< Psalms 145 >

1 David’s Psalm of praise. I will extol thee, my God, O king; and I will bless thy name for ever and ever.
Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
2 Every day will I bless thee; and I will praise thy name for ever and ever.
Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
3 Great is the LORD, and greatly to be praised; and his greatness is unsearchable.
Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
4 One generation shall praise thy works to another, and shall declare thy mighty acts.
Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
5 I will speak of the glorious honour of thy majesty, and of thy wondrous works.
Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
6 And men shall speak of the might of thy terrible acts: and I will declare thy greatness.
Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
7 They shall abundantly utter the memory of thy great goodness, and shall sing of thy righteousness.
Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
8 The LORD is gracious, and full of compassion; slow to anger, and of great mercy.
Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
9 The LORD is good to all: and his tender mercies are over all his works.
Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
10 All thy works shall praise thee, O LORD; and thy saints shall bless thee.
Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
11 They shall speak of the glory of thy kingdom, and talk of thy power;
Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
12 To make known to the sons of men his mighty acts, and the glorious majesty of his kingdom.
kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
13 Thy kingdom is an everlasting kingdom, and thy dominion endureth throughout all generations.
Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
14 The LORD upholdeth all that fall, and raiseth up all those that are bowed down.
Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
15 The eyes of all wait upon thee; and thou givest them their food in due season.
Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
16 Thou openest thy hand, and satisfiest the desire of every living creature.
Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
17 The LORD is righteous in all his ways, and holy in all his works.
Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
18 The LORD is near to all them that call upon him, to all that call upon him in truth.
Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
19 He will fulfil the desire of them that fear him: he also will hear their cry, and will save them.
Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
20 The LORD preserveth all them that love him: but all the wicked will he destroy.
Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
21 My mouth shall speak the praise of the LORD: and let all flesh bless his holy name for ever and ever.
Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.

< Psalms 145 >