< Psalms 119 >
1 (Yahweh is pleased with/Happy are) those about whom no one can say truthfully that they have done things that are wrong, those who always obey the laws of Yahweh.
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
2 Yahweh is pleased with those who (obey his requirements/do what he has instructed them to do), those who request him with their entire inner beings to help them [to do that].
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
3 They do not do things that are wrong; they behave like Yahweh wants them to.
Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
4 Yahweh, you have given [us] (your principles of behavior/all the things that you have declared that we should do), [and you told us] to obey them carefully.
Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
5 I desire that I will faithfully/always obey all (your statutes/that you have said that [we] should do).
Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
6 If I continually (heed/pay attention to) all (your commands/that you have commanded), I will not be disgraced/ashamed.
Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
7 When I learn [all of] (your regulations/the rules that you have given [to us)], I will praise you with a pure inner being [IDM].
Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
8 I will obey all (your statutes/that you have decreed that [we] should do); do not desert/abandon me!
Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
9 [I know] [RHQ] how a youth can (keep his life pure/avoid sinning); it is by obeying what you have told us to do.
Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
10 I try to serve you with my entire inner being; do not allow me to (wander away from obeying/disobey) (your commands/what you have commanded).
Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
11 I have (memorized/stored in my mind) [many of] (your words/what you have promised) in order that I will not sin against you.
Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
12 Yahweh, I praise you; teach me (your statutes/what you have declared).
Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
13 I [MTY] tell others (the regulations/the rules that you have given [to us)].
Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
14 I like to obey (your requirements/what you have instructed [us to do)]; I enjoy that more than being very rich.
Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
15 I will (study/think about) (your principles of behavior/what you have declared that we should do), and I will pay attention to what you have showed [me].
Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
16 I will be happy [to obey] (your statutes/what you have decreed that [we] should do), and I will not forget your words.
Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
17 Do good things for me, who serve you, in order that I may continue to live and obey (your words/what you have told us to do) during all my life.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
18 Open my mind in order that I may know the wonderful things that [are written] in your laws.
La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
19 I am living [here] on the earth for only a short time; (do not prevent me from [understanding]/help me to understand) [LIT] (your commands/what you have commanded).
Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
20 In my inner being I strongly desire to know (your regulations/the rules that you have given to us) all the time.
Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
21 You rebuke those who are proud; cursed are those who disobey (your commands/what you have commanded).
Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
22 Do not allow them to continue to insult and scorn me; [I request this] because I have obeyed what you have instructed us to do.
Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
23 Rulers gather together and plan ways to harm me, but I will (meditate on/study) (your statutes/what you have decreed).
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
24 I am delighted with (your requirements/what you have instructed [us to do)]; [it is as though] they are my advisors.
Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
25 [I think that] I will soon die [IDM]; revive/heal me, as you have told me that you would.
Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
26 When I told you about my behavior, you answered me; teach me (your statutes/what you have decreed that we should do).
Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
27 Help me to understand (your principles of behavior/what you have declared that we should do), and [then] I will (meditate on/think about) the wonderful things that you [have done].
Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
28 I am very sad/sorrowful [IDM], with the result that I have no strength; enable me to be strong [again], like you promised me that you would do.
Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
29 Prevent me from doing what is wrong, and be kind to me by teaching me your laws.
Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
30 I have decided that I will faithfully/always [obey you]; I have (paid attention to/heeded) (your regulations/the rules that you have given to us).
Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
31 Yahweh, I try to carefully hold fast to what you have instructed [us to do]; do not [abandon me, with the result that] I would become disgraced.
Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
32 I will eagerly obey [IDM] (your commands/what you have commanded), because you have enabled me to understand more [what you want me to do].
Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
33 Yahweh, teach me the meaning of (your statutes/the things that you have decreed that we should do), and [then] I will obey them, every one of them.
Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
34 Help me to understand your laws in order that I may obey them with all my inner being.
Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
35 I am happy with (your commands/what you have commanded), so (lead me along the paths/enable me to walk on the road) that you [have chosen for me].
Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
36 Cause me to want to obey your rules and not to want to become rich.
Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
37 Do not allow me to look at things that are worthless, and allow me to continue to live, like you promised that you would do.
Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
38 [Because] I serve you, do what you promised to do for me, which is what you also promise to do for [all] those who revere you.
Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
39 [People] insult me; protect me from those insults, [because] I hate them. The (regulations/rules that you have given [to us]) are [very] good!
Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
40 I very much desire [to obey] (your principles of behavior/what you have declared that we should do); because you are righteous, allow me to continue to live (OR, be good to me).
Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
41 Yahweh, show me that you faithfully love me, and rescue/save me, like you have said/promised that you would.
Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
42 After you do that, I will be able to reply to those who insult me, because I trust in (your word/what you have promised that you would do).
Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
43 Always enable me to [LIT] speak your truth, because I have confidence in (your regulations/the rules that you have given us).
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
44 I will always obey your laws, forever.
Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
45 I will be free [from (affliction/my enemies’ attacks)], because I have tried [to obey] (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
46 I will tell to kings (your requirements/what you have instructed us to do); and [because I did not abandon you], those kings will not cause me to be ashamed.
Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
47 I am delighted to [obey] (your commands/what you have commanded), and I love them.
nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
48 I respect/revere [IDM] (your commands/what you have commanded), and I love them, and I will (meditate on/think about) (your statutes/what you have decreed that [we] should do).
Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
49 Do not forget what you said/promised to do for me, who serve you, [because] what you have said has caused me to confidently expect [good things from you].
Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
50 When I have been suffering, you comforted me; you did what you promised me, and that [PRS] revived me.
Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
51 Proud people are always making fun of me, but I do not (turn away from/stop) [obeying] your laws.
Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
52 Yahweh, when I think about (your regulations/the rules) that you gave to us long ago, I am comforted/encouraged.
Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
53 When [I see that] wicked people have disregarded your laws, I become very angry.
Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
54 While I have been living here for a short time on the earth, I have written songs about (your statutes/what you have decreed that we should do).
Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
55 Yahweh, during the night I think about you [MTY], and [so] I obey your laws.
Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
56 What I have always done is to obey (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
57 Yahweh, you are the one whom I have chosen, and I promise to (obey your words/do what you have told us to do).
Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
58 With all my inner being I plead with you to be good to me; be kind to me, like you promised/said that you would do.
Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
59 I have thought about my behavior, and I [have decided to] return to [obeying] (your requirements/what you have instructed us to do).
Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
60 I hurry to obey (your commands/what you have commanded); I do not delay [at all].
Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
61 Wicked people have [tried to] seize me, [like a hunter tries to catch an animal] with a net [MET], but I do not forget your laws.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
62 In the middle of the night I wake up, and I praise you for (your commands/the rules that you have given us to do); they are fair/just.
Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
63 I am a friend of all those who revere you, those who obey (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
64 Yahweh, you faithfully/always love [people] all over the earth; teach me (your statutes/what you have decreed that [we] should do).
Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
65 Yahweh, you have done good things for me, like you promised/said that you would do.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
66 Teach me to think carefully before I decide what to do, and [teach me other things that I need to] know, because I believe [that it is good for us to obey] (your commands/what you have commanded).
Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
67 Before you afflicted/punished me, I did things that were wrong, but now I obey (your words/what you have told us to do).
Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
68 You are [very] good, and what you do is good; teach me (your statutes/what you have decreed that [we] should do).
Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
69 Proud people have told many lies about me, but [the truth is that] with all my inner being I obey (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
70 Those proud people (are stupid/do not understand your laws) [IDM], but [as for me], I am delighted with your laws.
Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
71 It was good for me that [you] afflicted/punished me, because the result was that I learned (your statutes/what you have decreed that [we] should do).
Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
72 The laws that you [MTY] gave/told [to us] are [worth] more to me than gold, more than thousands of pieces of gold and silver.
Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
73 You created me and formed my body (OR, kept me safe); help me to be wise in order that I may learn (your commands/what you have commanded).
Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
74 Those who have an awesome respect for you will see [what you have done for] me, and they will rejoice, because [they will see that] I have trusted in (your words/what you told us).
Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
75 Yahweh, I know that (your regulations/the rules that you have given to us) are right/fair and that you have afflicted/punished me because you faithfully do [what you have promised].
Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
76 Cause me to be comforted/encouraged by [knowing that] you faithfully love [me], like you said to me that you would do.
Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
77 Be merciful to me in order that I may [continue to] live, because I am delighted with your laws.
Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
78 Cause the proud people who falsely accuse me to be ashamed, [but] as for me, I will [continue] (meditating on/thinking about) (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
79 Cause those who revere you to come [back] to me in order that they may (OR, specifically, those who) know (your requirements/what you have instructed [us to do]).
Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
80 Enable me to perfectly [obey] (your statutes/what you have decreed that we should do) in order that I may not be ashamed [because of not doing that].
Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
81 I am very tired/exhausted while I wait for you to save [me from my enemies]; [but] I confidently expect that you will tell [me what you will do].
Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
82 My eyes are tired from waiting a long time for you to do what you promised/said that you would do, and I ask, “When will you help/encourage me?”
Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
83 I have become [as useless as] [MET] a wineskin that is [shriveled from hanging a long time] in the smoke [inside a house], but I have not forgotten (your statutes/what you have decreed that [we] should do).
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
84 How long must I wait? When will you punish those who (persecute/cause trouble for) me?
Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
85 [It is as though] proud people have dug deep pits for me [to fall into], people who do not obey your laws.
Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
86 All (your commands are/what you have commanded is) trustworthy; [but] people are (persecuting/causing trouble for) me by telling lies [about me, so please] help me!
Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
87 Those people have almost killed me, but I have not stopped [obeying] (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
88 Because you faithfully love [me], allow me [to continue] to live in order that I may [continue to] obey (your rules/what you have instructed [us to do]).
Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
89 Yahweh, your words will last forever; they will last as long as heaven lasts.
Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
90 You will faithfully [continue doing] ([for people who are not yet born/in every generation]) what you have (promised/said that you would do); you have put the earth in its place, and it remains firmly [there].
Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
91 To this day, [all things on the earth] remain because you decided that they should remain; everything [on the earth] serves you.
Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
92 If I had not been delighted [in obeying] your laws, I would have died because of what I was suffering.
Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
93 I will never forget (your principles of behavior/what you have declared that we should do), because as a result of [my obeying them] you have enabled me to [continue to] live.
Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
94 I belong to you; save/rescue me [from my enemies], because I have tried to obey (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
95 Wicked [men] are waiting to kill me, but I [will] think about what you have instructed [us to do].
Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
96 I have learned that there is a limit/end for everything, but what you command (has no limits/never ends).
Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
97 I love your laws very much. I (meditate on/think about) them all during the day.
Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
98 Because I know (your commands/what you have commanded), and because I think about them all the time, I have become wiser than my enemies.
Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
99 I understand more than my teachers do, because I (meditate on/think about) (your requirements/what you have instructed us to do).
Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
100 I understand more than [many] old people do, because I obey (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
101 I have avoided all evil behavior in order that I may obey (your words/what you have told us to do).
Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
102 I have not (turned away from/quit) [obeying] (your regulations/the rules that you have given to us), because you have taught me [while I have studied them].
Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
103 [When I read] your words, they are like [MET] sweet things that I taste/eat, [yes], they are even sweeter than honey.
Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
104 Because [I have learned] (your principles of behavior/what you have declared that we should do), I am able to understand [many things]; therefore, I hate all evil things [that some people do].
Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
105 Your words are [like] [MET] a lamp to guide me; they are [like] a light [MET] to show me the path [that I should walk on].
Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
106 I have solemnly promised, and I am solemnly promising it again, that I will [always] obey your (regulations/rules that you have given to us), and they are [all] fair/just.
Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
107 Yahweh, I am suffering very much; cause me to be strong/healthy [again], as you have promised to do.
A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
108 Yahweh, when I thank you while I pray, it is [like] [MET] a sacrifice to you; [please] accept it, and teach me your (regulations/rules that you have given to us).
Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
109 [My enemies are] often trying to kill me [IDM], but I do not forget your laws.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
110 Wicked [people] have tried to seize me [like a hunter tries to catch an animal] with a trap [MET], but I have not disobeyed (your principles of behavior/what you declared that we should do).
Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
111 (Your requirements/What you have instructed us to do) are my possession forever; because of them [PRS], I am joyful.
Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
112 I (have decided/am determined) [IDM] to obey (your statutes/what you have decreed that [we] should do) until the day that I die [MTY].
Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
113 I hate people who are [only] partly committed to you, but I love your laws.
Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
114 You are [like] a place where I can hide [from my enemies], and you are [like] a shield [MET] [behind which I am protected from them], and I trust in your promises.
Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
115 You evil people, stay away from me in order than I may obey (my God’s commands/what my God has commanded)!
Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
116 Enable me to be strong, as you promised/said that you would do, in order that I may [continue to] live. I am confidently expecting [that you will restore me]; (do not disappoint me/do not allow me to be disappointed).
Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
117 Hold me up, in order that I will be safe and always (pay attention to/heed) (your statutes/what you have decreed that we should do).
Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
118 You reject all those who disobey (your statutes/what you have decreed that [we] should do); but what they deceitfully plan to do will be (useless/in vain).
Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
119 You get rid of all the wicked [people] on the earth like [SIM] [people throw away] trash; therefore I love what you have instructed us to do.
Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
120 I [SYN] tremble because I am afraid of you; I am afraid [because you punish those who do not obey] (your regulations/the rules that you have given to us).
Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
121 [But] I have done what is right and fair/just; [so] do not allow people to oppress/mistreat me.
Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
122 Promise me that you will do good things for me and do not allow proud [people] to oppress me.
Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
123 My eyes are tired from waiting a long time for you to rescue [me], for you to save [me] like you promised/said that you would.
Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
124 Do something for me to show that you faithfully love [me], and teach me (your statutes/what you have decreed that we should do).
Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
125 I am one who serves you; enable me to understand [what you want me to know] in order that I will know (your requirements/what you have instructed us to do).
Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
126 Yahweh, now is the time for you to [punish people] because they have disobeyed your laws.
Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
127 Truly, I love (your commands/what you have commanded) more than I love gold; I love them more than I love [very] pure gold.
Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
128 So I conduct my life by (your principles of behavior/what you have declared that we should do), and I hate all the evil things that [some people do].
nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
129 (Your requirements are/All the things that you have instructed us to do are) wonderful, so I obey them with all my inner being.
Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
130 When someone explains (your words/what you have said), [it is as though] they are lighting a light; what they say causes [even] people who have not learned your laws to be wise.
Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
131 I eagerly desire to know (your commands/what you have commanded), like [SIM] a [dog] that pants with its mouth open [wanting to be fed].
Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
132 Listen to me and act kindly to me, like you do to [all] those who love you [MTY].
Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
133 Guide me as you promised/said that you would do and help me not to fall/sin; do not allow evil [people] to control what I do.
Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
134 Rescue/Save me from those who oppress me in order that I may obey (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
135 Be kind to me and teach me (your statutes/what you have decreed that [we] should do).
Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
136 I cry very much because [many] people do not obey your laws.
Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
137 Yahweh, you are righteous and (your regulations/the rules that you have given to us) are just/fair.
Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
138 (Your requirements/All the things that you have instructed us to do) are true and are all very right and fair.
Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
139 I am (furious/very angry) because my enemies disregard (your words/what you have told us to do).
Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
140 (Your promises are/All the things that you have said that you will do are) dependable and I love them.
Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
141 I am not important and people despise me, but I do not forget (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
142 You are righteous and you will be righteous forever, and your laws will never be changed.
Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
143 I [constantly] have troubles/difficulties and I am worried, but (your commands cause/what you have commanded causes) me to be happy.
Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
144 (Your requirements are/All the things that you have instructed us to do are) always fair; help me to understand them in order that I may [continue to] live.
Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
145 Yahweh, with all my inner being I call out to you; answer me and I will obey (your statutes/what you have decreed that [we] should do).
Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
146 I call out to you; save/rescue me in order that I [can continue to] obey [all] (your requirements/the things that you have instructed us to do).
Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
147 [Each morning] I arise before dawn and call to you to help me; I confidently expect you to do what you have (promised/said that you will do).
Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
148 All during the night I am awake, and I (meditate on/think about) what you have (promised/said that you would do).
Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
149 Yahweh, because you faithfully love me, listen to me [while I pray], and keep me safe because of [my obeying] (your regulations/what you have told us to do).
Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
150 Those evil people who oppress/persecute me are coming closer to me; they do not pay any attention to your laws.
Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
151 But Yahweh, you are near to me, and [I know that] (your commands/what you command) will never be changed.
Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
152 Long ago I found out about (your requirements/all the things that you have instructed us to do), and [I know that] you intended them to last forever.
Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
153 Look at me and see that I am suffering [very much], and heal me, because I do not forget your laws.
Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
154 Defend me [when others accuse me], and rescue me [from them]; allow me to [continue to] live, as you promised/said that you would.
Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
155 Wicked [people] do not obey (your statutes/what you have decreed that [we] should do), so you will certainly not save them.
Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
156 Yahweh, you are very merciful; allow me to [continue to] live because of [my obeying] (your regulations/the rules that you have given to us).
Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
157 Many [people] are my enemies and [many people] (cause me to suffer/persecute me), but I (do not turn aside from/have not stopped obeying) [LIT] (your requirements/what you have instructed us to do).
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
158 When I look at those who are not faithful to you, I am disgusted because they do not obey (your requirements/what you have instructed [us] to do).
Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
159 [Yahweh], notice that I love (your principles of behavior/what you have declared that we should do); because you faithfully love [me], allow me to [continue to] live.
Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
160 All that you have said is truth, and all (your regulations/the rules that you have given to us) will endure forever.
Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
161 Rulers persecute me for no reason, but in my inner being I revere (your words/what you have said).
Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
162 I am happy about (your words/what you have promised [to do for me)], as happy as someone who has found a great treasure.
Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
163 I thoroughly hate [DOU] [all] lies but I love your laws.
Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
164 Seven/Many times each day I thank you for (your regulations/the rules that you have given to us), and they are [all] just/fair.
Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
165 Things go well for those who love your laws; there is nothing adverse/bad that will happen to them.
Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
166 Yahweh, I confidently expect that you will rescue me [from my troubles], and I obey (your commands/what you have commanded us).
Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
167 I obey (what you require/what you have instructed) us to do; I love it [all] very much.
Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
168 I obey (your principles of behavior/what you have declared that we should do), and you see everything that I do.
Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
169 Yahweh, listen while I pray [for you to help me]; help me to understand [(your words/what you have told us to do)].
Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
170 Hear me while I pray and rescue/save me as you promised/said that you would.
Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
171 I [MTY] will always praise you because you teach me (your statutes/what you have decreed that [we] should do).
Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
172 I will sing about (your words/what you have promised to do) because (all your commands are/everything that you have commanded is) just/fair.
Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
173 I ask you [SYN] to [always] be ready to help me because I have chosen [to obey] (your principles of behavior/what you have declared that we should do).
Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
174 Yahweh, I eagerly desire for you to rescue/save me [from my enemies]; I am delighted with your laws.
Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
175 Allow me to [continue to] live in order that I can [continue to] praise you, and that your regulations/rules [that you have given to us] will continue to help me.
Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
176 I have [wandered away from you] like [SIM] a sheep that has become lost; search for me, because I have not forgotten (your commands/what you have commanded us).
Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.