< Malachi 4 >

1 [This is also what] the Commander of the armies of angels says: “There will be a time that I will judge [and punish] people. [When that happens, it will be] like [SIM] a very hot furnace. At that time, all the proud and wicked people will be burned up like [MET] stubble burns. They will be burned up completely, [like] roots and branches [and everything else on a tree burns completely in a very hot fire].
“Dájúdájú, ọjọ́ náà ń bọ̀; tí yóò máa jó bi iná ìléru. Gbogbo àwọn agbéraga, àti gbogbo àwọn olùṣe búburú yóò dàbí àgékù koríko: ọjọ́ náà tí ń bọ̀ yóò si jó wọn run,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ti ki yóò fi kù gbòǹgbò kan tàbí ẹ̀ka kan fún wọn.
2 But [as for] you who revere me [MTY], [the one who will save you will come to you] like [MET] [the sun shines in the morning, and enable you to] become righteous (OR, [do what is] righteous); he will restore you [and protect you like a bird protects its chicks] [MET] under its wings. [When he comes, ] you will [be very joyful], like [SIM] calves that go out from a barn into the pasture leaping [joyfully].
Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù orúkọ mi, oòrùn òdodo yóò yọ, pẹ̀lú ìmúláradá ni ìyẹ́ apá rẹ̀. Ẹ̀yin yóò sì jáde lọ, ẹ̀yin yóò sì máa fò fún ayọ̀ bi àwọn ẹgbọrọ màlúù tí a tú sílẹ̀ lórí ìso.
3 At the time when I judge people, you will tread on wicked people as though [SIM] they were the dirt under your feet. [That is what I], the Commander of the armies of angels, promise.
Ẹ̀yin yóò sì tẹ àwọn ènìyàn búburú mọ́lẹ̀: nítorí wọn yóò di eérú lábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ yín, ní ọjọ́ náà tí èmi yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 Be sure to obey the laws that I gave to Moses, who served me [well]. [Obey all] the commandments and regulations that I gave him on Sinai [Mountain], for all [you people of] Israel [to obey.]
“Ẹ rántí òfin Mose ìránṣẹ́ mi, àwọn ìlànà àti òfin èyí tí mo fún un ní Horebu fún gbogbo Israẹli.”
5 Listen [to this: Some day] I will send to you the prophet Elijah. [He will arrive] before the great and dreadful/terrible day when [I], Yahweh, [will judge and punish people].
“Wò ó, èmi yóò rán wòlíì Elijah sí i yín, ki ọjọ́ ńlá, ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa to dé.
6 Because of what he [preaches], parents and their children will [love] each other [again] [IDM]. If that does not happen, I will come and curse your country [and destroy it].”
Òun yóò sì pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ọkàn àwọn ọmọ sì ti àwọn baba wọn, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi yóò wá, èmi yóò sì fi ilẹ̀ náà gégùn.”

< Malachi 4 >