< Numbers 20 >
1 In March/April [of the next year], the Israeli people traveled/walked to the Zin Desert and (camped/set up their tents) near Kadesh [town]. While they/we were there, [Moses’/my older sister] Miriam died and was buried there.
Ní oṣù kìn-ín-ní, gbogbo àgbájọ ọmọ Israẹli gúnlẹ̀ sí pápá Sini, wọ́n sì dúró ní Kadeṣi. Níbẹ̀ ni Miriamu kú, wọ́n sì sin ín.
2 There was no water for the people to drink there, so they came to Aaron and Moses/me.
Omi kò sí fún ìjọ ènìyàn, àwọn ènìyàn sì kó ara wọn jọ pọ̀ sí Mose àti Aaroni,
3 They complained and said, “We wish that we had died in front of Yahweh’s Sacred Tent when our fellow Israelis died!
wọ́n bá Mose jà wọ́n sì wí pé, “Ìbá kúkú sàn kí a kú nígbà tí àwọn arákùnrin ti kú níwájú Olúwa!
4 (Did you bring us, who are Yahweh’s people, into this desert to die along with our livestock?/You brought us, who are Yahweh’s people, into this desert to die along with our livestock!) [RHQ]
Kí ni ó dé tí o sì kó gbogbo ìjọ ènìyàn Olúwa wá sí aginjù yìí, kí àwa àti àwọn ẹran ọ̀sìn wa bá à kú síbí?
5 Why did you bring us from Egypt to this miserable place [RHQ]? There is no grain, there are no figs, no grapes, and no pomegranates here. And there is no water for us to drink!”
Kí ni ó dé tí o fi mú wa gòkè kúrò ní Ejibiti wá sí ibi búburú yìí? Ibi tí kò ní oúnjẹ tàbí igi ọ̀pọ̀tọ́, èso àjàrà tàbí pomegiranate. Bẹ́ẹ̀ ni kò sí omi tí a ó mu níhìn-ín!”
6 Aaron and Moses/I turned away from the people and went to the entrance of the Sacred Tent and prostrated themselves/ourselves on the ground. Then Yahweh appeared to them/us with his bright glory,
Mose àti Aaroni kúrò ní ibi àpéjọ, wọ́n sì lọ dojúbolẹ̀ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahàn wọ́n.
7 and he said to Moses/me,
Olúwa sọ fún Mose pé,
8 “You and Aaron must take Aaron’s walking stick with you and gather all the people together. While the people are watching, command that water will flow out of that [large] rock over there. Water for the people will flow from it; all they and all their livestock will have enough water to drink.”
“Mú ọ̀pá, náà kí o sì pe ìjọ àwọn ènìyàn jọ, ìwọ àti Aaroni arákùnrin rẹ, kí ẹ sọ̀rọ̀ sí àpáta náà ní ojú wọn, yóò sì tú omi rẹ̀ jáde, ìwọ ó sì fún ìjọ àti ẹran wọn mu.”
9 So Moses/I did what Yahweh told him/me to do. He/I took Aaron’s walking stick from the place in the Sacred Tent where it was kept.
Báyìí ni Mose mú ọ̀pá láti iwájú Olúwa wá, gẹ́gẹ́ bí ó ti pàṣẹ fún un.
10 Then Aaron and he/I summoned all the people to gather at the rock. Then Moses/I shouted to them, “All you rebellious people, listen! Is it necessary for us to give you water from this rock?”
Òun àti Aaroni pe àwọn ènìyàn jọ sí ojú kan níwájú àpáta, Mose sì sọ fún wọn, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀, àwa kì yóò lè mú omi jáde láti inú àpáta yìí wá bí?”
11 Then Moses/I raised his/my hand and [instead of speaking to the rock], he/I struck the rock two times with the walking stick. And water gushed/poured out. So all the people and their livestock drank all the water that they wanted.
Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ó sì fi ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ lu àpáta lẹ́ẹ̀méjì. Omi sì tú jáde, gbogbo ìjọ ènìyàn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sì mu.
12 But Yahweh said to Aaron and Moses/me, “You did not believe that I could demonstrate my power to the Israeli people [and give them water without your striking the rock]. So you will not lead them into the land that I am giving to them!”
Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Nítorí pé ẹ̀yin kò gbà mí gbọ́ tó láti bu ọlá fún mi níwájú àwọn ọmọ Israẹli, ìwọ kò ní kó àwọn ìjọ ènìyàn yìí dé ilẹ̀ tí mo fún wọn.”
13 Later this place was called Meribah, [which means ‘arguing’], because there the Israeli people argued with Yahweh, and there he showed his power to them [by giving them water].
Èyí ni omi ti Meriba, níbi tí àwọn ọmọ Israẹli ti bá Olúwa jà àti ibi tí O ti fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni mímọ́ láàrín wọn.
14 [While the people were] at Kadesh [town], Moses/I sent messengers to the king of Edom to tell him this: “Your relatives, the Israeli people, are sending you this message. You know the many troubles/hardships that have happened to us.
Mose sì ránṣẹ́ láti Kadeṣi sí ọba Edomu, wí pé, “Èyí ni nǹkan tí arákùnrin rẹ Israẹli sọ, ìwọ ti mọ̀ nípa gbogbo ìnira, tí ó wá sí orí wa.
15 You know that our ancestors went down to Egypt. You know that they stayed there for many years. They suffered because the [rulers of] Egypt caused them to become their slaves [and to work very hard].
Àwọn baba ńlá wa sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti, a sì gbé ibẹ̀ fún ọ̀pọ̀ ọdún. Àwọn ará Ejibiti ni wá lára àti àwọn baba wa,
16 “But when they called out to Yahweh, he heard them and sent an angel who brought them out of Egypt. Now we have set up our tents here at Kadesh, a town at the border of your land.
ṣùgbọ́n nígbà tí a sọkún sí Olúwa, ó gbọ́ ẹkún wa, ó sì rán angẹli kan sí wa, ó sì mú wa jáde láti Ejibiti. “Báyìí àwa wà ní Kadeṣi, ìlú tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ.
17 Please allow us to travel through your country. We will [be careful to] not walk through your fields and your vineyards. We will not even drink water from your wells. As we travel, we will stay on the king’s highway, [the main road that goes from the south to the north], and we will not leave that road until we have crossed the border [of your country in the north].”
Jọ̀wọ́ jẹ́ kí a gba orílẹ̀-èdè rẹ kọjá, àwa kì yóò gba inú oko tàbí ọgbà àjàrà rẹ kọjá, tàbí mu omi láti inú kànga. A ó ma kọjá ní òpópónà ọba, àwa kì yóò yà sí ọ̀tún tàbí sí òsì títí àwa yóò fi kọjá ní ilẹ̀ rẹ.”
18 But the king of Edom refused. He replied, “Stay out of my country! If you try [to enter it], I will [send my army to] attack you!”
Ṣùgbọ́n Edomu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò le gba ibí kọjá; bí ẹ bá dán an wò, a ó dìde ogun sí yín, a ó sì bá yín jà pẹ̀lú idà.”
19 The Israeli messengers replied, “[If we travel through your country], we will stay on the main road. If we and any of our livestock drink any of your water, we will pay for it. We want only to travel through your country. We do not want anything else.”
Àwọn ọmọ Israẹli dáhùn pé, “A ó gba ọ̀nà tóóró, bí àwa tàbí ẹran ọ̀sìn wa bá sì mú lára omi rẹ, a ó san owó rẹ̀. A kàn fẹ́ rìn kọjá lórí ilẹ̀ rẹ ni kò sí nǹkan kan mìíràn tí a fẹ́ ṣe.”
20 But the king replied, “No! Stay out of our country! We will not [allow you] to travel through our land!” Then he sent the strongest soldiers in his army to prevent the Israelis [from entering his country].
Wọ́n tún dáhùn wí pé, “Ẹ kò lè kọjá.” Nígbà náà ni Edomu jáde wá láti kọjú ìjà sí wọn pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àti alágbára ọmọ-ogun.
21 So, because [the king of] Edom refused to allow the Israelis to travel through his country, the Israelis turned [and traveled a different way].
Nígbà tí Edomu sì kọ̀ jálẹ̀ láti jẹ́ kí wọn kọjá ní ilẹ̀ wọn, Israẹli yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
22 The Israeli people left Kadesh. They went to Hor Mountain,
Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì jáde láti Kadeṣi wọ́n sì wá sí orí òkè Hori.
23 [which is at the border of Edom]. While they were there, Yahweh said to Aaron and Moses/me,
Ní orí òkè Hori, ní ẹ̀gbẹ́ ààlà Edomu Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
24 “It is time for Aaron to die [EUP]. He will not enter the land that I am giving to you Israelis, because the two of you disobeyed me [when I told you to speak to the rock to cause] the water [to flow] at Meribah.
“Aaroni yóò kú. Kò ní wọ ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn ọmọ Israẹli, nítorí ẹ̀yin méjèèjì ṣe àìgbọ́ràn sí òfin mi níbi omi Meriba.
25 Now you, Moses, take Aaron and his son Eleazar up on Hor Mountain.
Mú Aaroni àti ọmọ rẹ̀ Eleasari lọ sí orí òkè Hori.
26 There you must remove Aaron’s robes [that he wears when he does the work of a priest], and put them on his son, Eleazar. Aaron will die up there.”
Bọ́ aṣọ Aaroni kí o sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, nítorí pé Aaroni yóò kú síbẹ̀.”
27 So Moses/I did what Yahweh commanded. The three of them/us climbed up Hor Mountain, while all the Israeli people watched.
Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n lọ sí orí òkè Hori ní ojú gbogbo ìjọ ènìyàn.
28 At the top of the mountain, Moses/I took off the robes that Aaron wore [while he did the work of a priest] and put them on Eleazar. Then Aaron died there on the top of the mountain, and Eleazar and Moses/I went back down.
Mose bọ́ aṣọ Aaroni ó sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, Aaroni sì kú sí orí òkè. Nígbà náà Mose àti Eleasari sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè,
29 When the Israeli people realized that Aaron had died, they all mourned for him for 30 days.
nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbọ́ pé Aaroni ti kú, gbogbo ilé Israẹli ṣe ìdárò rẹ̀ fún ọgbọ̀n ọjọ́.