< Psalms 86 >
1 Yahweh, listen [IDM] to what I say and answer me, because I am weak and needy.
Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
2 Prevent me from dying now, because I (am loyal to/continue to believe in) you; save/rescue me, because I serve you and I trust in you, my God.
Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
3 Lord, be kind to me, because I cry out to you all during the day.
Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
4 Lord, cause me to be glad, because I (pray to/worship) [IDM] you.
Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
5 Lord, you are good [to us], and you forgive [us]; you faithfully love very much all those who (pray/call out) to you.
Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
6 Lord, listen to my prayer; hear me when I cry out to you to help me.
Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
7 When I have troubles, I call out to you, because you answer me.
Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
8 Lord, among all the gods [whom the heathen nations worship], there is no one like you; not one of them has done [the great things] that you have done.
Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
9 Lord, [some day, people from] all the nations that you have established will come and bow down in front of you and they will praise you [MTY].
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
10 You are great, and you do wonderful/marvelous things; only you are God.
Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
11 Yahweh, teach me what you want me to do in order that I may conduct my life according to what you say, which is true. Cause/Teach me to revere you.
Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
12 Lord, my God, I [will] thank you with all my inner being, and I will praise you forever.
Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
13 You faithfully love me very much; you have prevented me from [dying and going to] the place where dead people are. (Sheol )
Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol )
14 But God, proud men are [trying to] attack me; a gang/group of cruel men are wanting to kill me; they are men who do not have any (respect for/interest in) you.
Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
15 But Lord, you always are mercifully and kind; you do not become angry quickly, you faithfully love us very much and always do for us what you have promised to do.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
16 Look down toward me and be merciful to me; cause me to be strong and save/rescue me who serves you [faithfully] like my mother did.
Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
17 Yahweh, do something to show me that you are being good to me in order that those who hate me will see that you have encouraged me and helped me, and as a result they will be ashamed.
Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.