< Psalms 9 >

1 Yahweh, I will praise you with all of my inner being. I will tell [others] about all the wonderful things that you have done.
Fún adarí orin. Ní ti ohun orin. “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi. Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.
2 I will sing to celebrate what you [MTY], who are much greater than all other gods, [have done].
Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ; èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.
3 When my enemies realize [that you are very powerful], they stumble, and then they are killed.
Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà; wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.
4 You sat on your throne to judge people, and you have judged fairly/justly concerning me.
Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú; ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.
5 You rebuked the [people of other] nations and you have gotten rid of the wicked people; you have erased their names forever.
Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run; Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.
6 Our enemies have disappeared; you destroyed their cities, and people do not even remember them any more.
Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá, ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu; àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.
7 But Yahweh rules forever. He judges [people while he sits] on his throne to judge people,
Olúwa jẹ ọba títí láé; ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.
8 and he will judge [all the people in] [SYN] the world justly; he will judge the people [of all nations] fairly [DOU].
Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo; yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.
9 Yahweh will be a refuge for those who are oppressed; [yes, he will be like] a shelter for them when they have trouble.
Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára, ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.
10 Those who know Yahweh [MTY] trust in him; he never abandons those who come to him ([for help/to worship him]).
Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ, nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.
11 Yahweh rules from Zion [Hill]; praise him while you sing to him. Tell [the people of all] the nations the [marvelous] things that he has done.
Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni; kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.
12 He does not forget [to punish] those who have murdered others; and he will not ignore people who are crying because they are suffering.
Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí; òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.
13 Yahweh, be merciful to me! Look at the ways that my enemies have injured me. Do not allow me to die [because of these injuries].
Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi! Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,
14 I want to live in order that I can praise you at the gates of Jerusalem [MTY] and to rejoice because you rescued me.
kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.
15 [It is as though] the [wicked people of many] nations have dug a pit for me to fall into [MET], but they have fallen into that same pit. [It is as if] they spread out a net to catch me [MET], but their feet have been caught in that same net.
Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́; ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.
16 Because of what you have done, people know that you decide matters [fairly/justly], but [you allow] wicked people to be trapped by the same evil things that they themselves do.
A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀; àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
17 Wicked people will all [die and] be buried in their graves, and [their spirits] will go to be with all those who have (forgotten about/rejected) you. (Sheol h7585)
Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run. (Sheol h7585)
18 But you will not forget those who are needy/poor; what they confidently expect will certainly happen.
Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé, ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.
19 Yahweh, arise and judge the [wicked] people of the nations; do not allow them to think that [because they are strong] they will never be punished.
Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí; jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.
20 Yahweh, teach them to be terrified about you. Cause them to know that they are merely human beings.
Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa; jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. (Sela)

< Psalms 9 >