< Psalms 87 >

1 The city that Yahweh established is on his sacred hill.
Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin. Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;
2 He loves that city, Jerusalem, more than he loves any other city in Israel.
Olúwa fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.
3 [You people in] [APO] the city that God (owns/lives in), people say wonderful things about your city.
Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀, ìlú Ọlọ́run,
4 [Some of those who know about God are the people of] Egypt and Babylonia, and also [the people of] Philistia and Tyre and Ethiopia; [some day they all] will say, “[Although I was not born in Jerusalem], [because I belong to Yahweh, it is as though] I was born there.”
“Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi: Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi, yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’”
5 And concerning Jerusalem, people will say [“It is as though] everyone was born there, and Almighty God will cause that city to remain strong/safe/secure.”
Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ, “Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀, àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀.”
6 Yahweh will write a list of [the names of] the people of various groups [who belong to him], and he will say that [he considers them] all to be citizens of Jerusalem.
Olúwa yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀: “Eléyìí ni a bí ní Sioni.”
7 They will all dance and sing, saying, “Jerusalem is the source of all our blessings.”
Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu ohun èlò orin yóò wí pé, “Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ.”

< Psalms 87 >