< Psalms 99 >

1 Yahweh is the [supreme] king, so [all] the people-groups should tremble ([in his presence/in front of him])! He sits on his throne [in the temple] above the [statues of] winged creatures, [so] the earth should quake/shake!
Olúwa jẹ ọba; jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì Ó jókòó lórí ìtẹ́ kérúbù jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì.
2 Yahweh is a mighty [king] in Jerusalem; [but] he is [also] the supreme ruler of all people-groups.
Olúwa tóbi ní Sioni; Ó sì ga jù gbogbo orílẹ̀-èdè lọ.
3 [So] they should praise him because he is very great/powerful; and he is holy!
Kí wọ́n sì yin orúkọ rẹ̀ tí ó tóbi tí ó ni ẹ̀rù, Mímọ́ ni Òun.
4 He is a mighty king who (loves/is pleased with) what is just/right; he has acted justly and fairly [DOU] in Israel.
Ọba náà ní agbára, ó sì fẹ́ òdodo, ìwọ fi ìdí àìṣègbè múlẹ̀; ìwọ ṣe ohun tí ó tọ́ àti ohun tí ó yẹ nínú Jakọbu.
5 Praise Yahweh our God! Worship him [in front of the Sacred Chest in his temple] [MTY], where he rules people. He is holy!
Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa ẹ foríbalẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀; ó jẹ́ mímọ́.
6 Moses and Aaron were two of his priests; Samuel also was someone who prayed to him. Those [three] cried out to Yahweh [to help them], and he answered them.
Mose àti Aaroni wà nínú àwọn àlùfáà rẹ̀ Samuẹli wà nínú àwọn tí ó ń ké pe orúkọ rẹ̀ wọ́n ké pe Olúwa, ó sì dá wọn lóhùn.
7 He spoke to Moses and Aaron from the cloud [that was like a huge] pillar; they obeyed [all] the laws and commandments [DOU] that he gave to them.
Ó sọ̀rọ̀ sí wọn nínú ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀, wọ́n pa ẹ̀rí rẹ̀ mọ́ àti ìlànà tí ó fún wọn.
8 Yahweh, our God, you answered [your people] [when they cried out to you to help them]; you are a God who forgave them [for those sins that they had committed], even though you punished them for the things that they did that are wrong.
Olúwa Ọlọ́run wa, ó dá wọn lóhùn; ó jẹ́ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì àwọn ọmọ Israẹli ìwọ tí ó ń fi ìyà àìṣedéédéé wọn jẹ wọ́n.
9 Praise Yahweh, our God, and worship him [at the temple] on his sacred hill; [it is right to do that] because Yahweh, our God, is holy!
Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa kí a sìn ín ní òkè mímọ́ rẹ̀ nítorí Olúwa Ọlọ́run wa jẹ́ mímọ́.

< Psalms 99 >