< Jeremiah 5 >

1 [Yahweh said to the people of Jerusalem], “Go up and down every street. Search in the marketplaces to find people who do what is fair/right, who try to be faithful to me. [If you find even one person like that], I will forgive [the people of Jerusalem and not destroy] their city.
“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
2 But when people there say, ‘I solemnly declare that as surely as Yahweh lives, [I will do what he says],’ they are lying.”
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 Yahweh, you are certainly [RHQ] searching for [people who tell the] truth. You struck/punished your people, but they did not pay any attention. You crushed them, but they ignored what you were telling them to do. They were extremely stubborn [IDM] and refused to return to you.
Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 I thought, “[We cannot expect] these [people to act righteously, because they] are poor; they do not have any sense. They do not know the way Yahweh wants them to conduct their lives; they do not know what God requires them to do.
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5 So, I will go and talk to their leaders, because they [surely] know how God wants them to conduct their lives.” But they also have stopped obeying Yahweh [MET], and they will not allow him to lead them.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
6 Because of that, lions will come out of the forests and kill them; wolves from the desert will attack them; leopards that lurk/wait outside their cities will maul anyone who walks outside the cities. [Those things will happen] because the people have sinned very much against God and have turned away from him very frequently.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
7 Yahweh says, “I cannot [RHQ] forgive these people; [even] their children have abandoned me. When they solemnly declare something, they ask their gods [to show that what they say is true]. I gave my people everything that they needed, but they often went to [the shrines of their idols] and committed adultery there.
“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
8 [Just like] [MET] well-fed male horses neigh, wanting sex with female horses, each of the men desires to have sex with his neighbor’s wife.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
9 (Should I not punish them for this [RHQ]?/I will certainly get revenge on this nation for this!) I will certainly get revenge [RHQ] on this nation whose people behave like that!
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
10 [I will say to your enemies], ‘The people [of Judah and Israel are like a vineyard]. Go along the rows in their vineyards and get rid of [most of] the people, but do not kill all of them. These people do not belong to me, [so get rid of them], [like a gardener] [MET] lops/cuts off branches from a vine.
“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 The people of Israel and Judah have turned away from me completely.’
Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
12 They have lied about me and said, ‘He will not punish us! He will not cause us to experience disasters! We will not experience wars or famines!
Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 What [God’s] prophets say is nothing but hot air! They do not have messages [from God]! We would like [the disasters that they predict] to happen to them!’”
Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
14 So, this is what Yahweh, the Commander of the armies of angels in heaven, has said to me: “Because my people are saying those things, I will give you a message to tell them [MTY] that will be [like] [MET] a fire, and [these people will be like] [MET] wood that the fire will burn up.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Listen to this, you people of Israel: I will bring [the army of] a distant nation to attack you. It is a very powerful nation that has existed for a long time. They speak a language that you do not know and which you will not be able to understand.
Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Their soldiers are all very strong, and the arrows from their quivers [MET] will (send many Israeli men to their graves/cause many Israeli people to die).
Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 They will eat the food that you have harvested from your fields, and eat your bread. They will kill your sons and daughters, and they will kill your flocks [of sheep] and herds [of cattle]. They will eat your grapes and your figs. They will [also] destroy your cities that have high walls around them and kill the people with their swords.
Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
18 But even when those things happen, I will not get rid of all of you.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
19 And when the survivors ask, ‘Why is Yahweh our God doing this to us?’ you will tell them, ‘You rejected him and worshiped foreign gods in your [own] land, so [now] you will become slaves of foreigners in a land that is not your land.’”
Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
20 [Yahweh said to me], “Proclaim this to the people of Israel and Judah:
“Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 Listen to this, you people who are foolish and who do not have any sense: You have eyes, but [it is as though] you cannot see; you have ears, but [it is as though] you cannot hear.
Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 Why do you not revere me [RHQ]? You should [RHQ] tremble when you are in my presence! I, Yahweh, am the one who put a barrier along the shores so that the waters of the ocean cannot cross it [and flood the land]. The waves roll and roar, but they cannot go past that barrier.
Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 But you people [are not like the waves that obey me]. You people are very stubborn and rebellious. You have constantly turned away from me.
Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 You do not say to yourselves, ‘We should revere Yahweh our God, the one who sends us rain at the times when we need it, the one who causes the grain to become ripe at the harvest season.’
Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 It is because of the wrong things that you have done, that those good things have not happened; it is because of the sins that you have committed that you have been prevented from receiving those blessings.
Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
26 Among my people are wicked people who hide along the roads to ambush/attack people like [SIM] men who hunt birds (put out nets/set traps) to catch them.
“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 Like [a hunter has] a cage full of birds [that he has captured], their homes are full of things that they have gotten by deceiving others. So now they are [very] rich and powerful.
Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28 They are big and fat, and there is no limit to the evil things that they have done. They do not try to defend orphans in the courtrooms, and they do not help poor people to get what they have a right to receive.
wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 So I will certainly [RHQ] punish them for doing those things. I will certainly [RHQ] (get revenge on their nation/do to their nation what they deserve).
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
30 Very appalling/horrible and terrible [DOU] things are happening in this country:
“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 Prophets speak [only] lies and priests rule by their own authority, and you people like that! But when you [start to] experience disasters, what will you do [RHQ]?”
Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?

< Jeremiah 5 >