< Psalms 10 >

1 Yahweh, (why are you far away [from us]?/it seems that you are far away [from us].) [RHQ] Why do you not pay attention when we have troubles [RHQ]?
Èéha ti ṣe, Olúwa, tí ìwọ fi dúró ní òkè réré? Èéha ti ṣe, tí ìwọ fi ara rẹ pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?
2 People who are proud gladly cause poor people to suffer. So [cause what they do to others to happen to them]! May they be caught in the [same] traps that they set to catch others [MET]!
Nínú àrékérekè ni ènìyàn búburú tí mu aláìlera, ẹni ti ó mú nínú ìdẹ̀kùn àrékérekè rẹ̀.
3 They brag about the [evil] things that they want to do. They praise people who seize from others things that do not belong to them, and they curse you, Yahweh.
Nítorí ènìyàn búburú ń ṣògo ìfẹ́ inú ọkàn rẹ̀; Ó bùkún olójúkòkòrò, ó sì ń kẹ́gàn Olúwa.
4 Wicked people are very proud. As a result, they do not (seek help from/are not concerned about) God; they do not even think that God exists.
Ènìyàn búburú kò lè rí nínú ìgbéraga rẹ̀; kò sí ààyè fún Ọlọ́run nínú gbogbo èrò rẹ̀.
5 But [it seems that] they succeed in everything that they do. They do not think that they will be condemned/punished for their deeds, and they (sneer at/make fun of) their enemies.
Ọ̀nà rẹ̀ ń gún régé nígbà gbogbo; òun ń gbéraga, òfin rẹ̀ sì jìnnà sí i; òun kẹ́gàn àwọn ọ̀tá rẹ̀.
6 They think, “Nothing bad will happen to us! We will never have troubles!”
O wí fún ara rẹ̀, “Kò sí ohun tí ó lè mì mí. Inú mi yóò máa dùn nígbà gbogbo, èmi kò sì ní ní wàhálà.”
7 When they talk [MTY], they are always cursing, lying, and threatening to harm others. They constantly say [MTY] evil things that show that they are ready to do cruel things to others.
Ẹnu rẹ̀ kún fún ègún àti irọ́ àti ìtànjẹ; wàhálà àti ohun búburú wà lábẹ́ ahọ́n rẹ̀.
8 They hide in villages, ready to (ambush/suddenly attack) and kill people who (are innocent/have done nothing wrong). They constantly search for people who will not be able to (resist/defend themselves) [when they are attacked].
Ó lúgọ ní bùba nítòsí ìletò. Ò gọ níbi ìkọ̀kọ̀ láti pa aláìṣẹ̀. Ojú rẹ̀ ń ṣọ́ àwọn tálákà ní ìkọ̀kọ̀.
9 They are like [MET] lions that crouch down and hide, waiting to pounce on their prey. They are like hunters that catch their prey with a net and then drag it away.
Ó ba ní ní bùba bí i kìnnìún nínú pàǹtí; Ó ba ní bùba láti mú àwọn aláìní ìrànwọ́; ó mú àwọn aláìlólùrànlọ́wọ́, ó sì wọ́ wọn lọ sínú àwọ̀n rẹ̀.
10 Just like helpless animals are crushed, people who cannot defend themselves are killed because wicked people are very strong.
Ó ba, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀; kí tálákà ba à le bọ́ sí ọwọ́ agbára rẹ̀.
11 Wicked people say, “God will not pay any attention [to what we do]. His eyes are covered, so he never sees anything.”
Ó wí fún ara rẹ̀, “Ọlọ́run ti gbàgbé; Ó pa ojú rẹ̀ mọ́, òun kì yóò rí i láéláé.”
12 Yahweh God, arise [and help us] Punish [IDM] those wicked people! And do not forget those who are suffering!
Dìde, Olúwa! Gbé ọwọ́ rẹ sókè, Ọlọ́run. Má ṣe gbàgbé àwọn olùpọ́njú.
13 Wicked people revile you [RHQ] continually. They think, “God will never punish us!”
Èéṣe tí ènìyàn búburú ṣe ń kẹ́gàn Ọlọ́run? Èéṣe tí o fi wí nínú ọkàn ara rẹ̀, “Kò ní pè mí láti ṣe ìṣirò”?
14 But you see the trouble and the distress [that they cause]. People who are suffering expect that you will help them; and you help orphans, [also].
Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni ó rí wàhálà àti ìrora; Ìwọ rò láti fi sí ọwọ́ rẹ. Tálákà fi ara rẹ̀ jì fún ọ; Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìní baba.
15 (Break the arms/Destroy the power) of wicked [DOU] people! Continue to pursue and punish them for the wicked things that they do, until they stop doing those things.
Ṣẹ́ apá àwọn ènìyàn búburú àti ènìyàn ibi; pè é láti wá ṣírò fún ìwà ìkà rẹ̀ tí a kò le è rí.
16 Yahweh, you are our king forever, but [wicked] nations will disappear from the earth.
Olúwa ń jẹ ọba láé àti láéláé; àwọn orílẹ̀-èdè yóò ṣègbé lórí ilé rẹ.
17 You have listened to afflicted/suffering people when they cry out to you. You hear them [when they pray], and you encourage [IDM] them.
Ìwọ́ gbọ́, Olúwa, ìfẹ́ àwọn tí a ni lára; Ìwọ gbà wọ́n níyànjú, ó sì gbọ́ igbe wọn,
18 You show that orphans and oppressed people have not done things that are wrong, with the result that human beings will not cause people to be terrified any more.
láti ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní baba àti àwọn ti a ni lára, kí ọkùnrin, tí ó wà ní ayé, kí ó má ṣe dẹ́rùbà ni mọ́.

< Psalms 10 >