< Hebrews 9 >
1 Now even the first Covenant had regulations for divine worship, and had also its sanctuary--a sanctuary belonging to this world.
Bẹ́ẹ̀ ni májẹ̀mú àkọ́kọ́ ní ìlànà fún ìsìn àti ibi mímọ́ ti ayé yìí.
2 For a sacred tent was constructed--the outer one, in which were the lamp and the table and the presented loaves; and this is called the Holy place.
A gbé àgọ́ kan dìde. Nínú yàrá rẹ̀ àkọ́kọ́ ni a ti rí ọ̀pá fìtílà, tábìlì, àti àkàrà ìfihàn. Èyí tí a ń pè ní ibi mímọ́.
3 And behind the second veil was a sacred tent called the Holy of holies.
Àti lẹ́yìn aṣọ ìkélé kejì, òun ni àgọ́ tí à ń pè ní Ibi Mímọ́ Jùlọ;
4 This had a censer of gold, and the ark of the Covenant lined with gold and completely covered with gold, and in it were a gold vase which held the manna, and Aaron's rod which budded and the tables of the Covenant.
tí ó ní àwo tùràrí wúrà, àti àpótí ẹ̀rí tí a fi wúrà bò yíká, nínú èyí tí ìkòkò wúrà tí ó ní manna gbé wà, àti ọ̀pá Aaroni tí o rúdí, àti àwọn wàláà májẹ̀mú;
5 And above the ark were the Cherubim denoting God's glorious presence and overshadowing the Mercy-seat. But I cannot now speak about all these in detail.
àti lórí àpótí ni àwọn kérúbù ògo ti i síji bo ìtẹ́ àánú; èyí tí a kò lè sọ̀rọ̀ rẹ̀ nísinsin yìí lọ́kọ̀ọ̀kan.
6 These arrangements having long been completed, the priests, when conducting the divine services, continually enter the outer tent.
Ǹjẹ́ nígbà tí a ti ṣe ètò nǹkan wọ̀nyí báyìí, àwọn àlùfáà a máa lọ nígbàkígbà sínú àgọ́ èkínní, wọn a máa ṣe iṣẹ́ ìsìn.
7 But into the second, the High Priest goes only on one day of the year, and goes alone, taking with him blood, which he offers on his own behalf and on account of the sins which the people have ignorantly committed.
Ṣùgbọ́n sínú èkejì ni olórí àlùfáà nìkan máa ń lọ lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo lọ́dún, fún ara rẹ̀, àti fún ìṣìnà àwọn ènìyàn.
8 And the lesson which the Holy Spirit teaches is this--that the way into the true Holy place is not yet open so long as the outer tent still remains in existence.
Ẹ̀mí Mímọ́ ń tọ́ka èyí pé a kò ì tí ì ṣí ọ̀nà Ibi Mímọ́ Jùlọ sílẹ̀ níwọ̀n ìgbà tí àgọ́ èkínní bá sì dúró,
9 And this is a figure--for the time now present--answering to which both gifts and sacrifices are offered, unable though they are to give complete freedom from sin to him who ministers.
èyí tí i ṣe àpẹẹrẹ fún ìgbà ìsinsin yìí. Gẹ́gẹ́ bí ètò yìí, a ń mú ẹ̀bùn àti ẹbọ wá, tí kò lè mú ẹ̀rí ọkàn olùsìn di pípé.
10 For their efficacy depends only on meats and drinks and various washings, ceremonies pertaining to the body and imposed until a time of reformation.
Èyí sì wà nínú ohun jíjẹ àti ohun mímu àti onírúurú ìwẹ̀, tí í ṣe ìlànà ti ara nìkan tí a fi lélẹ̀ títí fi di ìgbà àtúnṣe.
11 But Christ appeared as a High Priest of the blessings that are soon to come by means of the greater and more perfect Tent of worship, a tent which has not been built with hands--that is to say does not belong to this material creation--
Ṣùgbọ́n nígbà tí Kristi dé bí olórí àlùfáà àwọn ohun rere tí ń bọ̀, nípasẹ̀ àgọ́ tí o tóbi ti ó sì pé ju ti ìṣáájú, èyí tí a kò fi ọwọ́ dá, èyí yìí ni, tí kì í ṣe ti ẹ̀dá yìí.
12 and once for all entered the Holy place, taking with Him not the blood of goats and calves, but His own blood, and thus procuring eternal redemption for us. (aiōnios )
Bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ àti ọmọ màlúù, ṣùgbọ́n nípa ẹ̀jẹ̀ òun tìkára rẹ̀, o wọ Ibi Mímọ́ Jùlọ lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, lẹ́yìn tí ó ti rí ìdáǹdè àìnípẹ̀kun gbà fún wa. (aiōnios )
13 For if the blood of goats and bulls and the ashes of a heifer sprinkling those who have contracted defilement make them holy so as to bring about ceremonial purity,
Nítorí bí ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ àti ti akọ màlúù àti eérú ẹgbọrọ abo màlúù tí a fi wọ́n àwọn tí a ti sọ di aláìmọ́ ba ń sọ ni di mímọ́ fún ìwẹ̀nùmọ́ ara:
14 how much more certainly shall the blood of Christ, who strengthened by the eternal Spirit offered Himself to God, free from blemish, purify your consciences from lifeless works for you to serve the ever-living God? (aiōnios )
mélòó mélòó ni ẹ̀jẹ̀ Kristi, ẹni, nípa Ẹ̀mí ayérayé, tí ó fi ara rẹ̀ rú ẹbọ sí Ọlọ́run láìní àbàwọ́n, yóò wẹ èérí ọkàn yín nù kúrò nínú òkú iṣẹ́ láti sin Ọlọ́run alààyè? (aiōnios )
15 And because of this He is the negotiator of a new Covenant, in order that, since a life has been given in atonement for the offences committed under the first Covenant, those who have been called may receive the eternal inheritance which has been promised to them. (aiōnios )
Àti nítorí èyí ni ó ṣe jẹ́ alárinà májẹ̀mú tuntun pé bí ikú ti ń bẹ fún ìdáǹdè àwọn ìrékọjá ti o tí wà lábẹ́ májẹ̀mú ìṣáájú, kí àwọn tí a ti pè lè rí ìlérí ogún àìnípẹ̀kun gbà. (aiōnios )
16 For where there is a legal 'will,' there must also be a death brought forward in evidence--the death of him who made it.
Nítorí níbi tí ìwé ogún bá gbé wà, ikú ẹni tí o ṣe é kò lè ṣe àìsí pẹ̀lú;
17 And a will is only of force in the case of a deceased person, being never of any avail so long as he who made it lives.
nítorí ìwé ogún ní agbára lẹ́yìn ìgbà tí ènìyàn bá kú, nítorí kò ní agbára rárá nígbà tí ẹni tí o ṣè e bá ń bẹ láààyè.
18 Accordingly we find that the first Covenant was not inaugurated without blood.
Nítorí náà ni a kò ṣe ya májẹ̀mú ìṣáájú pàápàá sí mímọ́ láìsí ẹ̀jẹ̀.
19 For when Moses had proclaimed to all the people every commandment contained in the Law, he took the blood of the calves and of the goats and with them water, scarlet wool and hyssop, and sprinkled both the book itself and all the people,
Nítorí nígbà tí Mose ti sọ gbogbo àṣẹ nípa ti òfin fún gbogbo àwọn ènìyàn, ó mú ẹ̀jẹ̀ ọmọ màlúù àti ti ewúrẹ́, pẹ̀lú omi, àti òwú òdòdó, àti ewé hísópù ó sì fi wọ́n àti ìwé pàápàá àti gbogbo ènìyàn.
20 saying, "This is the blood which confirms the Covenant that God has made binding upon you."
Wí pé, “Èyí ní ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú tí Ọlọ́run pàṣẹ fún yín.”
21 And in the same way he also sprinkled blood upon the Tent of worship and upon all the vessels used in the ministry.
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ó sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n àgọ́, àti gbogbo ohun èlò ìsìn.
22 Indeed we may almost say that in obedience to the Law everything is sprinkled with blood, and that apart from the outpouring of blood there is no remission of sins.
Ó sì fẹ́rẹ̀ jẹ́ ohun gbogbo ni a fi ẹ̀jẹ̀ wẹ̀nù gẹ́gẹ́ bí òfin; àti pé láìsí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ kò sí ìdáríjì.
23 It was needful therefore that the copies of the things in Heaven should be cleansed in this way, but that the heavenly things themselves should be cleansed with more costly sacrifices.
Nítorí náà a kò lè ṣàì fi ìwọ̀nyí wé àwọn àpẹẹrẹ ohun tí ń bẹ lọ́run mọ́; ṣùgbọ́n ó yẹ kí a fi ẹbọ tí ó sàn ju ìwọ̀nyí lọ wẹ àwọn ohun ọ̀run pàápàá mọ́; ṣùgbọ́n ó yẹ kí a fi ẹbọ tí ó sàn ju ìwọ̀nyí lọ wẹ àwọn ohun ọ̀run pàápàá mọ́.
24 For not into a Holy place built by men's hands--a mere copy of the reality--did Christ enter, but He entered Heaven itself, now to appear in the presence of God on our behalf.
Nítorí Kristi kò wọ ibi mímọ́ tí a fi ọwọ́ ṣe lọ tí i ṣe àpẹẹrẹ ti òtítọ́; ṣùgbọ́n ó lọ sí ọ̀run pàápàá, nísinsin yìí láti farahàn ní iwájú Ọlọ́run fún wa.
25 Nor did He enter for the purpose of many times offering Himself in sacrifice, just as the High Priest enters the Holy place, year after year, taking with him blood not his own.
Kì í sí i ṣe pé kí ó lè máa fi ara rẹ̀ rú ẹbọ nígbàkígbà, bí olórí àlùfáà tí máa ń wọ inú Ibi Mímọ́ Jùlọ lọ lọ́dọọdún ti òun pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ti kì í ṣe tirẹ̀,
26 In that case Christ would have needed to suffer many times, from the creation of the world onwards; but as a matter of fact He has appeared once for all, at the Close of the Ages, in order to do away with sin by the sacrifice of Himself. (aiōn )
bí bẹ́ẹ̀ bá ni, òun ìbá tí máa jìyà nígbàkígbà láti ìpìlẹ̀ ayé. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ni ó fi ara hàn lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo lópin ayé láti mu ẹ̀ṣẹ̀ kúrò nípa ẹbọ ara rẹ̀. (aiōn )
27 And since it is reserved for all mankind once to die, and afterwards to be judged;
Níwọ́n bí a sì ti fi lélẹ̀ fún gbogbo ènìyàn láti kú lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí ìdájọ́,
28 so the Christ also, having been once offered in sacrifice in order that He might bear the sins of many, will appear a second time, separated from sin, to those who are eagerly expecting Him, to make their salvation complete.
bẹ́ẹ̀ ni Kristi pẹ̀lú lẹ́yìn tí a ti fi rú ẹbọ lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo láti ru ẹ̀ṣẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀, yóò farahàn ní ìgbà kejì láìsí ẹ̀ṣẹ̀ fún àwọn tí n wo ọ̀nà rẹ̀ fún ìgbàlà.