< Numbers 25 >

1 While the Israelis were camped at a place called Acacia [Grove], some of the men caused themselves to become unacceptable to God by having sex with some of the women of the Moab [people-group who lived in that area].
Nígbà tí àwọn Israẹli dúró ní Ṣittimu, àwọn ènìyàn sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin Moabu,
2 Then those women invited the men to come when the sacrifices were being offered to their gods. The Israeli men [accepted]. They went to the feasts with the women and worshiped the gods of the Moab people-group.
tí ó pè wọ́n sí ibi ẹbọ òrìṣà wọn. Àwọn ènìyàn náà jẹun wọ́n sì foríbalẹ̀ níwájú òrìṣà wọn.
3 By doing that, those Israeli people joined the women in worshiping the god Baal [add] the Moab people-group thought lived on Peor Mountain. That caused Yahweh to become very angry with his people.
Báyìí ni Israẹli ṣe darapọ̀ mọ́ wọn tí wọ́n sì jọ ń sin Baali-Peori. Ìbínú Olúwa sì ru sí wọn.
4 Yahweh said this to Moses/me: “Seize all the leaders of those men who are doing this and execute them while I am watching. Do that in the daytime. After you do that, I will no longer be angry with the Israeli people.”
Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú gbogbo àwọn olórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, pa wọ́n kí o sì fi wọ́n kọ́ sórí igi ní gbangba nínú oòrùn níwájú Olúwa, kí ìbínú Olúwa lè kúrò ní ọ̀dọ̀ Israẹli.”
5 So Moses/I said to the other Israeli leaders, “Each of you must execute your men who have joined [others] in worshiping Baal.”
Mose sọ fún àwọn onídàájọ́ Israẹli, “Ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ pa arákùnrin rẹ̀ èyí tí ó darapọ̀ ní fífi orí balẹ̀ fún Baali-Peori.”
6 [But later], while Moses/I and many [HYP] other people were crying at the entrance of the Sacred Tent, while they/we were watching, one of the Israeli men brought a woman from the Midian people-group into his tent [and started to have sex with her].
Nítòótọ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin Israẹli sì mú obìnrin Midiani wá síwájú ojú Mose àti gbogbo ìjọ ti Israẹli wọ́n sì ń sọkún ní àbáwọlé àgọ́ ìpàdé.
7 When Phinehas, who was the grandson of Aaron, saw that, he grabbed a spear
Nígbà tí Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni, àlùfáà, rí èyí, ó fi ìjọ sílẹ̀, pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ní ọwọ́ rẹ̀.
8 and rushed into the man’s tent. He thrust the spear completely through the man’s body and into the woman’s belly [and killed both of them]. When he did that, the (plague/serious illness) [that had started to strike the Israelis] stopped.
Ó sì tẹ̀lé arákùnrin Israẹli yìí lọ sínú àgọ́. Ó sì fi ọ̀kọ̀ gún àwọn méjèèjì ní àgúnyọ láti ara ọkùnrin Israẹli àti sí ara obìnrin náà. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn lórí àwọn ọmọ Israẹli sì dúró;
9 But 24,000 people had already died [from that plague].
ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí ó kú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn náà jẹ́ ẹgbàá méjìlá.
10 Then Yahweh said to Moses/me,
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
11 “Phinehas has caused me to stop being angry with the Israeli people, by being as eager as I am [to stop this sinful behavior]. I was ready to get rid of all the Israeli people because I was extremely angry, but Phinehas has prevented me from doing that.
“Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà, ti yí ìbínú mi padà kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí tí ó ní ìtara bí èmi náà ti ní ìtara fún iyì mi láàrín wọn, kí ó lè jẹ́ pé èmi ló pa wọ́n run nínú ìtara mi sí wọn.
12 Now tell him that I am making a special peace agreement with him.
Nítorí náà sọ fún un pé èmi ṣe májẹ̀mú àlàáfíà mi pẹ̀lú rẹ̀.
13 In this agreement, I am promising to give to him and to his descendants the right/authority to be priests. I am doing this because [he showed that] he was very eager to honor me, his God, by stopping this sinful behavior. He has caused the Israeli people to become acceptable to me again by causing them to be forgiven for their sin.”
Òun àti irú-ọmọ rẹ̀ yóò ní májẹ̀mú láéláé fún iṣẹ́ àlùfáà, nítorí pé ó ní ìtara fún Ọlọ́run rẹ̀ láti fi yẹ́ Ọlọ́run sí, ó sì ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Israẹli.”
14 The Israeli man who was killed with the woman of the Moab people-group was named Zimri. He was the son of Salu, who was the leader of a family from the tribe of Simeon.
Orúkọ ọmọ Israẹli tí a pa pẹ̀lú obìnrin Midiani náà ni Simri, ọmọ Salu, olórí ilé kan nínú àwọn ọmọ Simeoni.
15 The woman’s name was Cozbi. She was the daughter of Zur, who was the leader of one of the clans of the Midian people-group.
Orúkọ ọmọbìnrin Midiani náà tí a pa ní Kosbi ọmọbìnrin Suri, tí ṣe olóyè àwọn ẹ̀yà kan nínú ìdílé kan ní Midiani.
16 Then Yahweh said to Moses/me,
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
17 “[Take your men and] attack the Midian people-group and kill them.
“Ka àwọn ará Midiani sí ọ̀tá, kí o sì pa wọ́n,
18 They have become your enemies, because they tricked you Israeli people and induced/persuaded many of you to worship Baal, and because [one of your men had sex with] Cozbi, who was the daughter of a leader of the Midian people-group. She was killed at the time the plague [started because the people sinned] at Peor [Mountain].”
nítorí pé wọ́n ṣe sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá nígbà tí wọ́n tàn yín nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Peori, àti arábìnrin wọn Kosbi ọmọbìnrin ìjòyè Midiani kan, obìnrin tí a pa nígbà tí àjàkálẹ̀-ààrùn ṣẹlẹ̀ nítorí Peori.”

< Numbers 25 >