< Proverbs 29 >

1 He, that being often reproved hardeneth [his] neck, shall suddenly be destroyed, and that without remedy.
Ẹni tí ó sì ń ṣorí kunkun lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbáwí yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
2 When the righteous are in authority, the people rejoice: but when the wicked beareth rule, the people mourn.
Nígbà tí olódodo bá ń gbilẹ̀, àwọn ènìyàn a yọ̀ nígbà tí ènìyàn búburú ń ṣàkóso, àwọn ènìyàn ń kórìíra.
3 He that loveth wisdom rejoiceth his father: but he that keepeth company with harlots spendeth [his] substance.
Ènìyàn tí ó fẹ́ràn ọgbọ́n mú kí baba rẹ̀ láyọ̀ ṣùgbọ́n ẹni ti ń bá panṣágà kẹ́gbẹ́ ba ọrọ̀ ọ rẹ̀ jẹ́.
4 The king by judgment establisheth the land: but he that receiveth gifts overthroweth it.
Nípa ìdájọ́ òdodo ni ọba fi í mú ìlú tòrò nini, ṣùgbọ́n èyí tí ń ṣe ojúkòkòrò àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fà á lulẹ̀.
5 A man that flattereth his neighbor spreadeth a net for his feet.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá tan aládùúgbò rẹ̀ ó ń dẹ àwọ̀n de ẹsẹ̀ ẹ rẹ̀.
6 In the transgression of an evil man [there is] a snare: but the righteous doth sing and rejoice.
Ẹ̀ṣẹ̀ ènìyàn ibi ni ó jẹ́ ìdẹ̀kùn rẹ̀ ṣùgbọ́n olódodo le è kọrin kí ó sì máa yọ̀.
7 The righteous considereth the cause of the poor: [but] the wicked regardeth not to know [it].
Olódodo ń máa ro ọ̀rọ̀ tálákà, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kò sú sí i láti rò ó.
8 Scornful men bring a city into a snare: but wise [men] turn away wrath.
Àwọn ẹlẹ́yà a máa ru ìlú sókè, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn máa ń mú ìbínú kúrò.
9 [If] a wise man contendeth with a foolish man, whether he rageth or laugheth, [there is] no rest.
Bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn bá lọ sí ilé ẹjọ́ pẹ̀lú aláìgbọ́n aláìgbọ́n a máa bínú a sì máa jà, kò sì ní sí àlàáfíà.
10 The blood-thirsty hate the upright: but the just seek his soul.
Àwọn tí ó ń tàjẹ̀ sílẹ̀ kò rí ẹni dídúró ṣinṣin wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa olódodo.
11 A fool uttereth all his mind: but a wise [man] keepeth it in till afterwards.
Aláìgbọ́n ènìyàn fi gbogbo ẹnu rẹ̀ bínú ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa kó ìbínú rẹ̀ ní ìjánu.
12 If a ruler hearkeneth to lies, all his servants [are] wicked.
Bí olórí bá fetí sí irọ́, gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ a di ènìyàn búburú lójú rẹ̀.
13 The poor and the deceitful man meet together: the LORD enlighteneth both their eyes.
Tálákà ènìyàn àti aninilára jọ ní àbùdá yìí, Olúwa jẹ́ kí ojú àwọn méjèèjì máa ríran.
14 The king that faithfully judgeth the poor, his throne shall be established for ever.
Bí ọba kan bá ń ṣe ìdájọ́ tálákà pẹ̀lú òtítọ́ ìtẹ́ ìjọba rẹ yóò fìdímúlẹ̀ nígbà gbogbo.
15 The rod and reproof give wisdom: but a child left [to himself] bringeth his mother to shame.
Ọ̀pá ìbániwí ń fún ni ní ọgbọ́n ṣùgbọ́n ọmọ tí a fi sílẹ̀ fúnra rẹ̀ a dójútì ìyá rẹ̀.
16 When the wicked are multiplied, transgression increaseth: but the righteous shall see their fall.
Nígbà tí ènìyàn búburú ń gbilẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀ṣẹ̀ ń gbilẹ̀ ṣùgbọ́n olódodo yóò rí ìṣubú wọn.
17 Correct thy son, and he shall give thee rest; yes, he shall give delight to thy soul.
Bá ọmọ rẹ wí, yóò sì fún ọ ní àlàáfíà yóò sì mú inú dídùn wá sí inú ọkàn rẹ.
18 Where [there is] no vision, the people perish: but he that keepeth the law, happy [is] he.
Níbi tí kò ti sí ìfihàn, àwọn ènìyàn a gbé ìgbé ayé àìbìkítà, ṣùgbọ́n ìbùkún ní fún àwọn tí ń pa òfin mọ́.
19 A servant will not be corrected by words: for though he understandeth, he will not answer.
A kò le fi ọ̀rọ̀ lásán kìlọ̀ fún ìránṣẹ́ bí ó tilẹ̀ yé e, kò ní kọbi ara sí i.
20 Seest thou a man [that is] hasty in his words? [there is] more hope of a fool than of him.
Ǹjẹ́ ó rí ènìyàn tí ń kánjú sọ̀rọ̀? Ìrètí wà fún aláìgbọ́n jù ú lọ.
21 He that delicately bringeth up his servant from a child shall have him at length become [his] son.
Bí ènìyàn kan bá kẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ lákẹ̀ẹ́jù láti kékeré yóò mú ìbànújẹ́ wá ní ìgbẹ̀yìn.
22 An angry man stirreth up strife, and a furious man aboundeth in transgression.
Oníbìínú ènìyàn a ru ìjà sókè, onínú-fùfù ènìyàn a sì máa dá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀.
23 A man's pride shall bring him low: but honor shall uphold the humble in spirit.
Ìgbéraga ènìyàn a máa sọ ọ́ di ẹni ilẹ̀ ṣùgbọ́n onírẹ̀lẹ̀ ènìyàn a máa gba iyì kún iyì.
24 Whoever is partner with a thief, hateth his own soul: he heareth cursing, and discloseth [it] not.
Ẹni tí ó ń kó ẹgbẹ́, olè kórìíra ọkàn ara rẹ̀, ó ń gbọ́ èpè olóhun kò sì le è fọhùn.
25 The fear of man bringeth a snare: but he who putteth his trust in the LORD shall be safe.
Ìbẹ̀rù ènìyàn kan yóò sì di ìdẹ̀kùn ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bẹ̀rù Olúwa wà láìléwu.
26 Many seek the ruler's favor; but [every] man's judgment [cometh] from the LORD.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ń wá ojúrere alákòóso, ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ènìyàn tí ń gba ìdájọ́ òdodo.
27 An unjust man [is] an abomination to the just: and [he that is] upright in the way [is] abomination to the wicked.
Olódodo kórìíra àwọn aláìṣòótọ́: ènìyàn búburú kórìíra olódodo.

< Proverbs 29 >