< Job 9 >
Jobu sì dáhùn ó sì wí pé,
2 “Yes, I certainly know that [much of] what you said is true. But (how can anyone say to God, ‘I (am innocent/have not done what is wrong) and prove it?’/no one can say to God ‘I (am innocent/have not done what is wrong) and prove it.’) [RHQ]
“Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́. Báwo ní ènìyàn yóò ha ti ṣe jẹ́ aláre níwájú Ọlọ́run?
3 If someone wanted to argue with God [about that], God could ask him 1,000 questions, and that person would not be able to answer any of them!
Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà, òun kì yóò lè dalóhùn kan nínú ẹgbẹ̀rún ọ̀rọ̀.
4 God is very wise [IDM] and very powerful; no one who has tried to challenge God has been able to win.
Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun. Ta ni ó ṣe agídí sí i tí ó sì gbé fún rí?
5 He even moves mountains, without them (OR, anyone) knowing about it. When he is angry, he turns them upside down.
Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́: tí ó taari wọn ṣubú ní ìbínú rẹ̀.
6 He sends earthquakes that shake the ground; he causes the pillars that support the earth to tremble.
Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀, ọwọ̀n rẹ̀ sì mì tìtì.
7 [Some days] he speaks to the sun, and it does not rise, and [some nights] he prevents the stars from shining.
Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn, kí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.
8 He alone (stretched out/put in place) the sky; he alone puts his feet on the waves (OR, on the huge sea monster).
Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run, ti ó sì ń rìn lórí ìgbì Òkun.
9 He put in their places [the clusters/groups of stars that are called] The Dipper/Bear, Orion, the Pleiades, and the stars in the southern sky.
Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari àti Orioni, Pleiadesi àti ìràwọ̀ púpọ̀ ti gúúsù.
10 Only he does great things that we cannot understand; he does more marvelous things than we are able to count.
Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ, àní ohun ìyanu láìní iye.
11 He passes by where I am, but I do not see him; he moves further on, but I do not see him go.
Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i, ó sì kọjá síwájú, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.
12 If he [wants to] snatch something away, no one [RHQ] can hinder him; no one dares to ask him, ‘Why are you doing that?’ [RHQ]
Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà? Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?
13 God will not very easily stop being angry; he defeated [MTY] those who [tried to] help Rahab, [the great sea monster].
Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn, àwọn onírànlọ́wọ́ ti Rahabu a sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.
14 “So, [if God took me to court], what could I say [MTY] to answer him?
“Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé? Tí èmi yóò fi ma ṣe àwáwí?
15 Even though I (would be innocent/would not have done what is wrong), I would not be able to answer him. All I could do would be to request God, my judge/accuser, to act mercifully toward me.
Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn; ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.
16 If I summoned him to [come to the courtroom] and he said that he would come, I would not believe that he would pay attention to what I would say.
Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn, èmi kì yóò sì gbàgbọ́ pé, Òun ti fetí sí ohùn mi.
17 He sends storms to batter me, and he bruises me many times (without any reason to do that/even though I am innocent).
Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá, ó sọ ọgbẹ́ mi di púpọ̀ láìnídìí.
18 [It is as though] he will not let me get/catch my breath, because he causes me to suffer all the time.
Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi, ṣùgbọ́n ó mú ohun kíkorò kún un fún mi.
19 If I would try to (wrestle with/fight against) him, [there is no way that I could defeat him, ] [because] he is stronger than I am. If I would request him to appear in court, there is no one who could [RHQ] force him to go there.
Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó! Alágbára ni, tàbí ní ti ìdájọ́, ta ni yóò dá àkókò fún mi láti rò?
20 Even though I was innocent, what I would say would cause him to say that I must be punished [MTY]; even though I had not done anything wrong, he would prove that I am guilty.
Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi; bí mo wí pé olódodo ni èmi yóò sì fi mí hàn ní ẹni ẹ̀bi.
21 “I have not done what is wrong, but that is not important. I despise continuing to remain alive.
“Olóòótọ́ ni mo ṣe, síbẹ̀ èmi kò kíyèsi ara mi, ayé mi ní èmi ìbá máa gàn.
22 But it doesn’t matter, because God will get rid of [all of us, ] both those who are innocent and those who are wicked.
Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ: ‘Òun a pa ẹni òtítọ́ àti ènìyàn búburú pẹ̀lú.’
23 When people experience disaster and it causes them to suddenly die, God laughs at it, even if they are innocent.
Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì, yóò rẹ́rìn-ín nínú ìdààmú aláìṣẹ̀.
24 God has allowed wicked people to control [what happens in] the world. [It is as though] he has caused judges to be blindfolded, [with the result that they cannot judge fairly]. If it is not God who has put wicked people in control, who has done it?
Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú; ó sì bo àwọn onídàájọ́ rẹ̀ lójú; bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ ǹjẹ́ ta ni?
25 “My days go by very quickly, like a fast runner; [it is as though] they run away, and nothing good happens to me on those days.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ, wọ́n fò lọ, wọn kò rí ayọ̀.
26 My life goes by very rapidly, like a boat made from reeds sailing swiftly, or like an eagle that swoops down to seize a small animal.
Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ; bí idì tí ń yára si ohùn ọdẹ.
27 If I smile and say [to God], ‘I will forget what I am complaining about; I will stop looking sad and try to be cheerful/happy,’
Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi, èmi ó fi ọkàn lélẹ̀, èmi ó sì rẹ ara mi lẹ́kún.’
28 then I become afraid because of all that I am suffering, because I know that God does not consider that I am innocent.
Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí, èmi mọ̀ pé ìwọ kì yóò mú mi bí aláìṣẹ̀.
29 He will (condemn me/declare that I should be punished), so why should I keep trying in vain [to defend myself]?
Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi, ǹjẹ́ kí ni èmi ń ṣe làálàá lásán sí?
30 If I washed myself with snow or cleansed my hands with lye/soap [to get rid of my guilt],
Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi, tí mo fi omi aró wẹ ọwọ́ mi mọ́,
31 he would still throw me into a filthy pit; as a result [it would be as though] even my clothes would detest me.
síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò ọ̀gọ̀dọ̀ aṣọ ara mi yóò sọ mi di ìríra.
32 “God is not a human, as I am, so there is no way that I could answer him [to prove that I am innocent] if we went together to have a trial [in a courtroom].
“Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi, tí èmi ó fi dá a lóhùn tí àwa o fi pàdé ní ìdájọ́.
33 There is no one to (mediate/hear us and decide who is right), no one who has authority over both of us [IDM].
Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa tí ìbá fi ọwọ́ rẹ̀ lé àwa méjèèjì lára.
34 I wish/desire that he would stop punishing [MTY] me, and that he would not continue to terrify me.
Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi, kí ìbẹ̀rù rẹ̀ kí ó má sì ṣe dáyà fò mí.
35 If he did that, I would declare [that I am innocent] without being afraid of him, because I know that I really have not [done what is wrong like God thinks that I have].”
Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀; ṣùgbọ́n bí ó tí dúró tì mí, kò ri bẹ́ẹ̀ fún mi.