< Psalms 27 >
1 Yahweh is the one who gives light [to my soul/spirit] and the one who saves me, so I do not [RHQ] need to be afraid of anyone. Yahweh is the one to whom I go for refuge, so I will never be afraid.
Ti Dafidi. Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi; ta ni èmi yóò bẹ̀rù? Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi, ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?
2 When those who do evil come near me to attack me, they stumble and fall down.
Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi láti jẹ ẹran-ara mi, àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi, wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
3 [Even] if an army surrounds me, I [SYN] will not be afraid. [Even] if they attack me, I will trust [in God].
Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi, ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù; bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi, nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.
4 There is one thing that I have requested from Yahweh; this is the one thing that I desire: That I may worship in Yahweh’s house/temple every day of my life, and see that Yahweh is wonderful and inquire [what he wants me to do].
Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òhun ni èmi yóò máa wá kiri: kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwa ní ọjọ́ ayé mi gbogbo, kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà Olúwa, kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.
5 He will protect me when I have troubles; he will keep me safe in his Sacred Tent. He will set me safely (on a high rock/in a secure place).
Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀; níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́; yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.
6 Then I will triumph over [IDM] my enemies. I will shout joyfully as I offer sacrifices in his Sacred Tent, and I will praise Yahweh as I sing.
Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká; èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀; èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.
7 Yahweh, listen to me while I pray. Be kind to me and answer my prayer.
Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, Olúwa, ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn,
8 I sensed that I heard you say, “Come and worship me [IDM],” so, Yahweh, I will worship you.
Ọkàn mi wí pé, “Wá ojú u rẹ̀!” Ojú rẹ, Olúwa, ni ti èmí ń wá.
9 I am your servant; Do not be angry with me and turn away from me. You have always helped me. You are the one who has saved me, so do not abandon me [now].
Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi, má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì; ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi, Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí, háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.
10 [Even] if my father and mother desert me, you will take care of [IDM] me.
Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa yóò tẹ́wọ́ gbà mí.
11 Yahweh, teach me to do what you want me to do, and lead me on a safe path because I have many enemies.
Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú nítorí àwọn ọ̀tá mi.
12 Do not allow my enemies to do to me what they want; they say many false things about me and [threaten to do] violent things to me.
Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́, nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi, wọ́n sì mí ìmí ìkà.
13 But I know that because I trust in you you will be good to me as long as I live.
Èmi ní ìgbàgbọ́ pé, èmi yóò rí ìre Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
14 So trust in Yahweh, [all of you]! Be strong and courageous, and wait expectantly for him [to help you]!
Dúró de Olúwa; kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le àní dúró de Olúwa.