< Numbers 12 >
1 [Moses’/My older sister] Miriam and [his/my older brother] Aaron were saying this: “Is Moses the only one to whom Yahweh has spoken messages to tell to us [RHQ]? Does Yahweh not speak messages to us two also?” [They told people that] they were saying that because Moses/I had married a woman who was a descendant of the Cush people-group, [but they were really saying that because they (were jealous/did not want Moses/me to be the only leader of the Israeli people)]. But Yahweh heard what they were saying.
Miriamu àti Aaroni sọ̀rọ̀-òdì sí Mose nítorí pé ó fẹ́ obìnrin ará Etiopia.
Wọ́n sì wí pé, “Nípa Mose nìkan ni Olúwa ti sọ̀rọ̀ bí, kò ha ti ipa wa sọ̀rọ̀ bí?” Olúwa sì gbọ́ èyí.
3 [The truth was that] Moses/I was very humble. He/I was more humble than anyone else on the earth [and Moses/I had not appointed himself/myself to be their leader].
(Mose sì jẹ́ ọlọ́kàn tútù ju gbogbo ènìyàn tó wà lórí ilẹ̀ ayé lọ).
4 So immediately Yahweh spoke to Moses/me and to Aaron and Miriam. He said, “All three of you must go and stand at the Sacred Tent.” So they/we did that.
Lẹ́ẹ̀kan náà ni Olúwa sọ fún Mose, Aaroni àti Miriamu pé, “Ẹ̀yin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, jáde wá sínú àgọ́ ìpàdé.” Àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì jáde síta.
5 Then Yahweh descended to the entrance of the tent in a cloud [that resembled a huge white] pillar. He told Aaron and Miriam to step forward, so they did.
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ọ̀wọ́n ìkùùkuu, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó ké sí Aaroni àti Miriamu. Àwọn méjèèjì sì bọ́ síwájú,
6 Then he said to them, “Listen to me! When a prophet is among you, I [usually] reveal myself to him by allowing him to see visions, and I speak to him in dreams.
Ó wí pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, “Bí wòlíì Olúwa bá wà láàrín yín, Èmi Olúwa a máa fi ara à mi hàn án ní ojúran, Èmi a máa bá a sọ̀rọ̀ nínú àlá.
7 But that is not the way I speak to my servant Moses. I trust that he will lead my people [well].
Ṣùgbọ́n èyí kò rí bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú Mose ìránṣẹ́ mi; ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo ilé mi.
8 So I talk to him face-to-face. I speak to him (clearly/using words that he will understand easily), not using parables. He has even seen what I look like. So you should be afraid to criticize my servant Moses!”
Mo sì ń bá a sọ̀rọ̀ ní ojúkojú, ọ̀rọ̀ yékéyéké tí kì í ṣe òwe, ó rí àwòrán Olúwa. Kí ló wá dé tí ẹ̀yin kò ṣe bẹ̀rù láti sọ̀rọ̀-òdì sí Mose ìránṣẹ́ mi?”
9 Yahweh was very angry with Miriam and Aaron, and he left.
Ìbínú Olúwa sì ru sókè sí wọn Olúwa sì fi wọ́n sílẹ̀.
10 When the cloud rose up from the Sacred Tent, Aaron looked at Miriam, and he saw that her skin was [as white] as snow, because she now had leprosy.
Nígbà tí ìkùùkuu kúrò lórí àgọ́ lójijì ni Miriamu di adẹ́tẹ̀, ó funfun bí i yìnyín. Aaroni sì padà wo Miriamu ó sì rí i pé ó ti di adẹ́tẹ̀,
11 Aaron said to Moses/me, “My master, please do not punish us for this sin that we have foolishly committed.
Aaroni sì wí fún Mose pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀, èyí tí a fi ìwà òmùgọ̀ dá sí wa lọ́rùn.
12 Do not allow Miriam to be like a baby that is already dead when it is born, whose flesh is already half decayed!”
Má ṣe jẹ́ kí ó dàbí òkú ọmọ tí a bí, tí ìdajì ara rẹ̀ ti rà dànù.”
13 So Moses/I cried out to Yahweh, saying, “God, I plead with you to heal her!”
Torí èyí Mose sì kígbe sí Olúwa, “Ọlọ́run, jọ̀wọ́, mú un láradá!”
14 But Yahweh replied, “If her father had [rebuked her for doing something wrong by] spitting in her face, she would have been ashamed for seven days. [She should be ashamed because of what she has done]. So send her outside the camp for seven days. Then [she will not have leprosy any more, and] she may return to the camp.”
Olúwa sì dá Mose lóhùn, “Bí baba rẹ̀ bá tutọ́ sí i lójú, ojú kò wa ní í tì í fún ọjọ́ méje? Dá a dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, lẹ́yìn èyí ki a tó ó le mú wọlé.”
15 So they sent her outside the camp for seven days. (The people/We) did not move [to another location] until she returned.
Miriamu sì dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, àwọn ènìyàn kò sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn títí tí Miriamu fi wọ inú ibùdó padà.
16 But after [she returned], they/we left Hazeroth and moved [north] in the Paran Desert and set up their/our tents there.
Lẹ́yìn èyí, àwọn ènìyàn kúrò ní Haserotu, wọ́n sì pa ibùdó sí aginjù Parani.