< Philippians 2 >
1 If then I can appeal to you as the followers of Christ, if there is any persuasive power in love and any common sharing of the Spirit, or if you have any tender-heartedness and compassion, make my joy complete by being of one mind,
Bí ìwọ bá ní ìmúlọ́kànle nítorí pé ìwọ wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú Kristi, bi ìtùnú kan bá wà nínú ìfẹ́ rẹ̀, bí ìdàpọ̀ Ẹ̀mí kan bá wà, bí ìyọ́nú àti ìṣeun bá wà,
2 united by mutual love, with harmony of feeling giving your minds to one and the same object.
síbẹ̀ ẹ mú ayọ̀ mi kún nínú ìṣọ̀kan yín, nípa ìfẹ́ kan náà, wíwà ní ẹ̀mí kan náà àti ète kan náà.
3 Do nothing in a spirit of factiousness or of vainglory, but, with true humility, let every one regard the rest as being of more account than himself;
Ẹ má ṣe ohunkóhun nínú ìlépa ara tàbí ògo asán, ṣùgbọ́n ní ìrẹ̀lẹ̀ ọkàn kí olúkúlùkù ro àwọn ẹlòmíràn sí ẹni ti ó sàn ju òun lọ.
4 each fixing his attention, not simply on his own interests, but on those of others also.
Kí olúkúlùkù yín má ṣe ro ohun ti ara rẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n ti ẹlòmíràn pẹ̀lú.
5 Let the same disposition be in you which was in Christ Jesus.
Nínú ìbáṣepọ̀ yin pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn, ẹ ni irú ìlépa ọkàn náà bí ti Kristi Jesu.
6 Although from the beginning He had the nature of God He did not reckon His equality with God a treasure to be tightly grasped.
Ẹni tí, bí o tilẹ̀ jẹ́ ìrísí Ọlọ́run, kò kà á sí ohun tí ìbá fi ìwọra gbámú láti bá Ọlọ́run dọ́gba.
7 Nay, He stripped Himself of His glory, and took on Him the nature of a bondservant by becoming a man like other men.
Ṣùgbọ́n ó bọ́ ògo rẹ̀ sílẹ̀, ó sì mú àwọ̀ ìránṣẹ́, a sì ṣe é ni àwòrán ènìyàn.
8 And being recognized as truly human, He humbled Himself and even stooped to die; yes, to die on a cross.
Ó sì wà ní àwòrán ènìyàn, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, o sì tẹríba títí de ojú ikú, àní ikú lórí àgbélébùú.
9 It is in consequence of this that God has also so highly exalted Him, and has conferred on Him the Name which is supreme above every other,
Nítorí náà, Ọlọ́run ti gbé e ga sí ipele tí ó ga jùlọ, ó sì ti fi orúkọ kan ti ó borí gbogbo orúkọ fún un,
10 in order that in the Name of JESUS every knee should bow, of beings in Heaven, of those on the earth, and of those in the underworld,
pé ni orúkọ Jesu ni kí gbogbo eékún máa wólẹ̀, ní ọ̀run, àti ní orí ilẹ̀ ayé àti ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
11 and that every tongue should confess that JESUS CHRIST is LORD, to the glory of God the Father.
àti pé kí gbogbo ahọ́n jẹ́wọ́ pé, Jesu Kristi ni Olúwa, fún ògo Ọlọ́run Baba.
12 Therefore, my dearly-loved friends, as I have always found you obedient, labour earnestly with fear and trembling--not merely as though I were present with you, but much more now since I am absent from you--labour earnestly, I say, to make sure of your own salvation.
Nítorí náà ẹ̀yin ará mi, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ń gbọ́rọ̀ nígbà gbogbo, kì í ṣe nígbà ti mo wà lọ́dọ̀ yín nìkan, ṣùgbọ́n pàápàá nísinsin yìí tí èmi kò sí ni àárín yín, ẹ máa ṣiṣẹ́ ìgbàlà yín yọrí pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì,
13 For it is God Himself whose power creates within you the desire to do His gracious will and also brings about the accomplishment of the desire.
nítorí pé Ọlọ́run ni ó n ṣiṣẹ́ nínú yín, láti fẹ́ àti láti ṣiṣẹ́ fún ète rere rẹ̀.
14 Be ever on your guard against a grudging and contentious spirit,
Ẹ máa ṣe ohun gbogbo láìsí ìkùnsínú àti ìjiyàn.
15 so that you may always prove yourselves to be blameless and spotless--irreproachable children of God in the midst of a crooked and perverse generation, among whom you are seen as heavenly lights in the world,
Kí ẹ̀yin lè jẹ́ aláìlẹ́gàn àti oníwà mímọ́, ọmọ Ọlọ́run, aláìlábàwọ́n, láàrín oníwà wíwọ́ àti alárékérekè orílẹ̀-èdè láàrín àwọn ẹni tí a ń rí yín bí ìmọ́lẹ̀ ní ayé.
16 holding out to them a Message of Life. It will then be my glory on the day of Christ that I did not run my race in vain nor toil in vain.
Bí ẹ sì ṣe di ọ̀rọ̀ ìyè mú gírígírí, kí èmi lè ṣògo ni ọjọ́ Kristi pé èmi kò sáré lásán, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ṣe làálàá lásán.
17 Nay, even if my life is to be poured as a libation upon the sacrificial offering of your faith, I rejoice, and I congratulate you all.
Ṣùgbọ́n, bí a tilẹ̀ ń dà mí bí ọtí-ìrúbọ sórí ẹbọ iṣẹ́ ìsìn ìgbàgbọ́ yín, inú mi dùn, mo sì ń bá gbogbo yín yọ̀ pẹ̀lú.
18 And I bid you also share my gladness, and congratulate me.
Bákan náà ni kí ẹ̀yin máa yọ̀, kí ẹ sì máa bá mi yọ̀ pẹ̀lú.
19 But, if the Lord permits it, I hope before long to send Timothy to you, that I, in turn, may be cheered by getting news of you.
Mo ni ìrètí nínú Jesu Olúwa, láti rán Timotiu sí yín ni àìpẹ́ yìí, kí èmi pẹ̀lú lè ni ìfọ̀kànbalẹ̀ nígbà tí mo bá gbúròó yín.
20 For I have no one likeminded with him, who will cherish a genuine care for you.
Nítorí èmi kò ni ẹlòmíràn tí ó dàbí rẹ̀, tí yóò máa fi tinútinú ṣe àníyàn yín.
21 Everybody concerns himself about his own interests, not about those of Jesus Christ.
Nítorí gbogbo wọn ni ó tọ́jú nǹkan ti ara wọn, kì í ṣe àwọn nǹkan ti Jesu Kristi.
22 But you know Timothy's approved worth--how, like a child working with his father, he has served with me in furtherance of the Good News.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin mọ̀ pé Timotiu pegedé, gẹ́gẹ́ bí ọmọ lọ́dọ̀ baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ti ń bá mi ṣiṣẹ́ pọ̀, nínú iṣẹ́ ìyìnrere.
23 So it is he that I hope to send as soon as ever I see how things go with me;
Nítorí náà, mo ní ìrètí láti rán sí yín ní àìpẹ́ tí mo bá wòye bí yóò ti rí fún mi.
24 but trusting, as I do, in the Lord, I believe that I shall myself also come to you before long.
Ṣùgbọ́n mo ní gbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa, pé èmi tìkára mi pẹ̀lú yóò wá ní àìpẹ́.
25 Yet I deem it important to send Epaphroditus to you now--he is my brother and comrade both in labour and in arms, and is your messenger who has ministered to my needs.
Mo kà á sí pé n kò lè ṣàìrán Epafiroditu arákùnrin mi sí yín, àti olùbáṣiṣẹ́ pọ̀ mi, àti ọmọ-ogun ẹlẹgbẹ́ mi, ìránṣẹ́ yín pẹ̀lú, tí ẹ rán láti ṣè ránṣẹ́ fún mi nínú àìní mi.
26 I send him because he is longing to see you all and is distressed at your having heard of his illness.
Nítorí tí ọkàn rẹ̀ fà sí gbogbo yín, ó sì kún fún ìbànújẹ́, nítorí tí ẹ̀yin gbọ́ pé ó ṣe àìsàn.
27 For it is true that he has been ill, and was apparently at the point of death; but God had pity on him, and not only on him, but also on me, to save me from having sorrow upon sorrow.
Nítòótọ́ ni ó ti ṣe àìsàn títí dé ojú ikú, ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti ṣàánú fún un; kì í sì í ṣe fún òun nìkan, ṣùgbọ́n fún èmi pẹ̀lú kí èmi má ṣe ni ìbànújẹ́ lórí ìbànújẹ́.
28 I am therefore all the more eager to send him, in the hope that when you see him again you may be glad and I may have the less sorrow.
Nítorí náà ni mo ṣe ní ìtara láti rán an, pé nígbà tí ẹ̀yin bá sì tún rí i, kí ẹ̀yin lè yọ̀ àti kí ìkáyà sókè mi lè dínkù.
29 Receive him therefore with heartfelt Christian joy, and hold in honour men like him;
Nítorí náà, ẹ fi ayọ̀ púpọ̀ gbà á nínú Olúwa; kí ẹ sì máa bu ọlá fún irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀.
30 because it was for the sake of Christ's work that he came so near death, hazarding, as he did, his very life in endeavouring to make good any deficiency that there might be in your gifts to me.
Nítorí iṣẹ́ Kristi ni ó ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú, tí ó sì fi ẹ̀mí ara rẹ̀ wéwu, láti mu àìtó iṣẹ́ ìsìn yín sí mi kún.