí ó ń tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ pàdé rẹ̀, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e nínú agbára, ó sì darapọ̀ bá wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
11 Sotheli alle men, that knewen hym yisterdai and the thrid dai ago, sien that he was with the prophetis, and that he prophesiede, and thei seiden togidere, What thing bifelde to the sone of Cys? Whether also Saul is among prophetis?
Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó ti mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀ rí i tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú àwọn wòlíì, wọ́n bi ara wọn, “Kí ni ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí ọmọ Kiṣi yìí. Ṣé Saulu wà lára àwọn wòlíì ni?”
12 And o man answeride to another man, and seide, And who is `his fadir? Therfor it was turned in to a prouerbe, Whether also Saul is among prophetis?
Ọkùnrin kan tí ó ń gbé níbẹ̀ dáhùn pé, “Ta ni baba wọn?” Ó ti di ohun tí a fi ń pa òwe pé, ǹjẹ́ Saulu náà wà lára àwọn wòlíì bí?
13 Forsothe Saul ceside to prophesie, and he cam to an hiy place.
Lẹ́yìn tí Saulu dákẹ́ sísọ àsọtẹ́lẹ̀, ó lọ sí ibi gíga.
14 And the brothir of `the fadir of Saul seide to hym, and to his child, Whidur yeden ye? And thei answeriden, To seke the femal assis; and whanne we founden `not thoo, we camen to Samuel.
Nísinsin yìí, arákùnrin baba Saulu béèrè lọ́wọ́ Saulu àti ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Níbo ni ẹ lọ?” Ó wí pé, “À ń wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,” ṣùgbọ́n nígbà tí a kò rí wọn, a lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli.
15 And the brother of his fadir seide to hym, Schewe thou to me what Samuel seide to thee.
Arákùnrin baba Saulu wí pé, “Sọ fún mi ohun tí Samuẹli wí fún un yín.”
16 And Saul seide to `the brother of hys fadir, He schewide to vs, that the femal assis weren foundun. Sotheli Saul schewide not to hym of the word of rewme, `which word Samuel spak to hym.
Saulu dáhùn pé, “Ó fi dá wa lójú pé wọ́n ti rí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún arákùnrin baba a rẹ̀ ohun tí Samuẹli sọ nípa ọba jíjẹ.
17 And Samuel clepide togidere the puple to the Lord in Masphat;
Samuẹli pé àwọn ọmọ Israẹli jọ sí iwájú Olúwa ní Mispa.
18 and he seide to the sones of Israel, The Lord God of Israel seith these thingis, Y ledde Israel out of the lond of Egipt, and Y delyuerede you fro the hond of Egipcians, and fro the hond of alle kyngis that turmentiden you.
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Èmi mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, Èmi sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ agbára Ejibiti àti gbogbo ìjọba tí ó ń pọ́n ọn yín lójú.’
19 Forsothe to day ye han caste awei youre Lord God, which aloone sauyde you fro alle youre yuelis and tribulaciouns; and ye seiden, Nay, but ordeyne thou a kyng on vs. Now therfor stonde ye bifor the Lord bi youre lynagis, and bi meynees.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti kọ Ọlọ́run yín, tí ó gbà yín kúrò nínú gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú yín. Ẹ̀yin sì ti sọ pé, ‘Rárá, yan ọba kan fún wa.’ Báyìí, ẹ kó ara yín jọ níwájú Olúwa ní ẹ̀yà àti ìdílé yín.”
20 And Samuel settide to gidere alle the lynages of Israel, and lot felde on the lynage of Beniamyn.
Nígbà tí Samuẹli mú gbogbo ẹ̀yà Israẹli súnmọ́ tòsí, ó yan ẹ̀yà Benjamini.
21 And he settide togidere the lynage of Beniamyn, and the meynees therof; and lot felde on the meynees of Mathri, and it cam `til to Saul, the son of Cys. Therfor thei souyten hym, and he was not foundun there.
Ó kó ẹ̀yà Benjamini síwájú ní ìdílé ìdílé, a sì yan ìdílé Matiri. Ní ìparí a sì yan Saulu ọmọ Kiṣi. Ṣùgbọ́n ní ìgbà tí wọ́n wá a, a kò rí i,
22 And aftir these thingis thei counseliden the Lord, whether Saul schulde come thidur. And the Lord answeride, Lo! he is hid at hoom.
bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Olúwa pé, “Ṣé ọkùnrin náà ti wá sí bí ni?” Olúwa sì sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ láàrín àwọn ẹrù.”
23 Therfor thei runnen, and token hym fro thennus; and he stood in the myddil of the puple, and was hiyere than al the puple fro the schulder and `aboue.
Wọ́n sáré, wọ́n sì mú un jáde wá. Bí ó ti dúró láàrín àwọn ènìyàn, ó sì ga ju gbogbo àwọn tí ó kù lọ láti èjìká rẹ̀ sókè.
24 And Samuel seide to al the puple, Certis ye seen whom the Lord hath chose; for noon in al the puple is lijk hym. And al the puple cryede, and seide, Lyue the kyng!
Samuẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ṣé ẹ ti ri ọkùnrin tí Olúwa ti yàn? Kò sí ẹnìkan bí i rẹ̀ láàrín gbogbo àwọn ènìyàn.” Nígbà náà àwọn ènìyàn kígbe pé, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn!”
25 Forsothe Samuel spak to the puple the lawe of rewme, and wroot in a book, and puttide vp bifor the Lord. And Samuel dilyuerede al the puple, ech man in to his hows;
Samuẹli ṣàlàyé fún àwọn ènìyàn àwọn ìlànà ìjọba. Ó kọ wọ́n sínú ìwé, ó sì fi lélẹ̀ níwájú Olúwa. Lẹ́yìn náà, Samuẹli tú àwọn ènìyàn ká olúkúlùkù sí ilé e rẹ̀.
26 but also Saul yede in to his hous in to Gabaath; and the part of the oost yede with hym, whose hertis God hadde touchid.
Saulu náà padà sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah. Àwọn akọni ọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi ọwọ́ tọ́ ọkàn wọ́n sì sìn ín.
27 Forsothe the sones of Belyal seiden, Whether this man may saue vs? And thei dispisiden hym, and brouyten not yiftis, `that is, preisyngis, to him; forsothe he `dissymelide hym to here.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Beliali wí pé, “Báwo ni ọkùnrin yìí yóò ti ṣe gbà wá?” Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọn kò sì mú ẹ̀bùn wá fún un, ṣùgbọ́n Saulu fọwọ́ lérán.

< 1 Samuel 10 >