< Jeremiah 28 >
1 It happened in that year, in the beginning of the reign of Zedekiah king of Judah, in the fourth year and the fifth month, Hananiah son of Azzur the prophet, who was from Gibeon, spoke to me in Yahweh's house in front of the priests and all the people. He said,
Ní oṣù karùn-ún ní ọdún kan náà, ọdún kẹrin ní ìbẹ̀rẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọba Juda, wòlíì Hananiah ọmọ Assuri, tí ó wá láti Gibeoni, sọ fún mi ní ilé Olúwa tí ó wà ní iwájú àwọn àlùfáà àti gbogbo ènìyàn:
2 “Yahweh of hosts, God of Israel, says this: I have broken the yoke imposed by the king of Babylon.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi yóò mú àjàgà ọba Babeli rọrùn.
3 Within two years I will bring back to this place all the objects belonging to Yahweh's house that Nebuchadnezzar king of Babylon took from this place and transported to Babylon.
Láàrín ọdún méjì, Èmi yóò mú gbogbo ohun èlò tí ọba Nebukadnessari; ọba Babeli kó kúrò ní ilé Olúwa tí ó sì kó lọ sí Babeli padà wá.
4 Then I will bring back to this place Jehoiachin son of Jehoiakim, king of Judah, and all the captives of Judah who were sent to Babylon—this is Yahweh's declaration—for I will break the yoke of the king of Babylon.”
Èmi á tún mú ààyè Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda padà, àti gbogbo àwọn tí ń ṣe àtìpó láti Juda ní Babeli,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘àjàgà yín láti ọwọ́ ọba Babeli yóò rọrùn.’”
5 So Jeremiah the prophet spoke to Hananiah the prophet in front of the priests and to all the people who stood in Yahweh's house.
Wòlíì Jeremiah wí fún wòlíì Hananiah ní iwájú ọmọ àlùfáà àti àwọn ènìyàn tí wọ́n dúró ní ilé Olúwa.
6 Jeremiah the prophet said, “May Yahweh do this! May Yahweh confirm the words that you prophesied and bring back to this place the objects belonging to Yahweh's house, and all the captives from Babylon.
Jeremiah wòlíì wí pé, “Àmín! Kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀! Kí Olúwa kí ó mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ìwọ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ṣẹ, láti mú ohun èlò ilé Olúwa àti gbogbo àwọn ìgbèkùn láti ilẹ̀ Babeli padà wá sí ibí yìí.
7 However, listen to the word that I am proclaiming in your hearing and in the hearing of all the people.
Nísinsin yìí, ìwọ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí tí mo sọ sí etí rẹ àti sí etí gbogbo ènìyàn.
8 The prophets who existed before me and you from long ago also prophesied about many nations and against great kingdoms, about war, famine, and plague.
Ní ìbẹ̀rẹ̀ àwọn wòlíì tí ó ṣáájú rẹ àti èmi ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ogun, ibi àti àjàkálẹ̀ sí ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè.
9 So the prophet who prophesies that there will be peace—if his word comes true, then it will be known that he is indeed a prophet sent out by Yahweh.”
Ṣùgbọ́n, àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ àlàáfíà ni a mọ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì olóòtítọ́ tí Olúwa rán, tí àsọtẹ́lẹ̀ rẹ bá wá sí ìmúṣẹ.”
10 But Hananiah the prophet took the yoke from the neck of Jeremiah the prophet and broke it.
Wòlíì Hananiah gbé àjàgà ọrùn wòlíì Jeremiah kúrò, ó sì fọ́ ọ.
11 Then Hananiah spoke in front of all the people and said, “Yahweh says this: Just like this, within two years I will break from off the neck of every nation the yoke imposed by Nebuchadnezzar king of Babylon.” Then Jeremiah the prophet went on his way.
Hananiah sọ níwájú gbogbo ènìyàn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Bákan náà ni Èmi yóò fọ́ àjàgà ọrùn Nebukadnessari, ọba Babeli láàrín ọdún méjì.’” Wòlíì Jeremiah sì bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ.
12 After Hananiah the prophet had broken the yoke from the neck of Jeremiah the prophet, the word of Yahweh came to Jeremiah, saying,
Láìpẹ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì wá lẹ́yìn ìgbà tí wòlíì Hananiah ti gbé àjàgà kúrò ní ọrùn wòlíì Jeremiah wí pé:
13 “Go and speak to Hananiah and say, 'Yahweh says this: You broke a yoke of wood, but I will make instead a yoke of iron.'
“Lọ sọ fún Hananiah, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ìwọ ti wó àjàgà onígi, ṣùgbọ́n ní ààyè wọn, wà á bá àjàgà onírin.
14 For Yahweh of hosts, God of Israel, says this: I have placed a yoke of iron on the neck of all of these nations to serve Nebuchadnezzar king of Babylon, and they will serve him. I have also given him the wild beasts in the fields to rule over.”
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi yóò fi àjàgà onírin sí ọrùn gbogbo orílẹ̀-èdè láti lè máa sin Nebukadnessari ọba Babeli, àti pé gbogbo yín ni ẹ̀ ó máa sìn ín. Èmi yóò tún fún un ní àṣẹ lórí àwọn ẹranko búburú.’”
15 Next Jeremiah the prophet said to Hananiah the prophet, “Listen Hananiah! Yahweh has not sent you, but you yourself have caused this people to believe in lies.
Wòlíì Jeremiah sọ fún wòlíì Hananiah pé, “Gbọ́ ọ, Hananiah! Olúwa kò rán ọ, síbẹ̀, ìwọ jẹ́ kí orílẹ̀-èdè yìí gba irọ́ gbọ́.
16 So Yahweh says this: Look, I am about to send you out from the earth. You will die this year, since you proclaimed rebellion against Yahweh.”
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Mo ṣetán láti mú ọ kúrò nínú ayé, ní ọdún yìí ni ìwọ yóò kú nítorí o ti wàásù ọ̀tẹ̀ sí Olúwa.’”
17 In the seventh month of that same year, Hananiah the prophet died.
Ní oṣù keje ọdún yìí ni Hananiah wòlíì kú.