< Psalms 108 >
1 A Song or Psalm of David. O God, my heart is fixed; I will sing and give praise, even with my glory.
Orin. Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run, ọkàn mi dúró ṣinṣin èmi ó máa kọrin, èmi ó máa fi ọkàn mi kọrin.
2 Awake, psaltery and harp: I myself will awake early.
Jí ohun èlò orin àti haapu! Èmi ó jí ní kùtùkùtù,
3 I will praise thee, O LORD, among the people: and I will sing praises to thee among the nations.
èmi ó yìn ọ́, Olúwa, nínú àwọn orílẹ̀-èdè, èmi ó kọrin rẹ nínú àwọn ènìyàn.
4 For thy mercy is great above the heavens: and thy truth reacheth to the clouds.
Nítorí tí o tóbi ní àánú rẹ ju àwọn ọ̀run lọ àti òdodo rẹ dé àwọsánmọ̀.
5 Be thou exalted, O God, above the heavens: and thy glory above all the earth;
Gbé ara rẹ ga, Ọlọ́run, lórí àwọn ọ̀run, àti ògo rẹ lórí gbogbo ayé.
6 That thy beloved may be delivered: save with thy right hand, and answer me.
Kí a sì lè gba àwọn olùfẹ́ rẹ là; fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ìgbàlà, kí o sì dá mi lóhùn
7 God hath spoken in his holiness; I will rejoice, I will divide Shechem, and measure out the valley of Succoth.
Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀ pé, “Èmi yóò yọ̀, èmi yóò pín Ṣekemu, èmi yóò sì wọn àfonífojì Sukkoti kúrò.
8 Gilead is mine; Manasseh is mine; Ephraim also is the strength of my head; Judah is my lawgiver;
Gileadi ni tèmi, Manase ni tèmi, Efraimu ni ìbòrí mi, Juda ni olófin mi,
9 Moab is my washpot; over Edom will I cast out my shoe; over Philistia will I triumph.
Moabu sì ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ni èmi ó bọ́ bàtà mi sí, lórí òkè Filistia ni èmi yóò hó ìhó ayọ̀.”
10 Who will bring me into the strong city? who will lead me into Edom?
Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi? Ta ni yóò sìn mí wá sí Edomu?
11 Wilt not thou, O God, who hast cast us off? and wilt not thou, O God, go forth with our armies?
Ìwọ Ọlọ́run ha kọ́, ìwọ tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀. Ọlọ́run ìwọ kì yóò bá àwọn jagunjagun wa jáde mọ́.
12 Give us help from trouble: for vain is the help of man.
Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ nínú ìpọ́njú, nítorí ìrànlọ́wọ́ ènìyàn asán ni.
13 Through God we shall do valiantly: for he will tread down our enemies.
Nípasẹ̀ Ọlọ́run ni àwa ó ṣe akin nítorí òun ó tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.