< Job 19 >

1 Then Job replied:
Ìgbà náà ni Jobu dáhùn, ó sì wí pé:
2 “How long will you [three] torment me and crush my spirit by saying to me [that I am wicked]?
“Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin ó fi máa fi ìyà jẹ mí, tí ẹ̀yin ó fi máa fi ọ̀rọ̀ yìí?
3 You have already insulted me many [HYP] times; (are you not ashamed for saying these things to me?/you should be ashamed for saying these things to me.) [RHQ]
Ìgbà mẹ́wàá ní yin yọ mi lénu ẹ̀yin ti ń gàn mí; ojú kò tì yín tí ẹ fi jẹ mí ní yà.
4 Even if it were true that I have done things that are wrong, I have not injured you!
Kí a sì wí bẹ́ẹ̀ pé, mo ṣìnà nítòótọ́, ìṣìnà mi wà lára èmi tìkára mi.
5 If you truly think that you are better than I am, and you think that my being miserable now proves that I (am guilty/have committed many sins),
Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ̀yin ó ṣògo si mi lórí nítòótọ́, tí ẹ ó sì máa fi ẹ̀gàn mi gún mí lójú,
6 you need to realize that it is God who has caused me to suffer. [It is as though] he has trapped me with his net.
kí ẹ mọ̀ nísinsin yìí pé, Ọlọ́run ni ó bì mí ṣubú, ó sì nà àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.
7 “I cry out, ‘Help me!’, but no one answers me. I call out loudly, but there is no one, [not even God, ] who acts fairly toward me.
“Kíyèsi, èmi ń kígbe pe, ‘Ọwọ́ alágbára!’ Ṣùgbọ́n a kò gbọ́ ti èmi; mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ìdájọ́.
8 [It is as though] [MET] God has blocked my way, with the result that I cannot go where I want to; [it is as though] he has forced me to try to find my way in the darkness.
Ó ṣọgbà dí ọ̀nà mi tí èmi kò le è kọjá, Ó sì mú òkùnkùn ṣú sí ipa ọ̀nà mi.
9 He has (taken away my good reputation/caused people not to honor me any more); [it is as though] he removed [MET] a crown from my head.
Ó ti bọ́ ògo mi, ó sì ṣí adé kúrò ní orí mi.
10 He batters me from every side, and I will soon die. He has caused me to no longer confidently expect [him to do good things for me].
Ó ti bà mí jẹ́ ní ìhà gbogbo, ẹ̀mí sì pin; ìrètí mi ni a ó sì fàtu bí igi.
11 He attacks me because he is extremely angry with me [MET], and he considers that I am his enemy.
Ó sì tiná bọ ìbínú rẹ̀ sí mi, ó sì kà mí sí bí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀tá rẹ̀.
12 [It is as though] he sends his army to attack me; they surround my tent, preparing to attack me.
Ẹgbẹ́ ogun rẹ̀ sì dàpọ̀ sí mi, wọ́n sì mọ odi yí mi ká, wọ́n sì yí àgọ́ mi ká.
13 “God has caused my brothers to abandon me, and all those who know me act like strangers to me.
“Ó mú àwọn arákùnrin mi jìnà sí mi réré, àti àwọn ojúlùmọ̀ mi di àjèjì sí mi pátápátá.
14 All my relatives and good friends have left me.
Àwọn alájọbí mi fàsẹ́yìn, àwọn ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi sì di onígbàgbé mi.
15 The people who were guests in my house have forgotten me, and my female servants consider that I am a stranger or that I am a foreigner.
Àwọn ará inú ilé mi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi kà mí sí àjèjì; èmi jásí àjèjì ènìyàn ní ojú wọn.
16 When I summon my servants, they do not answer; I plead with them to come [to help me, but they do not come].
Mo pe ìránṣẹ́ mi, òun kò sì dá mi lóhùn; mo fi ẹnu mi bẹ̀ ẹ́.
17 My wife does not want to come close to me because my breath [smells very bad], and even my brothers detest me.
Ẹ̀mí mi ṣú àyà mi, àti òórùn mi ṣú àwọn ọmọ inú ìyá mi.
18 Even young children despise me; when I stand up [to talk to them], they laugh at me.
Àní àwọn ọmọdékùnrin fi mí ṣẹ̀sín, mo dìde, wọ́n sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi.
19 My dearest friends detest me, and those whom I love [very much] have turned against me.
Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi kórìíra mi, àwọn olùfẹ́ mi sì kẹ̀yìndà mí.
20 My body is [only] skin and bones; I am barely alive [IDM].
Egungun mi lẹ̀ mọ́ ara mi àti mọ́ ẹran-ara mi, mo sì yọ́ pẹ̀lú awọ eyín mi.
21 [“I plead with] you, my [three] friends, pity me, because God has (struck [EUP] me with his hand/caused me to suffer greatly).
“Ẹ ṣàánú fún mi, ẹ ṣàánú fún mi, ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, nítorí ọwọ́ Ọlọ́run ti bà mí.
22 Why do you cause me to suffer like God does? Why do you continue to slander [MET] me?
Nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe lépa mi bí Ọlọ́run, tí ẹran-ara mi kò tẹ́ yín lọ́rùn?
23 “I wish/desire that someone would take these words of mine and write them permanently in a book [in order that people can read them].
“Háà! Ìbá ṣe pé a le kọ̀wé ọ̀rọ̀ mi nísinsin yìí, ìbá ṣe pé a le kọ ọ sínú ìwé!
24 Or else, I wish that he would carve them on a rock with (a chisel/an iron tool) in order that they would last forever.
Kí a fi kálámù irin àti ti òjé kọ wọ́n sínú àpáta fún láéláé.
25 But I know that the one who vindicates/defends me in court is alive, and that some day he will stand [here] on the earth [and make the final decision about whether I deserve to be punished].
Nítorí èmi mọ̀ pé olùdáǹdè mi ń bẹ láààyè àti pe òun ni yóò dìde dúró lórí ilẹ̀ ní ìkẹyìn;
26 And even after diseases have eaten away my skin, while I still have my body, I will see God.
àti lẹ́yìn ìgbà tí a pa àwọ̀ ara mi run, síbẹ̀ láìsí ẹran-ara mi ni èmi ó rí Ọlọ́run,
27 I will see him myself; I will see him with my own eyes! I am overwhelmed [as I think about that]!
ẹni tí èmi ó rí fún ara mi, tí ojú mi ó sì wo, kì sì í ṣe ti ẹlòmíràn; ọkàn mi sì dákú ní inú mi.
28 “If you three men say, ‘What more can we do to cause Job to suffer?’ and if you say, ‘He has caused his own [troubles],’
“Bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa ó ti lépa rẹ̀ tó! Àti pé, gbogbo ọ̀rọ̀ náà ni a sá à rí ní ọwọ́ rẹ̀,’
29 you should be afraid that God will punish [MTY] you; he punishes those [like you] with whom he is angry; and when that happens, you will know that there is [someone who] judges [people].”
kí ẹ̀yin kí ó bẹ̀rù, nítorí ìbínú ní í mú ìjìyà wá nípa idà, kí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé ìdájọ́ kan ń bẹ.”

< Job 19 >