< Micah 6 >

1 Pay attention to what Yahweh says [to you Israeli people]: “Stand up [in court] and state what you are accusing [me] about. And allow the hills and mountains to hear what you will say.
Ẹ fi etí sí ohun tí Olúwa wí: “Dìde dúró, bẹ ẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ rẹ níwájú òkè ńlá; sì jẹ́ kí àwọn òkè kéékèèké gbọ́ ohun tí ó fẹ́ wí.
2 [But then] you mountains must [also] listen [carefully] [DOU] to what I, Yahweh, am complaining [about my people]. I have something to say about what [DOU] my Israeli people are doing that displeases me.
“Gbọ́, ìwọ òkè ńlá, ẹ̀sùn Olúwa; gbọ́, ìwọ ìpìlẹ̀ ilé ayérayé. Nítorí Olúwa ń bá àwọn ènìyàn rẹ̀ wíjọ́; òun yóò sì bá Israẹli rojọ́.
3 My people, what have I done to [cause trouble for] you [RHQ]? What have I done to cause you to experience difficulties? Answer me!
“Ẹ̀yin ènìyàn mi, kí ni mo ṣe fún yín? Àti nínú kí ni mo ti dá yin lágara? Dá mi lóhùn.
4 I [did great things for your ancestors]; I brought them out of Egypt; I rescued them from that land where they were slaves. I sent Moses to [lead] them, and [his older brother] Aaron and [his older sister] Miriam.
Nítorí èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì rà yín padà láti ilẹ̀ ẹrú wá. Mo rán Mose láti darí yín, bákan náà mo rán Aaroni àti Miriamu síwájú rẹ̀.
5 My people, think about when Balak, the king of Moab, requested Beor’s son Balaam [to curse your ancestors], and think about what Balaam replied. Think about [how your ancestors crossed the Jordan River miraculously while] they were traveling from Acacia to Gilgal. [Think about those things in order] that you may know that [I], Yahweh, do what is right.”
Ìwọ ènìyàn mi, rántí ohun tí Balaki ọba Moabu gbèrò àti ohun tí Balaamu ọmọ Beori dáhùn. Rántí ìrìnàjò rẹ̀ láti Ṣittimu dé Gilgali, kí ìwọ ba le mọ òdodo Olúwa.”
6 [The Israeli people ask, ] “What shall we bring to Yahweh [who lives in] heaven when we come to him and bow down before him? Should we bring calves that are a year-old that will be offerings that will be [killed and] completely burned [on the altar]?
Kí ni èmi yóò ha mú wá síwájú Olúwa tí èmi ó fi tẹ ara mi ba níwájú Ọlọ́run gíga? Kí èmi ha wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, pẹ̀lú ọmọ màlúù ọlọ́dún kan?
7 Will Yahweh be pleased [if we offer to him] 1,000 rams and 10,000 streams of [olive] oil? Should we offer our firstborn children [to be sacrifices] to pay for the sins that we have committed [DOU]?”
Ǹjẹ́ Olúwa yóò ní inú dídùn sí ẹgbẹgbàarùn-ún àgbò, tàbí sí ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìṣàn òróró? Èmi yóò ha fi àkọ́bí mi sílẹ̀ fún ìré-òfin-kọjá mi, èso inú ara mi fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkàn mi?
8 [No, because] he has shown each of us what is good [to do]; he has shown [RHQ] us what he requires each of us [to do]: He wants us to do what is just/fair and to love and to be merciful [to others], and [he wants us] to live humbly [while we fellowship] with him, our God.
Ó ti fihàn ọ́, ìwọ ènìyàn, ohun tí ó dára, àti ohun tí Olúwa ń béèrè lọ́wọ́ rẹ? Bí kò ṣe láti ṣe òtítọ́, kí o sì fẹ́ràn àánú, àti kí o rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
9 “I am Yahweh, so if you are wise, you should revere me. I am calling out to [you people of] Jerusalem, ‘The armies [MET] that will destroy your city are coming, so pay careful attention to me, the one who is causing them to punish you with my rod.
Gbọ́! Ohùn Olúwa kígbe sí ìlú ńlá náà, láti jẹ ọlọ́gbọ́n ni láti bẹ̀rù orúkọ rẹ. “Ẹ kíyèsi ọ̀pá rẹ̀ gbọ́ ọ̀pá àti Ẹni náà tí ó yàn án.
10 Do you think that [RHQ] I should forget that you wicked people filled your homes with valuable things that you acquired by cheating [others]? Do you think that [RHQ] I should forget that you used false measures [when you bought and sold things]? Those are things that I hate.
Ǹjẹ́ ìṣúra ìwà búburú ha wà ní ilé ènìyàn búburú síbẹ̀, àti òsùwọ̀n àìkún tí ó jẹ́ ohun ìbínú?
11 [Do you think] that [RHQ] I should say nothing about people who use scales that do not weigh correctly, and who use weights that are not accurate?
Ǹjẹ́ èmi ha lè kà wọ́n sí mímọ́ pẹ̀lú òsùwọ̀n búburú, pẹ̀lú àpò òsùwọ̀n ẹ̀tàn?
12 The rich people among you always act violently [to get money from poor people]. All of the people [in Jerusalem] are liars, and they [SYN] always deceive people.
Àwọn ọlọ́rọ̀ inú rẹ̀ kún fún ìwà ipá; àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ ti ọ̀rọ̀ èké àti ahọ́n wọn ń sọ ẹ̀tàn?
13 Therefore, I have [already] begun to get rid of you, to ruin you because of the sins that you have committed.
Nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ ṣàìsàn ní lílù ọ́, láti sọ ọ́ dahoro nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
14 [Soon] you will eat food, but you will not have enough to satisfy you; your stomachs will [still feel as though they are] empty. You will try to save up [money], but you will not be able to save anything, because I will send your enemies to take it from you in wars [MTY].
Ìwọ yóò jẹun ṣùgbọ́n kì yóò yó; ìyàn yóò wà láàrín rẹ. Ìwọ yóò kó pamọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò lò láìléwu, nítorí ohun tí ìwọ kò pamọ́ ni èmi yóò fi fún idà.
15 You will plant [seeds], but you will not harvest [anything]. You will press olives, but [others], not you, will use the [olive] oil. You will trample on grapes [and make wine from the juice], but [others], not you, will drink the wine.
Ìwọ yóò gbìn ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò kórè ìwọ yóò tẹ olifi, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò fi òróró rẹ̀ kún ara rẹ; ìwọ yóò tẹ èso àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò mu wáìnì.
16 [Those things will happen to you because] you obey [only] the wicked laws of [King] Omri, and [you do the terrible things that wicked King] Ahab and his descendants commanded. So, I will destroy your [country], and I will cause your people to be despised; people [of other nations] will insult you.’”
Nítorí tí ìwọ ti pa òfin Omri mọ́, àti gbogbo iṣẹ́ ilé Ahabu, tí ó sì ti tẹ̀lé ìmọ̀ràn wọn, nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ fún ìparun àti àwọn ènìyàn rẹ fún ìfiṣe ẹlẹ́yà; ìwọ yóò sì ru ẹ̀gàn àwọn ènìyàn mi.”

< Micah 6 >