< Isaiah 39 >

1 At that time Marduk-Baladan son of Baladan, king of Babylon, sent letters and a gift to Hezekiah; for he had heard that Hezekiah had been sick and had recovered.
Ní àkókò náà ni Merodaki-Baladani ọmọ Baladani ọba Babeli fi ìwé àti ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí Hesekiah, nítorí ó gbọ́ pé ó ṣàìsàn ó sì gbádùn.
2 Hezekiah was pleased by these things; he showed the messengers his storehouse of valuable things—the silver, the gold, the spices and precious oil, the storehouse of his weapons, and all that was found in his storehouses. There was nothing in his house, nor in all his kingdom, that Hezekiah did not show them.
Hesekiah gba àwọn ikọ̀ yìí tayọ̀tayọ̀, ó sì fi àwọn nǹkan tí ó wà nínú yàrá ìkẹ́rù sí mọ́ hàn wọ́n—fàdákà, wúrà, ohun olóòórùn dídùn, òróró dídára, gbogbo nǹkan ogun rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìṣúra rẹ̀ kò sí ohunkóhun tí ó wà nínú ààfin rẹ̀ tàbí ní ìjọba rẹ̀ tí Hesekiah kò fihàn wọ́n.
3 Then Isaiah the prophet came to King Hezekiah and asked him, “What did these men say to you? Where did they come from?” Hezekiah said, “They came to me from the distant country of Babylon.”
Lẹ́yìn náà wòlíì Isaiah lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah ọba ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí, níbo ni wọ́n sì ti wá?” “Láti ilẹ̀ jíjìnnà,” ni èsì Hesekiah. “Wọ́n wá sọ́dọ̀ mi láti Babeli.”
4 Isaiah asked, “What have they seen in your house?” Hezekiah answered, “They have seen everything in my house. There is nothing among my valuable things that I have not shown them.”
Wòlíì náà sì béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí nínú ààfin rẹ?” Hesekiah si dáhùn pe, “Wọ́n rí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin mi. Kò sí ohun kankan nínú ìṣúra mi tí èmi kò fihàn wọ́n.”
5 Then Isaiah said to Hezekiah, “Listen to the word of Yahweh of hosts:
Lẹ́yìn náà ni Isaiah sọ fún Hesekiah pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
6 'Look, the days are about to come when everything in your palace, the things that your ancestors stored away until this present day, will be carried to Babylon. Nothing will be left, says Yahweh.
Àsìkò ń bọ̀ nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin rẹ, àti ohun gbogbo tí àwọn baba rẹ ti kójọ títí di ọjọ́ òní yóò di kíkó lọ sí Babeli. Ohun kankan kò ní ṣẹ́kù ni Olúwa wí.
7 The sons born from you, whom you yourself have fathered—they will take them away, and they will become eunuchs in the palace of the king of Babylon.'”
Àti díẹ̀ nínú àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ, àwọn ẹ̀jẹ̀ àti ẹran-ara rẹ tí a ó bí fún ọ ni a ó kó lọ, wọn yóò sì di ìwẹ̀fà nínú ààfin ọba Babeli.”
8 Then Hezekiah said to Isaiah, “The word of Yahweh that you have spoken is good.” For he thought, “There will be peace and stability in my days.”
Hesekiah wí fún Isaiah pé, “Rere ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ sọ.” Nítorí ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Àlàáfíà àti ààbò yóò wà ní ìgbà ayé tèmi.”

< Isaiah 39 >