< Lamentations 3 >

1 I am a man who has seen misery under the rod of Yahweh's fury.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 He drove me away and caused me to walk in darkness rather than light.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Surely he turned his hand against me again and again, the whole day long.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 He made my flesh and my skin waste away; he broke my bones.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 He built up siege works against me, and surrounded me with bitterness and hardship.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 He made me live in dark places, like those who died long ago.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 He built a wall around me and I cannot escape. He made my chains heavy
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 and though I call out and cry for help, he shut out my prayer.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 He blocked my path with a wall of hewn stone; he made my paths crooked.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 He is like a bear waiting to ambush me, a lion in hiding;
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 he turned aside my paths, he has made me desolate.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 He bent his bow and set me as a target for his arrow.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 He pierced my kidneys with the arrows of his quiver.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 I became a laughingstock to all my people, the object of their taunting all day long.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 He filled me with bitterness and forced me to drink wormwood.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 He has made my teeth grind with gravel, and he made me cower in the ashes.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 My soul is deprived of peace; I have forgotten what happiness is.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 So I say, “My endurance has perished and so has my hope in Yahweh.”
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Remember my affliction and my wanderings, the wormwood and bitterness.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 I continually remember it and I am bowed down within me.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 But I call this to mind and therefore I have hope:
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 The steadfast love of Yahweh never ceases and his compassions never end,
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 they are new every morning; your faithfulness is great.
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 “Yahweh is my inheritance,” I said, therefore I will hope in him.
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Yahweh is good to those who wait for him, to the one who seeks him.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 It is good to wait silently for the salvation of Yahweh.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 It is good for a man that he bear the yoke in his youth.
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Let him sit alone in silence, when it is laid upon him.
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Let him put his mouth in the dust—there may yet be hope.
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Let him offer his cheek to the one who strikes him, and let him be filled to the full with reproach.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 For the Lord will not reject us forever,
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 but though he causes grief, he will have compassion according to the abundance of his steadfast love.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 For he does not afflict from his heart or torment the children of mankind.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 To crush underfoot all the prisoners of the earth,
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 to deny a man justice in the presence of the Most High,
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 to deny justice to a person—the Lord would not approve such things!
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Who has spoken and it came to pass, unless the Lord decreed it?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Is it not from the mouth of the Most High that both calamities and the good come?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 How can any person alive complain? How can a person complain about the punishment for his sins?
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Let us examine our ways and test them, and let us return to Yahweh.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Let us lift up our hearts and our hands to God in the heavens:
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 “We have transgressed and rebelled, and you have not forgiven.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 You have covered yourself with anger and pursued us, you have killed and you have not spared.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 You have covered yourself with a cloud so that no prayer can pass through.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 You have made us like filthy scum and refuse among the nations.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 All our enemies curse us,
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 panic and pitfall have come upon us, ruin and destruction.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 My eyes flow with streams of tears because my people are destroyed.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 My eyes will shed tears without ceasing, without relief,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 until Yahweh from heaven looks down and sees.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 My eyes cause me grief because of all the daughters of my city.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 I have been hunted like a bird by those who were my enemies; they hunted me without a reason.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 They cast me into a pit and they threw a stone on me,
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 and they caused waters to overflow, covering my head. I said, 'I have been cut off!'
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 I called on your name, Yahweh, from the depths of the pit.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 You heard my voice when I said, 'Do not close your ear to my cry for help.'
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 You came near on the day I called on you; you said, 'Do not fear.'
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Lord, you defended my case, you saved my life!
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 Yahweh, you have seen the wrong they have done to me; judge my case.
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 You have seen their insults, all their plots against me—
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 You have heard their scorn, Yahweh, and all their plans regarding me.
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 The lips and the accusations of my enemies come against me all the day.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Look at how they sit and then rise up; they mock me with their songs.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Pay back to them, Yahweh, according to what they have done.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 You will let their hearts be shameless! May your condemnation be upon them!
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 You pursue them in anger and destroy them from under the heavens, Yahweh!”
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

< Lamentations 3 >