< Psalms 102 >

1 A prayer of the afflicted when he is faint and pours out his lament before Yahweh. Hear my prayer, Yahweh; hear my cry to you.
Àdúrà olùpọ́njú tí àárẹ̀ mú, tí ó sí ọkàn rẹ̀ payá níwájú Olúwa. Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa, jẹ́ kí igbe ẹ̀bẹ̀ mi kí ó wá sí ọ̀dọ̀ rẹ.
2 Do not hide your face from me in my time of trouble. Listen to me. When I call out to you, answer me quickly.
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ tí èmi wà nínú ìpọ́njú. Dẹ etí rẹ sí mi; nígbà tí mo bá pè, dá mi lóhùn kíákíá.
3 For my days pass away like smoke, and my bones burn like fire.
Nítorí tí ọjọ́ mi run bí èéfín; egungun mi sì jóná bí ààrò.
4 My heart is crushed, and I am like grass that has withered. I forget to eat any food.
Àyà mi lù, ó sì rọ bí i koríko; mo gbàgbé láti jẹ oúnjẹ mi.
5 With my continual groaning, I have become very thin.
Nítorí ohùn ìkérora mi, egungun mi lẹ̀ mọ́ ẹran-ara mi.
6 I am like a pelican of the wilderness; I have become like an owl in the ruins.
Èmi dàbí ẹyẹ igún ní ijù: èmi dàbí òwìwí ibi ahoro.
7 I lie awake like a solitary bird, alone on the housetop.
Èmi dìde; èmi dàbí ẹyẹ lórí ilé.
8 My enemies taunt me all day long; those who mock me use my name in curses.
Ní ọjọ́ gbogbo, àwọn ọ̀tá ológoṣẹ́ mi ń gàn mí; àwọn tí ń ṣe ìkanra sí mi ń fi orúkọ mi bú.
9 I eat ashes like bread and mix my drink with tears.
Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi sì da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omijé.
10 Because of your raging anger, you have lifted me up to throw me down.
Nítorí ìbínú ríru rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.
11 My days are like a shadow that fades, and I have withered like grass.
Ọjọ́ mi dàbí òjìji àṣálẹ́ èmi sì rọ bí koríko.
12 But you, Yahweh, live forever, and your fame is for all generations.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, ni yóò dúró láéláé; ìrántí rẹ láti ìran dé ìran.
13 You will rise up and have mercy on Zion. Now is the time to have mercy upon her; the appointed time has come.
Ìwọ ó dìde ìwọ ó sì ṣàánú fún Sioni, nítorí ìgbà àti ṣe ojúrere sí i; àkókò náà ti dé.
14 For your servants hold her stones dear and feel compassion for the dust of her ruins.
Nítorí tí àwọn òkúta jẹ́ inú dídùn sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ; wọ́n sì káàánú erùpẹ̀ rẹ.
15 The nations will respect your name, Yahweh, and all the kings of the earth will honor your glory.
Àwọn kèfèrí yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, gbogbo ọba ayé yóò máa bẹ̀rù ògo rẹ.
16 Yahweh will rebuild Zion and will appear in his glory.
Torí tí Olúwa yóò gbé Sioni ró, yóò farahàn nínú ògo rẹ̀.
17 At that time, he will respond to the prayer of the destitute; he will not reject their prayer.
Yóò dáhùn àdúrà àwọn aláìní; kì yóò sì gan ẹ̀bẹ̀ wọn.
18 This will be written for future generations, and a people not yet born will praise Yahweh.
Jẹ́ kí a kọ èyí fún ìran tí ń bọ̀, àwọn ènìyàn tí a kò tí ì dá yóò yin Olúwa:
19 For he has looked down from the holy heights; from heaven Yahweh has viewed the earth,
“Olúwa wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀run wá ni ó bojú wo ayé,
20 to hear the groaning of the prisoners, to release those who were condemned to death.
láti gbọ́ ìrora ará túbú, láti tú àwọn tí a yàn sí ikú sílẹ̀.”
21 Then men will proclaim the name of Yahweh in Zion and his praise in Jerusalem
Kí a lè sọ orúkọ Olúwa ní Sioni àti ìyìn rẹ̀ ní Jerusalẹmu.
22 when the peoples and kingdoms gather together to serve Yahweh.
Ní ìgbà tí a kó àwọn ènìyàn àti ìjọba pọ̀ láti máa sìn Olúwa.
23 He has taken away my strength in the middle of life. He has shortened my days.
Ní ipa ọ̀nà mi, ó rẹ agbára mi sílẹ̀, ó gé ọjọ́ mi kúrú.
24 I said, “My God, do not take me away in the middle of life; you are here throughout all generations.
Èmi sì wí pé: “Ọlọ́run mi, má ṣe mú mi kúrò ní agbede-méjì ọjọ́ mi; ọdún rẹ̀ ń lọ láti ìran dé ìran.
25 In ancient times you set the earth in place; the heavens are the work of your hands.
Ní ìbẹ̀rẹ̀ ní ìwọ fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
26 They will perish, but you will remain; they will all grow old like a garment; like clothing, you will remove them, and they will disappear.
Wọn yóò ṣègbé, wọn yóò parun, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà; gbogbo wọn ni yóò gbó bí aṣọ. Bí ẹ̀wù ni ìwọ yóò pààrọ̀ wọn wọn yóò sì di àpatì.
27 But you are the same, and your years will have no end.
Ṣùgbọ́n ìwọ wà digbí síbẹ̀, ọdún rẹ kò sì ní òpin.
28 The children of your servants will live on, and their descendants will live in your presence.”
Àwọn ọmọ ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò dúró ní iwájú rẹ pẹ́; a ó sì fi ẹsẹ̀ irú-ọmọ wọn sọlẹ̀ ní iwájú rẹ.”

< Psalms 102 >