< Psalms 87 >

1 A Psalm [or] Song for the sons of Korah. His foundation [is] in the holy mountains.
Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin. Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;
2 The LORD loveth the gates of Zion more than all the dwellings of Jacob.
Olúwa fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.
3 Glorious things are spoken of thee, O city of God. (Selah)
Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀, ìlú Ọlọ́run,
4 I will make mention of Rahab and Babylon to them that know me: behold Philistia, and Tyre, with Cush; this [man] was born there.
“Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi: Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi, yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’”
5 And of Zion it shall be said, This and that man was born in her: and the Highest himself shall establish her.
Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ, “Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀, àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀.”
6 The LORD shall count, when he writeth up the people, [that] this [man] was born there. (Selah)
Olúwa yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀: “Eléyìí ni a bí ní Sioni.”
7 As well the singers as the players on instruments [shall be there]: all my springs [are] in thee.
Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu ohun èlò orin yóò wí pé, “Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ.”

< Psalms 87 >