< Psalms 105 >
1 Give thanks to Yahweh, and tell others that he is very great! Tell everyone in the world what he has done!
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Sing to him; praise him as you sing to him; tell others about his wonderful miracles.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Be happy because [you know that] he [MTY] is holy! You people who worship Yahweh, rejoice!
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Ask Yahweh to help you and give you his strength, and continue to ask him!
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 You people who are descendants of God’s servant Abraham, you descendants of Jacob, the man God chose, think about [all] the wonderful things that he has done: He performed miracles, and he punished [all our enemies].
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 He is Yahweh, our God. He rules and judges [people] throughout the earth.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 He never forgets the agreement that he made; he made a promise that will last for 1,000 generations;
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 that is the agreement that he made with Abraham, and he repeated that agreement with Isaac.
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 [Later] he confirmed it [again] to Jacob as an agreement for the Israeli [people] that would last forever.
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 What he said was, “I will give you the Canaan region; it will belong to you [and your descendants forever].”
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 [He said that to them] when there were only a few of them, a tiny group of people who were living in that land like strangers.
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 They continued to wander from one place to another, from one kingdom to another.
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 But he did not allow others to oppress them. He warned those kings by saying to them,
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 “Do not do harm the [people] whom I have chosen! Do not harm my prophets!”
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 He sent a famine to Canaan, and [as a result all the people] had no food to eat.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 So his people went to Egypt, but first he sent someone there. He sent Joseph, who had been sold to be a slave.
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 [Later, while Joseph was in prison in Egypt], they put his legs in shackles that bruised his feet, and they put an iron collar around his neck.
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 There, Yahweh (refined Joseph’s character/tested Joseph to see if Joseph would continue to trust him), until what Joseph predicted would happen (came true/happened).
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 The king [of Egypt] summoned him, and he set Joseph free; this ruler of many people-groups released Joseph [from prison].
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 [Then] he appointed him to take care of everything in the king’s household, to take care of everything that the king possessed.
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 (Joseph was permitted/He permitted Joseph) to command the king’s servants to do anything that Joseph wanted them to do, and [even] to tell the king’s advisors the things that they should do [for the people of Egypt].
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Later, [Joseph’s father] Jacob arrived in Egypt. He lived like a foreigner in the land that belonged to the descendants of Ham.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 And [years later] Yahweh caused the descendants of Jacob to become very numerous. [As a result], their enemies, [the Egyptians], considered that the Israelis were too strong.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 [So] Yahweh caused the rulers of Egypt to (turn against/hate) the Israeli people, and they planned ways to get rid of his people.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 [But then] Yahweh sent his servant Moses along with [Moses’ older brother] Aaron, whom Yahweh had [also] chosen [to be his servant].
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 Those two performed amazing miracles among the people of Egypt, in that land where the descendants of Ham lived.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Yahweh sent darkness, so that the people of Egypt could not see anything [DOU], but the rulers of Egypt refused [RHQ] to obey when [Moses and Aaron] commanded [them to let the Israeli people leave Egypt].
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Yahweh caused [all] the water in Egypt to become (blood/[red like] blood), and [his doing that] caused all the fish to die.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 [Then he caused] the land to become full of frogs; the king and his officials even had frogs in their bedrooms.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 [Then] Yahweh commanded that flies come, and swarms of them descended [on the people of Egypt], and gnats [also] swarmed across the whole country.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Instead of sending rain, Yahweh sent [terrible] hail, and lightning flashed throughout the land.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 The hail ruined their grapevines and fig trees and shattered all the [other] trees.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 He commanded locusts to come, and swarms of them came; [so many that] they could not be counted.
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 The locusts ate every green plant in the land, ruining all the crops.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 [Then] Yahweh killed the oldest son in every house [of the people of Egypt] [DOU].
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Then he brought the Israeli [people] out [from Egypt]; they were carrying loads of [jewelry made of] silver and gold [that the women of Egypt had given to them]. No one was left behind because of being sick.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 [The people of] Egypt were glad when the Israeli people left, because they had become very afraid of the Israelis.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 [Then] Yahweh spread a cloud to cover the Israelis; and [at night it became] a big fire [in the sky] to give them light.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 [Later] the Israelis asked for [meat to eat], and Yahweh sent [flocks of] quail to them, and he gave them plenty of manna [food] from the sky [each morning].
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 [One day] he caused a rock to open up and water poured out [for them to drink]; it was like a river flowing in that desert.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 [He did that] because he kept thinking about the sacred promise [that he had given] to his servant, Abraham.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 So his people were joyful as he brought them out from Egypt; those people whom he had chosen were shouting joyfully as they went.
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 He gave to them the land that belonged to the people-groups [that lived there in Canaan], and the Israelis harvested crops that [other] people had planted.
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 [Yahweh did all these things] in order that his people would do all the things that he had commanded them to do [DOU]. Praise Yahweh!
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.