< Job 11 >
1 Then Zophar, from [the] Naamah [area], said this to Job:
Ìgbà náà ni Sofari, ará Naama, dáhùn, ó sì wí pé,
2 “(Should no one answer all that you have said?/Someone should certainly answer all that you have said.) [RHQ] Just because you talk a lot, (should that cause us to declare that you (are innocent/have done nothing wrong)?/that should not cause us to declare that you (are innocent/have done nothing wrong).) [RHQ]
“A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀? A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?
3 Job, (should your babbling cause us to be silent?/your babbling should certainly not cause us to be silent.) [RHQ] When you make fun of us, shall no one [rebuke you and] cause you to be ashamed?
Ṣé àmọ̀tán rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí? Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?
4 You say, ‘What I say is true; God knows that I am (innocent/without guilt).’
Ìwọ sá à ti wí fún Ọlọ́run pé, ‘Ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní ojú rẹ.’
5 But I wish/desire that God would talk and say something [MTY] to answer you!
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀, kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ
6 God knows everything about everything, so I wish/desire that he would tell you the secrets that he knows because he is wise. But you need to know that God is punishing you less than you deserve!
kí ó sì fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ, nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run ti gbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.
7 [“Tell me], will you ever be able to find out the things about God that are very difficult to understand? Will you be able to find out everything that there is to know about Almighty God?
“Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí? Ìwọ ha le ṣe àwárí ibi tí Olódùmarè dé bi?
8 [What there is to know about God] is greater than [the distance from earth to] heaven; so there is no way [RHQ] that you can [understand it all]. It is greater than [the distance from here to] the place of the dead; so it is impossible for you [RHQ] to know it all. (Sheol )
Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe? Ó jìn ju jíjìn isà òkú lọ; kí ni ìwọ le mọ̀? (Sheol )
9 What there is to know about God is wider than the earth and wider than the ocean.
Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ, ó sì ní ibú ju òkun lọ.
10 “If God comes to you and puts you in prison and then brings you to a court, (who can stop him?/no one can stop him.) [RHQ]
“Bí òun bá rékọjá, tí ó sì sé ọnà tàbí tí ó sì mú ni wá sí ìdájọ́, ǹjẹ́, ta ni ó lè dí i lọ́wọ́?
11 He knows which people are worthless; and when he sees people doing wicked things, (will he ignore it?/he will certainly not ignore it!) [RHQ]
Òun sá à mọ ẹlẹ́tàn ènìyàn; àti pé ṣé bí òun bá rí ohun búburú, ṣé òun kì i fi iyè sí i?
12 Stupid people [like you] will start to become wise [SAR] when wild donkeys [stop giving birth to wild donkeys and] start giving birth to tame donkeys.
Ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn ki yóò di ọlọ́gbọ́n bi ko ti rọrùn fún ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó láti bí ènìyàn.
13 “Job, repent [IDM]; reach out your hands to seek God’s help.
“Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un, tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,
14 If you have done evil things, stop doing them; and do not allow any people in your house to do wicked things.
bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ,
15 If you do what I have said, surely you will lift up your head because you will not be ashamed; you will be strong, and not afraid [of anything].
nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láìní àbàwọ́n, àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù.
16 You will forget all your troubles; they will be like [the] water [of a flood] that has all disappeared.
Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ; ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti sàn kọjá lọ.
17 [Your troubles will be ended, like the darkness ends] at the dawn; [it will be as though] [MET] the sun is shining brightly on you, like [it shines] at noon.
Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ, bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísinsin yìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.
18 You will feel safe/secure, because you will confidently expect [that good things will happen to you]; God will protect you and enable you to rest safely [each night].
Ìwọ ó sì wà láìléwu, nítorí pé ìrètí wà; àní ìwọ ó rin ilé rẹ wò, ìwọ ó sì sinmi ní àlàáfíà.
19 You will lie down, and no one will cause you to be afraid. And many people will come and request you to do things for them.
Ìwọ ó sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rùbà ọ́, àní ènìyàn yóò máa wá ojúrere rẹ.
20 But wicked people [SYN] will not be able to understand [why bad things are happening to them]; they will not have any way to escape [from their troubles]. The only thing that they will want to do is to die. [EUP]”
Ṣùgbọ́n ojú ìkà ènìyàn yóò mófo; gbogbo ọ̀nà àbáyọ ni yóò nù wọ́n, ìrètí wọn a sì dàbí ẹni tí ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́.”