< Psalms 55 >
1 For the chief musician; on stringed instruments. A maschil of David. Give ear to my prayer, God; and do not hide yourself from my plea.
Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Fi etí sí àdúrà mi, Ọlọ́run, má ṣe fi ojú pa ẹ̀bẹ̀ mi rẹ́:
2 Pay attention to me and answer me; I have no rest in my troubles
gbọ́ mi kí o sì dá mi lóhùn. Èrò mi ń dà mí láàmú, èmi sì ń pariwo.
3 because of the voice of my enemies, because of the oppression of the wicked; for they bring trouble on me and persecute me in anger.
Sí ohùn àwọn ọ̀tá ni, nítorí igbe àwọn ènìyàn búburú; nítorí wọ́n mú ìjìyà wá sórí mi, wọ́n sì kẹ́gàn mi nínú ìbínú wọn.
4 My heart trembles within me, and the terrors of death have fallen on me.
Ọkàn mi wà nínú ìrora pẹ̀lú; ẹ̀rù ikú kọjú ìjà sí mi.
5 Fearfulness and trembling have come on me, and horror has overwhelmed me.
Ìbẹ̀rù àti ìwárìrì wa sí ara mi; ìbẹ̀rù ti bò mí mọ́lẹ̀.
6 I said, “Oh, if only I had wings like a dove! Then would I fly away and be at rest.
Èmi sọ pé, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà! Èmi ìbá fò lọ kí n sì sinmi.
7 See, then I would wander far away; I would stay in the wilderness. (Selah)
Èmi ìbá sálọ, jìnnà réré, kí ń sì dúró sí aginjù;
8 I would hurry to a shelter from the stormy wind and tempest.”
èmi ìbá yára lọ́ si ibùgbé mi ní ibi ààbò, jìnnà kúrò nínú ìjì àti ẹ̀fúùfù líle.”
9 Devour them, Lord, confuse their language! For I have seen violence and strife in the city.
Da àwọn ẹni búburú láàmú, Olúwa, da ahọ́n wọn rú, nítorí èmi rí ìwà agbára àti ìjà ní ìlú náà.
10 Day and night they go about on its walls; iniquity and mischief are in the middle of it.
Ọ̀sán àti òru ni wọ́n fi ń rìn gbogbo odi kiri; ìwà ìkà àti èébú wà láàrín rẹ̀.
11 Wickedness is in the middle of it; oppression and deceit do not leave its streets.
Ìwà búburú ń bẹ ní àárín rẹ̀; ẹ̀tàn àti èké kò kúrò ní ìgboro rẹ̀.
12 For it was not an enemy who rebuked me, then I could have borne it; neither was it he who hated me who raised himself up against me, then I would have hidden myself from him.
Tí ọ̀tá bá tàbùkù mi, èmi yóò fi ara mọ́ ọn; tí ọ̀tá bá gbé ara rẹ̀ ga sí mi, èmi ìbá sá pamọ́ fún un.
13 But it was you, a man equal to myself, my companion and my close friend.
Ṣùgbọ́n tí ó bá ṣe ìwọ, ọkùnrin bí ẹgbẹ́ mi, ẹlẹgbẹ́ mi, àti ọ̀rẹ́ tí ó súnmọ́ mi,
14 We had sweet fellowship together; we walked in the house of God with the throng.
pẹ̀lú ẹni tí èmi ti jẹ ìgbádùn adùn ìdàpọ̀, bí a ṣe ń rìn pẹ̀lú àwùjọ ní ilé Ọlọ́run.
15 Let death come suddenly on them; let them go down alive to Sheol, for wickedness is where they live, right among them. (Sheol )
Kí ikú kí ó dé bá wọn, kí wọn ó lọ láààyè sí isà òkú, jẹ́ kí wọn ó sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú ìpayà, nítorí tí ìwà búburú ń bẹ ní ibùjókòó wọn, àti nínú wọn. (Sheol )
16 As for me, I will call on God, and Yahweh will save me.
Ṣùgbọ́n èmi pe Ọlọ́run; Olúwa yóò sì gbà mí.
17 In the evening, morning and at noonday I complain and moan; he will hear my voice.
Ní alẹ́, ní òwúrọ̀ àti ní ọ̀sán èmi sọkún jáde nínú ìpọ́njú, o sì gbọ́ ohùn mi.
18 He will safely rescue my life from the battle that was against me, for those who fought against me were many.
Ó rà mí padà láìléwu kúrò nínú ogun tí ó dìde sí mi, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó dìde sí mi.
19 God, the one who rules from eternity, will hear them and humiliate them. (Selah) They never change, and they do not fear God.
Ọlọ́run yóò gbọ́, yóò sì pọ́n wọn lójú àní, ẹni tí ó ti jókòó láti ìgbàanì (Sela) nítorí tí wọn kò ní àyípadà, tí wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọ́run.
20 My friend has raised his hands against those who were at peace with him; he has not respected the covenant that he had.
Ọ̀rẹ́ mi yìí ti dalẹ̀ èmi ọ̀rẹ́ rẹ̀; ó ti ba májẹ̀mú rẹ̀ jẹ́.
21 His mouth was smooth as butter, but his heart was hostile; his words were softer than oil, yet they were actually drawn swords.
Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ kúnná ju òrí-àmọ́, ṣùgbọ́n ogun wà ni àyà rẹ̀; ọ̀rọ̀ rẹ̀ fẹ́lẹ́ ju òróró lọ, ṣùgbọ́n idà fífàyọ ní wọn.
22 Place your burdens on Yahweh, and he will sustain you; he will never allow a righteous person to totter.
Gbé ẹrù rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ Olúwa yóò sì mú ọ dúró; òun kò ní jẹ́ kí olódodo ṣubú.
23 But you, God, will bring the wicked down into the pit of destruction; bloodthirsty and deceitful men will not live even half as long as others, but I will trust in you.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni yóò mu àwọn ọ̀tá mi wá sí ihò ìparun; àwọn ẹni tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ àti ẹni ẹ̀tàn, kì yóò gbé ààbọ̀ ọjọ́ wọn. Ṣùgbọ́n fún èmi, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ.