< Ephesians 5 >

1 Therefore be imitators of God, as His dear children.
Nítorí náà, ẹ máa ṣe àfarawé Ọlọ́run bí àwọn olùfẹ́ ọmọ,
2 And live and act lovingly, as Christ also loved you and gave Himself up to death on our behalf as an offering and sacrifice to God, yielding a fragrant odor.
ẹ sì máa rìn ní ìfẹ́, gẹ́gẹ́ bí Kristi pẹ̀lú ti fẹ́ wa, tí ó sì fi ara rẹ̀ fún wa ní ọrẹ àti ẹbọ fún Ọlọ́run fún òórùn dídùn.
3 But fornication and every kind of impurity, or covetousness, let them not even be mentioned among you, for they ought not to be named among God's people.
Ṣùgbọ́n àgbèrè àti gbogbo ìwà èérí, tàbí ojúkòkòrò, kí a má tilẹ̀ dárúkọ rẹ̀ láàrín yín mọ́, bí ó ti yẹ àwọn ènìyàn mímọ́.
4 Avoid shameful and foolish talk and low jesting--they are all alike discreditable--and in place of these give thanks.
Ìbá à ṣe ìwà ọ̀bùn, àti ìṣọ̀rọ̀ òmùgọ̀, tàbí ìṣẹ̀fẹ̀ àwọn ohun tí kò tọ́; ṣùgbọ́n ẹ kúkú máa dúpẹ́.
5 For be well assured that no fornicator or immoral person and no money-grubber--or in other words idol-worshipper--has any share awaiting him in the Kingdom of Christ and of God.
Nítorí ẹ̀yin mọ èyí dájú pé, kò sí panṣágà, tàbí aláìmọ́ ènìyàn, tàbí wọ̀bìà (tí í ṣé abọ̀rìṣà), tí yóò ni ìpín kan ni ìjọba Kristi àti Ọlọ́run.
6 Let no one deceive you with empty words, for it is on account of these very sins that God's anger is coming upon the disobedient.
Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni fi ọ̀rọ̀ asán tàn yín jẹ: nítorí nípasẹ̀ nǹkan wọ̀nyí ní ìbínú Ọlọ́run fi ń bọ̀ wá sórí àwọn ọmọ aláìgbọ́ràn.
7 Therefore do not become sharers with them.
Nítorí náà ẹ má ṣe jẹ́ alájọpín pẹ̀lú wọn.
8 There was a time when you were nothing but darkness. Now, as Christians, you are Light itself.
Nítorí ẹ̀yin tí jẹ́ òkùnkùn lẹ́ẹ̀kan ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin dí ìmọ́lẹ̀, nípa tí Olúwa: ẹ máa rín gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀
9 Live and act as sons of Light--for the effect of the Light is seen in every kind of goodness, uprightness and truth--
(nítorí èso Ẹ̀mí ni ìṣoore, àti òdodo àti òtítọ́).
10 and learn in your own experiences what is fully pleasing to the Lord.
Ẹ sì máa wádìí ohun tí í ṣe ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa.
11 Have nothing to do with the barren unprofitable deeds of darkness, but, instead of that, set your faces against them;
Ẹ má sì ṣe bá àwọn oníṣẹ́ òkùnkùn kẹ́gbẹ́ pọ̀, ṣùgbọ́n ẹ kúkú máa bá wọn wí.
12 for the things which are done by these people in secret it is disgraceful even to speak of.
Nítorí ìtìjú tilẹ̀ ni láti máa sọ̀rọ̀ nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí àwọn aláìgbọ́ràn ń ṣe ní ìkọ̀kọ̀.
13 But everything can be tested by the light and thus be shown in its true colors; for whatever shines of itself is light.
Ṣùgbọ́n ohun gbogbo tí a tú síta ni ìmọ́lẹ̀ ń fì hàn: nítorí ohunkóhun tí ó bá fi nǹkan hàn, ìmọ́lẹ̀ ni.
14 For this reason it is said, "Rise, sleeper; rise from among the dead, and Christ will shed light upon you."
Nítorí náà ni ó ṣe wí pé, “Jí, ìwọ̀ ẹni tí ó sun, sí jíǹde kúrò nínú òkú Kristi yóò sì fún ọ ní ìmọ́lẹ̀.”
15 Therefore be very careful how you live and act. Let it not be as unwise men, but as wise.
Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa rìn ní ìwà pípé, kì í ṣé bí àwọn òmùgọ̀, ṣùgbọ́n bí àwọn ọlọ́gbọ́n;
16 Buy up your opportunities, for these are evil times.
ẹ máa ra ìgbà padà, nítorí búburú ní àwọn ọjọ́.
17 On this account do not prove yourselves wanting in sense, but try to understand what the Lord's will is.
Nítorí náà, ẹ má ṣé jẹ aláìlóye, ṣùgbọ́n ẹ máa mòye ohun tí ìfẹ́ Olúwa jásí.
18 Do not over-indulge in wine--a thing in which excess is so easy--
Ẹ má sí ṣe mú wáìnì ní àmupara, nínú èyí tí rúdurùdu wà; ṣùgbọ́n ẹ kún fún Ẹ̀mí Mímọ́.
19 but drink deeply of God's Spirit. Speak to one another with psalms and hymns and spiritual songs. Sing and offer praise in your hearts to the Lord.
Ẹ sì máa bá ara yín sọ̀rọ̀ nínú Saamu, àti orin ìyìn, àti orin Ẹ̀mí, ẹ máa kọrin, kí ẹ sì máa kọrin dídùn ní ọkàn yín sí Olúwa.
20 Always and for everything let your thanks to God the Father be presented in the name of our Lord Jesus Christ;
Ẹ máa dúpẹ́ nígbà gbogbo fún ohun gbogbo lọ́wọ́ Ọlọ́run, àní Baba, ní orúkọ Jesu Kristi Olúwa wá.
21 and submit to one another out of reverence for Christ.
Ẹ máa tẹríba fún ara yín ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
22 Married women, submit to your own husbands as if to the Lord;
Ẹ̀yin aya, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọkọ yín, gẹ́gẹ́ bí fún Olúwa.
23 because a husband is the Head of his wife as Christ also is the Head of the Church, being indeed the Saviour of this His Body.
Nítorí pé ọkọ ni ó ń ṣe orí aya, gẹ́gẹ́ bí Kristi tí i ṣe orí ìjọ, tí òun si ń ṣe ara rẹ̀, Òun sì ni Olùgbàlà rẹ̀.
24 And just as the Church submits to Christ, so also married women should be entirely submissive to their husbands.
Nítorí náà gẹ́gẹ́ bí ìjọ tí i tẹríba fún Kristi, bẹ́ẹ̀ sì ní kì àwọn aya máa ṣe sí ọkọ wọn ní ohun gbogbo.
25 Married men, love your wives, as Christ also loved the Church and gave Himself up to death for her;
Ẹ̀yin ọkọ, ẹ fẹ́ràn àwọn aya yín, gẹ́gẹ́ bí Kristi tí fẹ́ràn ìjọ, tí ó sì fi ara rẹ̀ fún un.
26 in order to make her holy, cleansing her with the baptismal water by the word,
Kí òun lè sọ ọ́ di mímọ́ lẹ́yìn tí ó tí fi ọ̀rọ̀ wẹ̀ ẹ́ nínú agbada omí.
27 that He might present the Church to Himself a glorious bride, without spot or wrinkle or any other defect, but to be holy and unblemished.
Kí òun lé mú un wá sọ́dọ̀ ara rẹ̀ bí ìjọ tí ó ní ògo ní àìlábàwọ́n, tàbí àlébù kan, tàbí irú nǹkan bá-wọ̀n-ọn-nì: ṣùgbọ́n kí ó lè jẹ́ mímọ́ àti aláìlábùkù.
28 So too married men ought to love their wives as much as they love themselves. He who loves his wife loves himself.
Bẹ́ẹ̀ ní ó tọ́ kí àwọn ọkùnrin máa fẹ́ràn aya wọn gẹ́gẹ́ bí ara àwọn fúnra wọn.
29 For never yet has a man hated his own body. On the contrary he feeds and cherishes it, just as Christ feeds and cherishes the Church;
Nítorí kò sì ẹnìkan tí ó ti kórìíra ara rẹ̀; bí kò ṣe pé kí ó máa bọ́ ọ kí ó sì máa ṣìkẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Kristi sì ti ń ṣe sí ìjọ.
30 because we are, as it were, parts of His Body.
Nítorí pé àwa ni ẹ̀yà ara rẹ̀, àti tí ẹran-ara rẹ̀, àti egungun ara rẹ̀.
31 "For this reason a man is to leave his father and his mother and be united to his wife, and the two shall be as one."
Nítorí èyí ní ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, òun yóò sì dàpọ̀ mọ́ aya rẹ̀, àwọn méjèèjì yóò sì di ara kan.
32 That is a great truth hitherto kept secret: I mean the truth concerning Christ and the Church.
Àṣírí ńlá ní èyí: ṣùgbọ́n èmí ń sọ nípá ti Kristi àti tí ìjọ.
33 Yet I insist that among you also, each man is to love his own wife as much as he loves himself, and let a married woman see to it that she treats her husband with respect.
Ṣùgbọ́n kí olúkúlùkù yín fẹ́ràn aya rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun fúnra rẹ̀; kí aya kí ó sì bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀.

< Ephesians 5 >