< Acts 14 >

1 It came about in Iconium that Paul and Barnabas entered together into the synagogue of the Jews and spoke in such a way that a great multitude both of Jews and of Greeks believed.
Ó sí ṣe, ni Ikoniomu, Paulu àti Barnaba jùmọ̀ wọ inú Sinagọgu àwọn Júù lọ, wọ́n sì sọ̀rọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Júù àti àwọn Helleni gbàgbọ́.
2 But the Jews who were disobedient stirred up the minds of the Gentiles and made them bitter against the brothers.
Ṣùgbọ́n àwọn aláìgbàgbọ́ Júù rú ọkàn àwọn aláìkọlà sókè, wọ́n sì mú wọn ni ọkàn ìkorò sí àwọn arákùnrin náà.
3 So they stayed there for a long time, speaking boldly with the Lord's power, while he gave evidence about the message of his grace. He did this by granting signs and wonders to be done by the hands of Paul and Barnabas.
Nítorí náà Paulu àti Barnaba gbé ibẹ̀ pẹ́, wọ́n ń fi ìgboyà sọ̀rọ̀ nínú Olúwa, ẹni tí ó jẹ́rìí sí ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, ó sì mu kí iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu máa ti ọwọ́ wọn ṣe.
4 But the majority of the city was divided: some people sided with the Jews, and some with the apostles.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ìlú náà pín sí méjì: apá kan dàpọ̀ mọ́ àwọn Júù, apá kan pẹ̀lú àwọn aposteli.
5 When both Gentiles and Jews attempted to persuade their leaders to mistreat and stone Paul and Barnabas,
Bí àwọn aláìkọlà, àti àwọn Júù pẹ̀lú àwọn olórí wọn ti fẹ́ kọlù wọ́n láti fi àbùkù kàn wọ́n, àti láti sọ wọ́n ní òkúta,
6 they became aware of it and fled to the cities of Lycaonia, Lystra and Derbe, and the surrounding region,
wọ́n gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì sálọ sí Lysra, àti Dabe, àwọn ìlú Likaonia àti sí agbègbè àyíká.
7 and there they were proclaiming the gospel.
Níbẹ̀ ni wọ́n sì ń wàásù ìyìnrere.
8 At Lystra a certain man sat, powerless in his feet, a cripple from his mother's womb, who never had walked.
Ọkùnrin kan sí jókòó ni Lysra, ẹni tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò mókun, arọ láti inú ìyá rẹ̀ wá, tí kò rìn rí.
9 This man heard Paul speaking. Paul fixed his eyes on him and saw that he had faith to be made well.
Ọkùnrin yìí gbọ́ bí Paulu ti ń sọ̀rọ̀: ẹni, nígbà tí ó tẹjúmọ́ ọn ti ó sì rí i pé, ó ni ìgbàgbọ́ fún ìmúláradá.
10 So he said to him in a loud voice, “Stand up on your feet.” Then the man jumped up and walked around.
Ó wí fún un ní ohùn rara pé, “Dìde dúró ṣánṣán lórí ẹsẹ̀ rẹ!” Ó sì ń fò sókè, ó sì ń rìn.
11 When the multitude saw what Paul had done, they raised their voice, saying in the dialect of Lycaonia, “The gods have come down to us in the form of men.”
Nígbà tí àwọn ènìyàn sì rí ohun tí Paulu ṣe, wọ́n gbé ohùn wọn sókè ni èdè Likaonia, wí pé, “Àwọn ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wá wá ni àwọ̀ ènìyàn!”
12 They called Barnabas “Zeus,” and Paul, “Hermes,” because he was the main speaker.
Wọn sì pe Barnaba ni Seusi àti Paulu ni Hermesi nítorí òun ni olórí ọ̀rọ̀ sísọ.
13 The priest of Zeus, whose temple was just outside the city, brought oxen and wreaths to the gates; he and the multitudes wanted to offer sacrifice.
Àlùfáà Seusi, ẹni ti ilé òrìṣà rẹ̀ wá lẹ́yìn odi ìlú wọn sì mú màlúù àti màrìwò wá sí ẹnu ibodè láti rú ẹbọ pẹ̀lú ìjọ ènìyàn sí àwọn aposteli wọ̀nyí.
14 But when the apostles, Barnabas and Paul, heard of it, they tore their clothing and quickly went out into the crowd, crying out
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn aposteli Barnaba àti Paulu gbọ́, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọn sí súré wọ inú àwùjọ, wọn ń ké rara pé:
15 and saying, “Men, why are you doing these things? We also are human beings with the same feelings as you. We bring you good news, that you should turn from these useless things to a living God, who made the heavens, the earth, and the sea and everything that is in them.
“Ará, èéṣe ti ẹ̀yin fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí? Ènìyàn bí ẹ̀yin náà ni àwa ń ṣe pẹ̀lú, ti a sì ń wàásù ìyìnrere fún yín, kí ẹ̀yin ba à lè yípadà kúrò nínú ohun asán wọ̀nyí sí Ọlọ́run alààyè, tí ó dá ọ̀run àti ayé, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn.
16 In the past ages, he allowed all the nations to walk in their own ways.
Ní ìran tí ó ti kọjá, ó faradà á fún gbogbo orílẹ̀-èdè, láti máa rìn ni ọ̀nà tiwọn.
17 But still, he did not leave himself without witness, in that he did good and gave you the rains from heaven and fruitful seasons, filling your hearts with food and gladness.”
Ṣùgbọ́n kò fi ara rẹ̀ sílẹ̀ ní àìní ẹ̀rí, ní ti pé ó ṣe rere, ó ń fún yín lójò láti ọ̀run wá, àti ni àkókò èso, ó ń fi oúnjẹ àti ayọ̀ kún ọkàn yín.”
18 Even with these words, Paul and Barnabas barely kept the multitudes from sacrificing to them.
Díẹ̀ ni ó kù kí wọn má le fi ọ̀rọ̀ wọ̀nyí dá àwọn ènìyàn dúró, kí wọn má ṣe rú ẹbọ bọ wọ́n.
19 But some Jews from Antioch and Iconium came and persuaded the crowds. They stoned Paul and dragged him out of the city, thinking that he was dead.
Àwọn Júù kan sì ti Antioku àti Ikoniomu wá, nígbà tí wọ́n yí àwọn ènìyàn lọ́kàn padà, wọ́n sì sọ Paulu ní òkúta, wọ́n wọ́ ọ kúrò sí ẹ̀yin odi ìlú náà, wọn ṣe bí ó ti kú.
20 Yet as the disciples were standing around him, he got up and entered the city. The next day, he went to Derbe with Barnabas.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn dúró ti i yíká, ó dìde ó sì padà wọ inú ìlú náà lọ. Ní ọjọ́ kejì ó bá Barnaba lọ sí Dabe.
21 After they had proclaimed the gospel in that city and made many disciples, they returned to Lystra, to Iconium, and to Antioch.
Nígbà tí wọ́n sì ti wàásù ìyìnrere fún ìlú náà, tí wọ́n sì ni ọmọ-ẹ̀yìn púpọ̀, wọn padà lọ sí Lysra, àti Ikoniomu, àti Antioku,
22 They kept strengthening the souls of the disciples and encouraging them to continue in the faith, saying, “We must enter into the kingdom of God through many sufferings.”
wọn sì ń mú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn lọ́kàn le, wọ́n sì ń gbà wọ́n níyànjú láti dúró nínú ìgbàgbọ́, àti pé nínú ìpọ́njú púpọ̀, ni àwa ó fi wọ ìjọba Ọlọ́run.
23 When they had appointed for them elders in every church, and had prayed with fasting, they entrusted them to the Lord, in whom they had believed.
Nígbà tí wọ́n sì ti yan àwọn alàgbà fún olúkúlùkù ìjọ, tí wọn sì ti fi àwẹ̀ gbàdúrà, wọn fi wọ́n lé Olúwa lọ́wọ, ẹni tí wọn gbàgbọ́.
24 Then they passed through Pisidia and came to Pamphylia.
Nígbà tí wọn sí la Pisidia já, wọ́n wá sí Pamfilia.
25 When they had spoken the word in Perga, they went down to Attalia.
Nígbà tí wọn sì ti sọ ọ̀rọ̀ náà ni Perga, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Atalia.
26 From there they sailed to Antioch, where they had been committed to the grace of God for the work which they had now completed.
Àti láti ibẹ̀ lọ wọ́n ṣíkọ̀ lọ sí Antioku ní ibi tí a gbé ti fi wọ́n lé oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run lọ́wọ́, fún iṣẹ́ tí wọ́n ṣe parí.
27 When they arrived in Antioch and gathered the church together, they reported all the things that God had done with them, and how he had opened a door of faith for the Gentiles.
Nígbà tí wọ́n sì dé, tí wọ́n sì pé ìjọ jọ, wọ́n ròhìn gbogbo ohun tí Ọlọ́run fi wọ́n ṣe, àti bí ó ti ṣí ìlẹ̀kùn ìgbàgbọ́ fún àwọn aláìkọlà.
28 They stayed for a long time with the disciples.
Níbẹ̀ ni wọ́n ń gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ni ọjọ́ púpọ̀.

< Acts 14 >