< 1 Kings 19 >

1 Forsothe Achab telde to Jezabel alle thingis whiche Elie hadde do, and how he hadde slayn by swerd alle the prophetis of Baal.
Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
2 And Jezabel sente a messanger to Elie, and seide, Goddis do these thingis to me, and adde these thingis, no but to morewe in this our Y schal putte thi lijf as the lijf of oon of hem.
Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
3 Therfor Elie dredde, and roos, and yede whidur euer wille bar hym; and he cam in to Bersabe of Juda, and he lefte there his child;
Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
4 and yede in to deseert, the weie of o dai. And whanne he cam, and sat vndir o iunypere tre, he axide to his soule, that he schulde die; and he seide, Lord, it suffisith to me, take my soule; for Y am not betere than my fadris.
nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
5 And he castide forth hym silf, and slepte in the schadewe of the iunypere tree. And lo! the aungel of the Lord touchide hym, and seide to hym, Rise thou, and ete.
Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
6 He bihelde, and, lo! at his heed was a loof bakun vndur aischis, and a vessel of watir. Therfor he ete, and drank, and slepte eft.
Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
7 And the aungel of the Lord turnede ayen the secounde tyme, and touchide hym; and `the aungel seide to hym, Rise thou, and ete; for a greet weie is to thee.
Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
8 And whanne he hadde rise, he ete, and drank; and he yede in the strengthe of that mete bi fourti dayes and fourti nyytis, `til to Oreb, the hil of God.
Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
9 And whanne he hadde come thidur, he dwellide in a denne; and lo! the word of the Lord `was maad to him, and seide to hym, Elie, what doist thou here?
Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
10 And he answeride, Bi feruent loue Y louede feruentli, for the Lord God of oostis; for the sones of Israel forsoken the couenaunt of the Lord; thei destrieden thin auters, and killiden bi swerd thi prophetis; and Y am left aloone, and thei seken my lijf, that thei do it awei.
Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
11 And he seide to Elie, Go thou out, and stonde in the hil, bifor the Lord. And lo! the Lord passith, and a greet wynde, and strong, turnynge vpsodoun hillis, and al to brekinge stonys bifor the Lord; not in the wynde ys the Lord. And aftir the wynd is a stirynge; not in the stiryng is the Lord.
Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
12 And aftir the stiryng is fier; not in the fier is the Lord. And aftir the fier is the issyng of thinne wynd; there is the Lord.
Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
13 And whanne Elie hadde herd this, he hilide his face with a mentil, and he yede out, and stood in the dore of the denne. And a vois spak to hym, and seide, Elie, what doist thou here?
Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
14 And he answeride, Bi feruent loue Y louede feruentli, for the Lord God of oostis; for the sones of Israel forsoken thi couenaunt; thei distrieden thin auteris, and thei killiden bi swerd thi prophetis; and Y am left aloone, and thei seken my lijf, that thei do it awey.
Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
15 And the Lord seide to hym, Go, and turne ayen in to thi weie, bi the deseert, in to Damask; and whanne thou schalt come thidur, thou schalt anoynte Asahel kyng on Sirie;
Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
16 and thou schalt anoynte kyng on Israel Hieu, the sone of Namsi; sotheli thou schalt anoynte prophete for thee, Elise, sone of Saphat, which is of Abelmeula.
Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
17 And it schal be, who euer schal fle the swerd of Asahel, Hieu schal sle hym; and who euer schal fle the swerd of Hieu, Elise schal sle hym.
Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
18 And Y schal leeue to me in Israel seuene thousynde of men, of whiche the knees ben not bowid bifor Baal, and ech mouth that worschipide not hym, and kisside hond.
Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
19 Therfor Elie yede forth fro thennus, and foond Elise, sone of Saphat, erynge in twelue yockis of oxis; and he was oon in the twelue yockis of oxys, erynge. And whanne Elie hadde come to hym, Elie castide his mentil on hym.
Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
20 Which ran anoon after Elie, whanne the oxis weren left, and seide, Y preie thee, kysse Y my fadir and my modir, and so Y schal sue thee. And Elie seide to hym, Go thou, and turne ayen, for Y haue do to thee that that was myn.
Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
21 `Sotheli he turnede ayen fro Elie, and took tweine oxis, and killide hem; and with the plow of oxis he sethide the fleischis, and yaf to the puple, and thei eeten; and he roos, and yede, and suede Elie, and `mynystride to hym.
Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.

< 1 Kings 19 >