< 1 Chronicles 9 >

1 Therfor al Israel was noumbrid, and the summe of hem was writun in the book of kyngis of Israel and of Juda; and thei weren translatid in to Babiloyne for her synne.
Gbogbo Israẹli ni a kọ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá nínú ìwé àwọn ọba Israẹli. Àwọn ènìyàn Juda ni a kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli nítorí àìṣòótọ́ wọn.
2 Sotheli thei that dwelliden first in her citees, and in the possessiouns of Israel, and the preestis, and the dekenes, and Natyneys, dwelliden in Jerusalem.
Nísinsin yìí, àwọn tí ó kọ́kọ́ tún tẹ̀dó lórí ohun ìní wọn ní ìlú wọn ni díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa.
3 Of the sones of Juda, and of the sones of Beniamyn, also of the sones of Effraym, and of Manasses;
Àwọn tí ó wá láti Juda láti Benjamini àti láti Efraimu àti Manase tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu jẹ́:
4 Othi, the sone of Amyud, sone of Semry, sone of Omroy, sone of Bonny, of the sones of Phares, the sone of Juda;
Uttai ọmọ Ammihudu, ọmọ Omri, ọmọ Imri, ọmọ Bani, ìran ọmọ Peresi ọmọ Juda.
5 and of Sylom, Asia, the firste gendrid, and his sones;
Àti nínú ará Ṣilo: Asaiah àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀.
6 sotheli of the sones of Zaray, Heuel, and hise britheren; sixe hundrid fourescore and ten.
Ní ti ará Sera: Jeueli. Àwọn ènìyàn láti Juda sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́wàá.
7 Forsothe of the sones of Beniamyn; Salo, the sone of Mosollam, the sones of Odoia, the sones of Asana,
Àti nínú àwọn ọmọ Benjamini ni: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Hodafiah; ọmọ Hasenuah;
8 and Jobanya, the sone of Jerobam, and Ela, the sone of Ozi, the sones of Mochozi, and Mosollam, the sone of Saphacie, sone of Rahuel, sone of Jebanye, and the britheren of hem,
Ibinaiah ọmọ Jerohamu; Ela ọmọ Ussi, ọmọ Mikri; àti Meṣullamu ọmọ Ṣefatia; ọmọ Reueli, ọmọ Ibinijah.
9 bi her meynees; nyne hundrid sixe and fifti. Alle these weren princes of her kynredis by the housis of her fadris.
Àwọn ènìyàn láti Benjamini gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ ọ́ nínú ìran wọn nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó dín mẹ́rìnlélógójì. Gbogbo àwọn ọkùnrin yí jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé.
10 Forsothe of the preestis, Joiada, Jozarib, and Jachym;
Ní ti àwọn àlùfáà: Jedaiah; Jehoiaribi; Jakini;
11 and Azarie, the sone of Helchie, sone of Mosollam, sone of Sadoch, sone of Maraioth, sone of Achitob, was bischop of the hows of the Lord.
Asariah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, olórí tí ó ń bojútó ilé Ọlọ́run;
12 Forsothe Adaias, sone of Jeroam, sone of Phasor, sone of Melchia, and Masaia, sone of Adihel, sone of Jezra, sone of Mosollam, sone of Mosselamoth, sone of Emyner,
Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah; àti Masai ọmọ Adieli, ọmọ Jahisera, ọmọ Meṣullamu ọmọ Meṣilemiti, ọmọ Immeri.
13 also her britheren, prynces bi her meynees, weren a thousynde seuene hundrid and fourescoore, men strongeste in bodili myyt, to make the werk of seruyce in the hows of the Lord.
Àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀sán ó dín méjì. Wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin, tí wọ́n lè dúró fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run.
14 Forsothe of dekenes, Semeya, the sone of Assub, sone of Ezricam, sone of Asebyn, of the sones of Merary;
Ní ti àwọn ará Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ará Merari;
15 also Balthasar the carpenter, and Galebeth, and Machama, sone of Mycha, sone of Zechri, sone of Asaph,
Bakibakari, Hereṣi, Galali àti Mattaniah, ọmọ Mika, ọmọ Sikri, ọmọ Asafu;
16 and Obdias, sone of Semey, sone of Calaal, sone of Idithum, and Barachie, the sone of Asa, sone of Helcana, that dwellide in the porchis of Methophati.
Obadiah ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni; àti Berekiah ọmọ Asa, ọmọ Elkana, tí ó ń gbé nínú àwọn ìlú àwọn ará Netofa.
17 Sotheli the porteris weren Sellum, and Achub, and Thelmon, and Achyman, and the britheren of hem; Sellum was the prince;
Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà: Ṣallumu, Akkubu, Talmoni, Ahimani àti arákùnrin wọn, Ṣalumu olóyè wọn,
18 til to that tyme thei kepten bi her whilis in the yate of the kyng at the eest, of the sones of Leuy.
ti wà ní ipò ìdúró ní ẹnu-ọ̀nà ọba ní apá ìhà ìlà-oòrùn títí di àkókò yí. Wọ̀nyí ni àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí ó jẹ́ ti ìpàgọ́ àwọn ará Lefi.
19 Sellum forsothe, the sone of Chore, sone of Abiasaph, sone of Chore, with hise britheren, and with the hows of his fadir; these ben the sones of Chore on the werkis of the seruyce, keperis of the porchis of the tabernacle, and the meynees of hem kepten bi whilis the entryng of the castelis of the Lord.
Ṣallumu ọmọ Kore ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora, àti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Láti ìdílé rẹ̀ (àwọn ará Korati) ni ó dúró fún ṣíṣọ́ ìloro ẹnu-ọ̀nà àgọ́ gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti ń dúró fún ṣíṣọ́ àbáwọlé ibùgbé Olúwa.
20 Forsothe Phynees, the sone of Eleazar, was the duyk of hem bifor the Lord.
Ní ìgbà àkọ́kọ́ Finehasi ọmọ Eleasari jẹ́ olórí fún àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà, Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
21 Sotheli Zacarie, the sone of Mosollam, was porter of the yate of the tabernacle of witnessyng.
Sekariah, ọmọ Meṣelemiah jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àbáwọlé sí àgọ́ ibi ìpàdé.
22 Alle these chosun in to porteris bi yatis weren twei hundrid and twelue, and weren discryued in her owne townes, which dekenes Dauid and Samuel, the prophete, ordeyneden in her feith,
Gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, àwọn tí a yàn láti jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àwọn ìloro jẹ́ igba ó lé méjìlá. A ka àwọn wọ̀nyí nípa ìdílé ní ìletò wọn. Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ni a ti yàn sí ipò láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Samuẹli, aríran, nítorí òtítọ́ wọn.
23 both hem and the sones of hem in the doris of the hows of the Lord, and in the tabernacle of witnessyng, bi her whiles.
Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ni ó wà fún ṣíṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ilé tí a pè ní àgọ́.
24 Porteris weren bi foure coostis, that is, at the eest, and at the west, and at the north, and at the south.
Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà wà ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin: ìlà-oòrùn, ìwọ̀-oòrùn àríwá àti gúúsù.
25 Forsothe her britheren dwelliden in townes, and camen in her sabatis fro tyme til to tyme.
Àwọn arákùnrin wọn ní àwọn ìletò wọn ní láti wá ní àkókò dé àkókò láti pín iṣẹ́ ìsìn wọn fún àkókò ọjọ́ méje.
26 Al the noumbre of porteris was bitakun to these foure dekenes, and thei kepten the chaumbris, and the tresours of the hows of the Lord.
Ṣùgbọ́n àwọn olórí alábojútó ẹnu-ọ̀nà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ni a yàn fún àwọn iyàrá àti àwọn àpótí ìṣúra ní ilé Ọlọ́run.
27 Also thei dwelliden in her kepyngis bi the cumpas of the temple of the Lord, that whanne tyme were, thei schulden opene the yatis eerli.
Wọ́n á lo gbogbo òru ní dídúró yí ilé Ọlọ́run ká, nítorí wọ́n ní láti ṣọ́ ọ, wọ́n sì ní àṣẹ sí kọ́kọ́rọ́ fún ṣíṣí i ní àràárọ̀.
28 Men of her kyn weren also on the vessels of seruyce; for the vessels weren borun in at noumbre, and weren borun out of hem.
Díẹ̀ wà ní ìdí ohun èlò tí à ń lò fún ìsìn ilé Ọlọ́run; wọn a máa kà á nígbà tí wọ́n gbé e wọlé àti nígbà tí a kó wọn jáde.
29 And thei that hadden the vesselis of seyntuarie bitakun to her kepyng, weren souereyns on flour, and wyn, and oile, and encense, and swete smellinge spyceries.
Àwọn mìíràn ni a yàn láti bojútó ohun èlò àti gbogbo ohun èlò ilé tí a yà sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run, àti ìyẹ̀fun àti ọtí èso àjàrà àti òróró náà, tùràrí àti tùràrí olóòórùn dídùn.
30 Sotheli the sones of preestis maden oynementis of swete smellynge spiceries.
Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn àlùfáà ni ó ń bojútó pípò tùràrí olóòórùn dídùn papọ̀.
31 And Mathatias dekene, the firste gendrid sone of Sellum of the kynrede of Chore, was the souereyn of alle thingis that weren fried in the friyng panne.
Ará Lefi tí a sọ ní Mattitiah àkọ́bí ọmọkùnrin Ṣallumu ará Kora ni a yàn, tí ń ṣe alábojútó ohun tí a dín.
32 Sotheli men of the sones of Caath, the britheren of hem, weren on the looues of settyng forth, that thei schulden make redi euere newe looues bi ech sabat.
Àti nínú àwọn arákùnrin wọn, nínú àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣe ìtọ́jú àkàrà ìfihàn, láti máa pèsè rẹ̀ ní ọjọọjọ́ ìsinmi.
33 These ben the princis of chauntouris bi the meynees of Leuytis, that dwelliden in chaumbris, so that thei schulden serue contynueli dai and nyyt in her seruyce.
Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Lefi dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì ṣe lára iṣẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ náà lọ́sàn, lóru.
34 The heedis of Leuitis bi her meynees, the princes, dwelliden in Jerusalem.
Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Lefi, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
35 Forsothe there dwelliden in Gabaon; Jaiel, the fadir of Gabaon, and the name of his wijf Maacha;
Jeieli baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka,
36 Abdon, his firste gendrid sone, and Sur, and Cys, and Baal,
pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀ jẹ́ Abdoni, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu.
37 and Ner, and Nadab, and Gedor, and Ahaio, and Zacharie, and Macelloth; forsothe Macelloth gendride Semmaa;
Gedori, Ahio, Sekariah àti Mikiloti.
38 these dwelliden euene ayens her britheren in Jerusalem, with her britheren.
Mikiloti jẹ́ baba Ṣimeamu, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
39 Sotheli Ner gendride Cys, and Cys gendride Saul, and Saul gendride Jonathan, and Melchisue, and Abynadab, and Hisbaal.
Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba a Saulu, àti Saulu baba a Jonatani, àti Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
40 Forsothe the sone of Jonathan was Myribaal, and Myribaal gendride Mycha.
Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali, tí ó jẹ́ baba Mika.
41 Sotheli the sones of Micha weren Phiton, and Malech, and Thara;
Àwọn ọmọ Mika: Pitoni. Meleki, Tarea àti Ahasi.
42 forsothe Aaz gendride Jara, and Jara gendride Alamath, and Azmoth, and Zamri; and Zamri gendride Moosa,
Ahasi jẹ́ baba Jada, Jada jẹ́ baba Alemeti, Asmafeti, Simri, sì Simri jẹ́ baba Mosa.
43 sotheli Moosa gendride Baana, whose sone Raphaia gendride Elisa, of whom Esel was gendrid.
Mosa jẹ́ baba Binea; Refaiah jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
44 Forsothe Esel hadde sixe sones bi these names, Ezricam, Bochru, Hismael, Saria, Obdia, Anan; these weren the sones of Hesel.
Aseli ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli Ṣeariah, Obadiah àti Hanani, gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.

< 1 Chronicles 9 >