< Job 15 >
1 Then Eliphaz replied to Job:
Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
2 “If you were truly wise [RHQ], you would not have replied to us by claiming that you know a lot; what you are saying is just a lot of hot air [MET].
“Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán kí ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?
3 You should not [RHQ] be saying things that do not benefit anyone, using words that do no one any good.
Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?
4 [By what you say, ] you show that you do not revere God, and you are hindering people from meditating/thinking about God.
Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì, ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.
5 [It is as though] your sins are telling you what to say; you talk like people who will not admit that they are wicked.
Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.
6 Everything that you say [MTY] shows that you should be punished; so, it is not necessary for me to show that.
Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi; àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.
7 [“Tell me do you know more than everyone else because you think that] you are the first person who was ever born? [SAR, RHQ] Were you born before the hills [were created]?
“Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí? Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?
8 Were you listening when God made all his plans? [SAR, RHQ] Or do you think that you are the only person who is wise?
Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí? Tàbí ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?
9 (What do you know that we do not know?/You do not know anything that we do not know.) [RHQ] You do not understand [RHQ] anything that is not also clear to us.
Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
10 My friends and I are also wise; we acquired [wisdom] from old gray-haired people, from people who were born before your father was born.
Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
11 God wants to comfort you, and to speak gently/kindly to you; (is that not enough for you/do you need more than that)?
Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ? Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
12 Why do you allow yourself to be (carried away/excited) by your emotions? Why are [you very angry, with the result that] your eyes flash?
Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri, kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.
13 You are angry [IDM] with God, and so you [MTY] are criticizing/denouncing him.
Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?
14 “(How can any person, [including you, ] be sinless?/No person, [including you], can be sinless.) [RHQ] (How can anyone on the earth be [completely] righteous?/No one on the earth can be [completely] righteous.) [RHQ]
“Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́, àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
15 Hey, God does not even trust his angels; he does not consider even them to be [completely] pure.
Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀, àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,
16 So, he certainly does not [trust] abominable/disgusting and depraved/corrupt people who do evil things [as easily] as they drink water [MET].
mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.
17 Job, listen to what I will tell you. I will declare to you what I know,
“Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi; èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
18 things that wise men have told me, truths that their ancestors did not keep hidden.
ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́.
19 God gave this land to those ancestors, who were truly wise; no one from another country caused them to think wrongly [IDM].
Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan, ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
20 It is wicked people who suffer with great pain all the time that they are alive; that is what happens to those who (oppress/act violently toward) others.
Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
21 They constantly hear sounds that terrify them; while they are prospering, bandits attack them.
Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀; nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
22 Wicked people surely know that they will not escape from darkness/death, because [they are sure that someone] is waiting to kill them with a sword.
Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápá kan fún idà.
23 They wander around, searching for food, saying ‘Where can I find some?’ And they know that they will soon experience disasters.
Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
24 Because they are afraid of those things happening to them, they are afraid and worry that these things will come to them like [the army of] a king comes to attack [their enemies and cause them to suffer] [SIM].
Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.
25 [Those things happen to them] because they (shook their fists/dared to fight) against Almighty God, and thought that they were strong enough to defeat him.
Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,
26 They stubbornly [IDM] rush to attack God [as though they were carrying] a strong shield [to protect themselves].
ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga, àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.
27 They are so fat [that they are unable to fight].
“Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀ lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
28 They will live in cities that have been abandoned, cities which have become a heap of ruins.
Òun sì gbé inú ahoro ìlú, àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.
29 But they will not remain rich very long; Everything that they own will be taken from them; their possessions will all disappear.
Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò lè dúró pẹ́; bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
30 They will not escape from the darkness [of death]; they will be like trees whose branches are burned by fire and whose blossoms are blown away by the wind.
Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn; ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀, àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.
31 Since they are very foolish, with the result that they trust in things that are really worthless, then things that are worthless will be all that they get.
Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ. Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.
32 Before they are old, they will wither; they will be like [MET] branches that wither and never become green again.
A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀, ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.
33 They will be like [SIM] vines whose grapes fall off before they are ripe, like olive trees whose blossoms fall off before they produce any fruit.
Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù, yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.
34 Wicked/godless people will not have any descendants, and fires will completely burn up the homes of [those who built those homes using] money they received from bribes.
Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
35 They plan to cause trouble and to do evil things, and they are always preparing to deceive people.”
Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀, ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”