< 1 Samuel 29 >
1 Now the Philistines gathered together all their army at Aphek; the Israelites camped by the spring that is in Jezreel.
Àwọn Filistini sì kó gbogbo ogun wọn jọ sí Afeki: Israẹli sì dó ni ibi ìsun omi tí ó wà ní Jesreeli.
2 The princes of the Philistines passed on by hundreds and by thousands; David and his men passed on in the rear guard with Achish.
Àwọn ìjòyè Filistini sì kọjá ní ọ̀rọ̀ọ̀rún àti lẹgbẹẹgbẹ̀rún; Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pẹ̀lú Akiṣi sì kẹ́yìn.
3 Then the princes of the Philistines said, “What are these Hebrews doing here?” Achish said to the other princes of the Philistines, “Is not this David, the servant of Saul, the king of Israel, who has been with me these days, or rather these years, and I have found no fault with him since he came away to me to this day?”
Àwọn ìjòyè Filistini sì béèrè wí pé, “Kín ni àwọn Heberu ń ṣe níhìn-ín yìí?” Akiṣi sì wí fún àwọn ìjòyè Filistini pé “Dafidi kọ yìí, ìránṣẹ́ Saulu ọba Israẹli, tí ó wà lọ́dọ̀ mi láti ọjọ́ wọ̀nyí tàbí láti ọdún wọ̀nyí, èmi kò ì tì í rí àṣìṣe kan ni ọwọ́ rẹ̀ láti ọjọ́ tí ó ti dé ọ̀dọ̀ mi títí di òní yìí.”
4 But the princes of the Philistines were angry with him and said, “Send the man back, that he may return to the place you assigned him. He will not go down with us into battle, for he will turn against us during the fighting. For how else could he make himself acceptable to his master than by taking the heads of our own men?
Àwọn ìjòyè Filistini sì bínú sí i; àwọn ìjòyè Filistini sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí ọkùnrin yìí padà kí ó sì lọ sí ipò rẹ̀ tí ó fi fún un, kí ó má sì jẹ́ kí ó bá wa sọ̀kalẹ̀ lọ sí ogun, kí ó má ba à jásí ọ̀tá fún wa ni ogun, kín ni òun ó fi ba olúwa rẹ̀ làjà, orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọ́?
5 Is this not David of whom they sang one to another in dances, saying, 'Saul has slain his thousands, and David his ten thousands'?”
Ṣé èyí ni Dafidi tiwọn torí rẹ̀ gberin ara wọn nínú ijó wí pé, “‘Saulu pa ẹgbẹ̀rún rẹ̀, Dafidi si pa ẹgbẹgbàarùn-ún tirẹ̀.’”
6 Then Achish called David and said to him, “As Yahweh lives, you have been good, and your going out and your coming in with me in the army is good in my view; for I have found nothing wrong with you since the day of your coming to me to this very day. Nevertheless, the princes are not favorable to you.
Akiṣi sì pe Dafidi, ó sì wí fún un pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ìwọ jẹ́ olóòótọ́ àti ẹni ìwà rere lójú mi, ní àlọ rẹ àti ààbọ̀ rẹ pẹ̀lú mi ní ogun: nítorí pé èmi ko tí ì ri búburú kan lọ́wọ́ rẹ́ láti ọjọ́ ti ìwọ ti tọ̀ mí wá, títí o fi dì òní yìí ṣùgbọ́n lójú àwọn ìjòyè, ìwọ kò ṣe ẹni tí ó tọ́.
7 So now return and go in peace, so that you do not displease the princes of the Philistines.”
Ǹjẹ́ yípadà kí o sì máa lọ ní àlàáfíà, kí ìwọ má ṣe bà àwọn Filistini nínú jẹ́.”
8 David said to Achish, “But what have I done? What have you found in your servant as long as I have been before you to this day, that I may not go and fight against the enemies of my master the king?”
Dafidi sì wí fún Akiṣi pé, “Kín ni èmi ṣe? Kín ni ìwọ sì rí lọ́wọ́ ìránṣẹ́ rẹ láti ọjọ́ ti èmi ti ń gbé níwájú rẹ títí di òní yìí, tí èmi kì yóò fi lọ bá àwọn ọ̀tá ọba jà.”
9 Achish answered and said to David, “I know that you are as blameless in my sight as an angel of God; nevertheless, the princes of the Philistines have said, 'He must not go up with us to the battle.'
Akiṣi sì dáhùn, ó sì wí fún Dafidi pé, “Èmi mọ̀ pé ìwọ ṣe ẹni rere lójú mi, bi angẹli Ọlọ́run; ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Filistini wí pé, ‘Òun kì yóò bá wa lọ sí ogun.’
10 So now rise up early in the morning with the servants of your master who have come with you; as soon as you are up early in the morning and have light, go away.”
Ǹjẹ́, nísinsin yìí dìde ní òwúrọ̀ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ tí ó bá ọ wá, ki ẹ si dìde ní òwúrọ̀ nígbà tí ilẹ̀ bá mọ́ kí ẹ sì máa lọ.”
11 So David rose up early, he and his men, to leave in the morning, to return into the land of the Philistines. But the Philistines went up to Jezreel.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì dìde ní òwúrọ̀ láti padà lọ sí ilẹ̀ àwọn Filistini. Àwọn Filistini sì gòkè lọ sí Jesreeli.